< Salme 25 >

1 En Psalme af David. Til dig, Herre! opløfter jeg min Sjæl.
Ti Dafidi. Olúwa, ìwọ ni mo gbé ọkàn mi sókè sí.
2 Jeg forlader mig paa dig, min Gud! lad mig ikke beskæmmes, at mine Fjender ikke skulle fryde sig over mig.
Ọlọ́run, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ; má ṣe jẹ́ kí ojú ó tì mí má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi ó yọ̀ mí.
3 Ja, ingen, som bier efter dig, skal beskæmmes; beskæmmes skulle de, som handle troløst uden Aarsag.
Ẹni tí ó dúró tì ọ́ ojú kì yóò tì í, àwọn tí ń ṣẹ̀ láìnídìí ni kí ojú kí ó tì.
4 Herre! lad mig kende dine Veje, lær mig dine Stier.
Fi ọ̀nà rẹ hàn mí, Olúwa, kọ mi ní ipa tìrẹ;
5 Gør, at jeg gaar frem i din Sandhed, og lær mig den; thi du er min Frelses Gud, jeg bier efter dig den ganske Dag.
ṣe amọ̀nà mi nínú òtítọ́ ọ̀ rẹ, kí o sì kọ́ mi, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run ìgbàlà mi; ìwọ ni mo dúró tì ní gbogbo ọjọ́.
6 Herre! kom din Barmhjertighed og din Miskundhed i Hu; thi de have været fra Evighed.
Rántí, Olúwa àánú àti ìfẹ́ ẹ̀ rẹ̀ ńlá, torí pé wọ́n ti wà ní ìgbà àtijọ́.
7 Kom ikke mine Ungdoms Synder eller mine Overtrædelser i Hu; men kom du mig i Hu efter din Miskundhed for din Godheds Skyld, Herre!
Má ṣe rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ìgbà èwe mi tàbí ìrékọjá mi; gẹ́gẹ́ bí i ìfẹ́ ẹ rẹ̀ rántí mi nítorí tí ìwọ dára, Ìwọ! Olúwa.
8 Herren er god og oprigtig, derfor underviser han Syndere om Vejen.
Rere àti ẹni ìdúró ṣinṣin ní Olúwa: nítorí náà, ó kọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni ọ̀nà náà.
9 Han skal gøre, at de ydmygede komme til Ret, og han skal lære de ydmygede sin Vej.
Ó ṣe amọ̀nà àwọn onírẹ̀lẹ̀ ni ohun tí ó dára, ó sì kọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ ní ọ̀nà rẹ̀.
10 Alle Herrens Stier ere Miskundhed og Sandhed for dem, som bevare hans Pagt og hans Vidnesbyrd.
Gbogbo ipa ọ̀nà Olúwa ni ìfẹ́ àti òdodo tí ó dúró ṣinṣin, fún àwọn tí ó pa májẹ̀mú àti ẹ̀rí rẹ̀ mọ́.
11 For dit Navns Skyld, Herre, forlad mig dog min Misgerning; thi den er stor.
Nítorí orúkọ rẹ, Olúwa, dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí, nítorí tí ó tóbi.
12 Hvo er den Mand, som frygter Herren? han skal undervise ham om den Vej, som han skal udvælge.
Àwọn wo ni ó bẹ̀rù Olúwa? Yóò kọ́ wọn ní ọ̀nà èyí tí wọn yóò yàn.
13 Hans Sjæl skal bo i Lyksalighed, og hans Sæd skal arve Landet.
Wọn yóò lo ọjọ́ wọn nínú àlàáfíà, àwọn ọmọ wọn yóò sì gba ilẹ̀ náà.
14 Herrens Omgang er med dem, som frygte ham, og hans Pagt er med dem, til at lade dem kende den.
Olúwa fi ọkàn tán, àwọn tí o bẹ̀rù u rẹ̀; ó sọ májẹ̀mú rẹ̀ di mí mọ̀ fún wọn.
15 Mine Øjne ere stedse til Herren; thi han skal drage mine Fødder ud af Garnet.
Ojú mi gbé sókè sọ́dọ̀ Olúwa, nítorí pé yóò yọ ẹsẹ̀ mi kúrò nínú àwọ̀n náà.
16 Vend dit Ansigt til mig og vær mig naadig; thi jeg er enlig og elendig.
Yípadà sí mi, kí o sì ṣe oore fún mi; nítorí pé mo nìkan wà, mo sì di olùpọ́njú.
17 Mit Hjertes Ængstelser have vidt udbredt sig; før mig ud af mine Trængsler!
Tì mí lẹ́yìn kúrò nínú ìpọ́njú àyà mi; kí o sì fà mí yọ kúrò nínú ìpọ́njú mi.
18 Se hen til min Elendighed og min Møje, og forlad mig alle mine Synder!
Kíyèsi ìjìyà àti wàhálà mi, kí o sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi jì.
19 Se hen til mine Fjender, thi de ere mange; og de hade mig med uretfærdigt Had.
Kíyèsi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀tá mi, tí wọn kórìíra mi pẹ̀lú ìwà ìkà wọn.
20 Bevar min Sjæl og red mig, at jeg ikke beskæmmes, thi jeg tror paa dig.
Pa ọkàn mi mọ́, kí o sì gbà mí sílẹ̀; má ṣe jẹ́ kí a fi mí sínú ìtìjú, nítorí pé ìwọ ni ibi ìsádi mi.
21 Lad Retsindighed og Oprigtighed bevare mig; thi jeg bier efter dig.
Jẹ́ kí òtítọ́ inú àti ìdúró ṣinṣin kí ó pa mí mọ́; nítorí pé mo dúró tì ọ́.
22 Forløs, o Gud, Israel af al dets Nød!
Ra Israẹli padà, Ìwọ Ọlọ́run, nínú gbogbo ìṣòro rẹ̀!

< Salme 25 >