< Genesis 11 >

1 Now the earth was of one language and of the same speech.
Lẹ́yìn náà, gbogbo àgbáyé sì ń sọ èdè kan ṣoṣo.
2 And when they were advancing from the east, they found a plain in the land of Shinar, and they dwelt in it.
Bí àwọn ènìyàn ṣe ń tẹ̀síwájú lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, wọ́n rí pẹ̀tẹ́lẹ̀ kan ní ilẹ̀ Ṣinari, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
3 And each one said to his neighbor, “Come, let us make bricks, and bake them with fire.” And they had bricks instead of stones, and pitch instead of mortar.
Wọ́n sì wí fún ara wọn pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a mọ bíríkì kí a sì sún wọ́n jìnà.” Bíríkì ni wọ́n ń lò ní ipò òkúta, àti ọ̀dà ilẹ̀ tí wọn ń lò láti mú wọn papọ̀ dípò ẹfun (òkúta láìmù tí wọ́n fi ń ṣe símẹ́ńtì àti omi).
4 And they said: “Come, let us make a city and a tower, so that its height may reach to heaven. And let us make our name famous before we are divided into all the lands.”
Nígbà náà ni wọ́n wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tẹ ìlú kan dó fún ara wa, kí a sì kọ́ ilé ìṣọ́ kan tí yóò kan ọ̀run, kí a ba à lè ní orúkọ, kí a má sì tú káàkiri sórí gbogbo ilẹ̀ ayé.”
5 Then the Lord descended to see the city and the tower, which the sons of Adam were building.
Ṣùgbọ́n, Olúwa sọ̀kalẹ̀ láti wo ìlú àti ilé ìṣọ́ tí àwọn ènìyàn náà ń kọ́.
6 And he said: “Behold, the people are united, and all have one tongue. And since they have begun to do this, they will not desist from their plans, until they have completed their work.
Olúwa wí pé, “Bí àwọn ènìyàn bá ń jẹ́ ọ̀kan àti èdè kan tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe iṣẹ́ yìí, kò sí ohun tí wọ́n gbèrò tí wọn kò ní le ṣe yọrí.
7 Therefore, come, let us descend, and in that place confound their tongue, so that they may not listen, each one to the voice of his neighbor.”
Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a sọ̀kalẹ̀ lọ, kí a da èdè wọn rú kí èdè wọn má ba à yé ara wọn mọ́.”
8 And so the Lord divided them from that place into all the lands, and they ceased to build the city.
Olúwa sì tú wọn ká sórí ilẹ̀ gbogbo, wọ́n sì ṣíwọ́ ìlú náà tí wọn ń tẹ̀dó.
9 And for this reason, its name was called ‘Babel,’ because in that place the language of the whole earth became confused. And from then on, the Lord scattered them across the face of every region.
Ìdí èyí ni a fi pè é ní Babeli nítorí ní ibẹ̀ ni Olúwa ti da èdè gbogbo ayé rú. Olúwa tí sì tú àwọn ènìyàn ká sí gbogbo orí ilẹ̀ ayé.
10 These are the generations of Shem. Shem was one hundred years old when he conceived Arphaxad, two years after the great flood.
Wọ̀nyí ni ìran Ṣemu. Ọdún méjì lẹ́yìn ìkún omi, tí Ṣemu pé ọgọ́rùn-ún ọdún ni ó bí Arfakṣadi.
11 And after he conceived Arphaxad, Shem lived for five hundred years, and he conceived sons and daughters.
Lẹ́yìn tí ó bí Arfakṣadi, Ṣemu tún wà láààyè fún ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ọdún, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
12 Next, Arphaxad lived for thirty-five years, and then he conceived Shelah.
Nígbà tí Arfakṣadi pé ọdún márùndínlógójì ni ó bí Ṣela.
13 And after he conceived Shelah, Arphaxad lived for three hundred and three years, and he conceived sons and daughters.
Arfakṣadi sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó lẹ́yìn tí ó bí Ṣela, ó sì bí àwọn ọmọbìnrin àti àwọn ọmọkùnrin mìíràn.
14 Likewise, Shelah lived for thirty years, and then he conceived Eber.
Nígbà tí Ṣela pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Eberi.
15 And after he conceived Eber, Shelah lived for four hundred and three years, and he conceived sons and daughters.
Ṣela sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó lẹ́yìn tí ó bí Eberi tán, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
16 Then Eber lived for thirty-four years, and he conceived Peleg.
Eberi sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n, ó sì bí Pelegi.
17 And after he conceived Peleg, Eber lived for four hundred and thirty years, and he conceived sons and daughters.
Eberi sì wà láààyè fún irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n lẹ́yìn tí ó bí Pelegi, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
18 Likewise, Peleg lived for thirty years, and then he conceived Reu.
Nígbà tí Pelegi pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Reu.
19 And after he conceived Reu, Peleg lived for two hundred and nine years, and he conceived sons and daughters.
Pelegi sì tún wà láààyè fún igba ọdún ó lé mẹ́sàn-án lẹ́yìn tí ó bí Reu, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
20 Then Reu lived for thirty-two years, and then he conceived Serug.
Nígbà tí Reu pé ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ni ó bí Serugu.
21 Likewise, after he conceived Serug, Reu lived for two hundred and seven years, and he conceived sons and daughters.
Reu tún wà láààyè lẹ́yìn tí ó bí Serugu fún igba ọdún ó lé méje, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn.
22 In truth, Serug lived for thirty years, and then he conceived Nahor.
Nígbà tí Serugu pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Nahori.
23 And after he conceived Nahor, Serug lived for two hundred years, and he conceived sons and daughters.
Serugu sì wà láààyè fún igba ọdún lẹ́yìn tí ó bí Nahori, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
24 And so Nahor lived for twenty-nine years, and then he conceived Terah.
Nígbà tí Nahori pé ọmọ ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n, ó bí Tẹra.
25 And after he conceived Terah, Nahor lived for one hundred and nineteen years, and he conceived sons and daughters.
Nahori sì wà láààyè fún ọdún mọ́kàn dín lọ́gọ́fà lẹ́yìn ìbí Tẹra, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
26 And Terah lived for seventy years, and then he conceived Abram, and Nahor, and Haran.
Lẹ́yìn tí Tẹra pé ọmọ àádọ́rin ọdún ó bí Abramu, Nahori àti Harani.
27 And these are the generations of Terah. Terah conceived Abram, Nahor, and Haran. Next Haran conceived Lot.
Wọ̀nyí ni ìran Tẹra. Tẹra ni baba Abramu, Nahori àti Harani. Harani sì bí Lọti.
28 And Haran died before his father Terah, in the land of his nativity, in Ur of the Chaldeans.
Harani sì kú ṣáájú Tẹra baba rẹ̀ ní ilẹ̀ ìbí rẹ̀ ní Uri ti ilẹ̀ Kaldea.
29 Then Abram and Nahor took wives. The name of Abram’s wife was Sarai. And the name of Nahor’s wife was Milcah, the daughter of Haran, the father of Milcah, and the father of Iscah.
Abramu àti Nahori sì gbéyàwó. Orúkọ aya Abramu ni Sarai, nígbà tí aya Nahori ń jẹ́ Milka, tí ṣe ọmọ Harani. Harani ni ó bí Milka àti Iska.
30 But Sarai was barren and had no children.
Sarai sì yàgàn, kò sì bímọ.
31 And so Terah took his son Abram, and his grandson Lot, the son of Haran, and his daughter-in-law Sarai, the wife of his son Abram, and he led them away from Ur of the Chaldeans, to go into the land of Canaan. And they approached as far as Haran, and they dwelt there.
Tẹra sì mú ọmọ rẹ̀ Abramu àti Lọti ọmọ Harani, ọmọ ọmọ rẹ̀, ó sì mú Sarai tí i ṣe aya ọmọ rẹ̀. Abramu pẹ̀lú gbogbo wọn sì jáde kúrò ní Uri ti Kaldea láti lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Ṣùgbọ́n nígbà tí wọn dé Harani wọ́n tẹ̀dó síbẹ̀.
32 And the days of Terah that passed were two hundred and five years, and then he died in Haran.
Nígbà tí Tẹra pé ọmọ igba ọdún ó lé márùn-ún ni ó kú ní Harani.

< Genesis 11 >