< Joshua 14 >

1 This is what the sons of Israel possessed in the land of Canaan, which Eleazar, the priest, and Joshua, the son of Nun, and the leaders of the families, by the tribes of Israel, gave to them,
Ìwọ̀nyí ni ilẹ̀ tí àwọn ọmọ Israẹli gbà gẹ́gẹ́ bí ogún ní ilẹ̀ Kenaani, tí Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn agbo ilé Israẹli pín fún wọn.
2 dividing all by lot, just as the Lord had instructed by the hand of Moses, to the nine tribes and to the one half tribe.
Ìbò ni a fi pín ìní wọn fún àwọn ẹ̀yà mẹ́sàn-án ààbọ̀ gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ọwọ́ Mose.
3 For to the two and one half tribes, Moses had given a possession beyond the Jordan, aside from the Levites, who received no land among their brothers.
Mose ti fún àwọn ẹ̀yà méjì àti ààbọ̀ ní ogún wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Lefi ni kò fi ìní fún ní àárín àwọn tí ó kù.
4 For by succession, the sons of Joseph, in their place, were divided into two tribes, Manasseh and Ephraim. But the Levites did not receive another portion of land, except cities in which to live, and their suburbs, so as to feed their beasts of burden and cattle.
Àwọn ọmọ Josẹfu sì di ẹ̀yà méjì, Manase àti Efraimu. Àwọn ọmọ Lefi kò gba ìpín ní ilẹ̀ náà bí kò ṣe àwọn ìlú tí wọn yóò máa gbé, pẹ̀lú pápá oko tútù fún ọ̀wọ́ ẹran àti agbo ẹran wọn.
5 Just as the Lord had commanded Moses, so the sons of Israel did, and they divided the land.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli pín ilẹ̀ náà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
6 And so, the sons of Judah approached Joshua at Gilgal. And Caleb, the son of Jephone, the Kenizzite, spoke to him: “You know what the Lord said to Moses, the man of God, at Kadesh-barnea, about me and you.
Àwọn ọkùnrin Juda wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ní Gilgali. Kalebu ọmọ Jefunne ti Kenissiti wí fún un pé, “Ìwọ rántí ohun tí Olúwa sọ fún Mose ènìyàn Ọlọ́run ní Kadeṣi-Barnea nípa ìwọ àti èmi.
7 I was forty years old when Moses, the servant of the Lord, sent me from Kadesh-barnea, so that I might consider the land. And I reported to him what seemed to me to be true.
Mo jẹ́ ọmọ ogójì ọdún nígbà tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa rán mi láti Kadeṣi-Barnea lọ rin ilẹ̀ náà wò. Mo sì mú ìròyìn wá fún un gẹ́gẹ́ bí o ti dá mi lójú,
8 But my brothers, who had ascended with me, broke the heart of the people. And I nevertheless followed the Lord my God.
ṣùgbọ́n àwọn arákùnrin mi tí wọ́n bá mi lọ mú àyà àwọn ènìyàn já. Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi fi gbogbo ọkàn tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run mi.
9 And Moses swore, on that day, saying: ‘The land that your foot has tread upon shall be your possession, and that of your sons, unto eternity. For you have followed the Lord my God.’
Ní ọjọ́ náà, Mose búra fún mi pé, ‘Ilẹ̀ tí ẹsẹ̀ rẹ ti rìn ni yóò jẹ́ ìní rẹ àti ti àwọn ọmọ rẹ láéláé, nítorí pé ìwọ fi tọkàntọkàn wà pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run mi.’
10 Therefore, the Lord has granted life to me, just as he promised, even to the present day. It has been forty-five years since the Lord spoke this word to Moses, when Israel was wandering through the wilderness. Today, I am eighty-five years old,
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, kíyèsi i Olúwa dá mi sí gẹ́gẹ́ bí ó ti wí, láti ọdún márùndínláàádọ́ta yìí wá, láti ìgbà tí Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ yìí fún Mose, nígbà tí Israẹli ń rìn kiri nínú aginjù, sì kíyèsi i nísinsin yìí, èmi nìyìí lónìí, ọmọ àrùndínláàdọ́rùn-ún ọdún.
11 being just as strong as I was at that time, when I was sent to explore the land. The fortitude in me at that time continues even until today, as much to fight as to march.
Síbẹ̀ èmi ní agbára lónìí, bí ìgbà tí Mose rán mi jáde. Èmi sì ní agbára láti jáde fún ogun nísinsin yìí gẹ́gẹ́ bí mo ti wà ní ìgbà náà.
12 Therefore, grant to me this mountain, which the Lord has promised in your hearing also, on which are the Anakim, and cities, great and fortified. Perhaps it may be that the Lord will be with me, and I will be able to destroy them, just as he promised to me.”
Nísinsin yìí fi ìlú orí òkè fún mi èyí tí Olúwa ṣe ìlérí fún mi ní ọjọ́ náà. Ìwọ gbọ́ ní ìgbà náà pé àwọn ọmọ Anaki ti wà ní ibẹ̀, àti àwọn ìlú wọn tóbi, pé ó sì ṣe olódi, ṣùgbọ́n bí Olúwa ba fẹ́, èmi yóò lé wọn jáde, gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ.”
13 And Joshua blessed him, and he delivered Hebron to him as a possession.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua súre fun Kalebu ọmọ Jefunne ó si fun un ní Hebroni ni ilẹ̀ ìní.
14 And from then on, Hebron was for Caleb, the son of Jephunneh, the Kenizzite, even to the present day. For he followed the Lord, the God of Israel.
Bẹ́ẹ̀ ni Hebroni jẹ́ ti Kalebu ọmọ Jefunne ará Kenissiti láti ìgbà náà, nítorí tí ó tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run Israẹli tọkàntọkàn.
15 Previously, the name Hebron was called Kiriath-Arba. Adam, the greatest among the Anakim, was laid there. And the land ceased from battles.
(Hebroni a sì máa jẹ́ Kiriati-Arba ní ẹ̀yìn Arba, èyí tí ó jẹ́ ènìyàn ńlá nínú àwọn ọmọ Anaki.) Nígbà náà ni ilẹ̀ náà sinmi ogun.

< Joshua 14 >