< Ezra 2 >

1 Now these [are] the children of the province that went up out of the captivity, of those which had been carried away, whom Nebuchadnezzar the king of Babylon had carried away unto Babylon, and came again unto Jerusalem and Judah, every one unto his city;
Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
2 Which came with Zerubbabel: Jeshua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordecai, Bilshan, Mispar, Bigvai, Rehum, Baanah. The number of the men of the people of Israel:
Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
3 The children of Parosh, two thousand an hundred seventy and two.
Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
4 The children of Shephatiah, three hundred seventy and two.
Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
5 The children of Arah, seven hundred seventy and five.
Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
6 The children of Pahath-moab, of the children of Jeshua [and] Joab, two thousand eight hundred and twelve.
Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
7 The children of Elam, a thousand two hundred fifty and four.
Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
8 The children of Zattu, nine hundred forty and five.
Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
9 The children of Zaccai, seven hundred and threescore.
Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
10 The children of Bani, six hundred forty and two.
Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
11 The children of Bebai, six hundred twenty and three.
Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
12 The children of Azgad, a thousand two hundred twenty and two.
Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
13 The children of Adonikam, six hundred sixty and six.
Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
14 The children of Bigvai, two thousand fifty and six.
Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
15 The children of Adin, four hundred fifty and four.
Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
16 The children of Ater of Hezekiah, ninety and eight.
Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
17 The children of Bezai, three hundred twenty and three.
Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
18 The children of Jorah, an hundred and twelve.
Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
19 The children of Hashum, two hundred twenty and three.
Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
20 The children of Gibbar, ninety and five.
Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
21 The children of Beth-lehem, an hundred twenty and three.
Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
22 The men of Netophah, fifty and six.
Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
23 The men of Anathoth, an hundred twenty and eight.
Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
24 The children of Azmaveth, forty and two.
Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
25 The children of Kirjath-arim, Chephirah, and Beeroth, seven hundred and forty and three.
Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
26 The children of Ramah and Gaba, six hundred twenty and one.
Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
27 The men of Michmas, an hundred twenty and two.
Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
28 The men of Beth-el and Ai, two hundred twenty and three.
Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
29 The children of Nebo, fifty and two.
Nebo jẹ́ méjìléláàádọ́ta
30 The children of Magbish, an hundred fifty and six.
Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
31 The children of the other Elam, a thousand two hundred fifty and four.
Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
32 The children of Harim, three hundred and twenty.
Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
33 The children of Lod, Hadid, and Ono, seven hundred twenty and five.
Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
34 The children of Jericho, three hundred forty and five.
Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
35 The children of Senaah, three thousand and six hundred and thirty.
Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
36 The priests: the children of Jedaiah, of the house of Jeshua, nine hundred seventy and three.
Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
37 The children of Immer, a thousand fifty and two.
Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
38 The children of Pashur, a thousand two hundred forty and seven.
Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
39 The children of Harim, a thousand and seventeen.
Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
40 The Levites: the children of Jeshua and Kadmiel, of the children of Hodaviah, seventy and four.
Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
41 The singers: the children of Asaph, an hundred twenty and eight.
Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
42 The children of the porters: the children of Shallum, the children of Ater, the children of Talmon, the children of Akkub, the children of Hatita, the children of Shobai, [in] all an hundred thirty and nine.
Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
43 The Nethinims: the children of Ziha, the children of Hasupha, the children of Tabbaoth,
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
44 The children of Keros, the children of Siaha, the children of Padon,
Kerosi, Siaha, Padoni,
45 The children of Lebanah, the children of Hagabah, the children of Akkub,
Lebana, Hagaba, Akkubu,
46 The children of Hagab, the children of Shalmai, the children of Hanan,
Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
47 The children of Giddel, the children of Gahar, the children of Reaiah,
Giddeli, Gahari, Reaiah,
48 The children of Rezin, the children of Nekoda, the children of Gazzam,
Resini, Nekoda, Gassamu,
49 The children of Uzza, the children of Paseah, the children of Besai,
Ussa, Pasea, Besai,
50 The children of Asnah, the children of Mehunim, the children of Nephusim,
Asna, Mehuni, Nefisimu,
51 The children of Bakbuk, the children of Hakupha, the children of Harhur,
Bakbu, Hakufa, Harhuri.
52 The children of Bazluth, the children of Mehida, the children of Harsha,
Basluti, Mehida, Harṣa,
53 The children of Barkos, the children of Sisera, the children of Thamah,
Barkosi, Sisera, Tema,
54 The children of Neziah, the children of Hatipha.
Nesia àti Hatifa.
55 The children of Solomon’s servants: the children of Sotai, the children of Sophereth, the children of Peruda,
Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
56 The children of Jaalah, the children of Darkon, the children of Giddel,
Jaala, Darkoni, Giddeli,
57 The children of Shephatiah, the children of Hattil, the children of Pochereth of Zebaim, the children of Ami.
Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
58 All the Nethinims, and the children of Solomon’s servants, [were] three hundred ninety and two.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
59 And these [were] they which went up from Tel-melah, Tel-harsa, Cherub, Addan, [and] Immer: but they could not shew their father’s house, and their seed, whether they [were] of Israel:
Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
60 The children of Delaiah, the children of Tobiah, the children of Nekoda, six hundred fifty and two.
Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
61 And of the children of the priests: the children of Habaiah, the children of Koz, the children of Barzillai; which took a wife of the daughters of Barzillai the Gileadite, and was called after their name:
Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
62 These sought their register [among] those that were reckoned by genealogy, but they were not found: therefore were they, as polluted, put from the priesthood.
Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
63 And the Tirshatha said unto them, that they should not eat of the most holy things, till there stood up a priest with Urim and with Thummim.
Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
64 The whole congregation together [was] forty and two thousand three hundred [and] threescore,
Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
65 Beside their servants and their maids, of whom [there were] seven thousand three hundred thirty and seven: and [ there were] among them two hundred singing men and singing women.
Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
66 Their horses [were] seven hundred thirty and six; their mules, two hundred forty and five;
Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
67 Their camels, four hundred thirty and five; [their] asses, six thousand seven hundred and twenty.
ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
68 And [some] of the chief of the fathers, when they came to the house of the LORD which [is] at Jerusalem, offered freely for the house of God to set it up in his place:
Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
69 They gave after their ability unto the treasure of the work threescore and one thousand drams of gold, and five thousand pound of silver, and one hundred priests’ garments.
Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
70 So the priests, and the Levites, and [some] of the people, and the singers, and the porters, and the Nethinims, dwelt in their cities, and all Israel in their cities.
Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.

< Ezra 2 >