< 2 Corinthians 11 >

1 I wish you were bearing with me little (a *no) (of foolishness; *N+kO) but indeed you do endure me.
Mo rò wí pé ẹ ó faradà díẹ̀ nínú ìwà òmùgọ̀ mi ṣùgbọ́n bẹ́ẹ̀ ni, mo fẹ́ kí ẹ gbà mí láàyè.
2 I am jealous as to for you of God with [the] jealousy; I have betrothed for you to one husband a virgin pure to present to Christ,
Nítorí pé èmi ń jowú lórí i yín bí ẹni ìwà-bí-Ọlọ́run, nítorí tí mo ti fì yín fún ọkọ kan, kí èmi bà á lè mú yín wá bí wúńdíá tí ó mọ́ sọ́dọ̀ Kristi.
3 I am afraid however lest perhaps as the serpent deceived Eve in the craftiness of him, (thus *k) may be corrupted the minds of you from the simplicity (and the purity *NO) in Christ.
Ṣùgbọ́n ẹ̀rù ń bà mí, kí ó má bà á jẹ́ pé, bí ejò ti tan Efa jẹ́ nípasẹ̀ àrékérekè rẹ̀, a lè mú ọkàn yín ṣáko lọ kúrò nínú òtítọ́ yín àti ìfarajì fún Kristi.
4 If indeed for the [one] coming another Jesus proclaims whom not we did proclaim, or a spirit different you receive which not you did receive, or glad tidings different which not you did accept, well (you are enduring [it]. *N+k+o)
Nítorí bí ẹnìkan bá wá tí ó sì wàásù Jesu mìíràn, yàtọ̀ sí èyí tí a ti wàásù rí tàbí bí ẹ̀yin bá gba ẹ̀mí mìíràn, yàtọ̀ sí èyí tí ẹ ti gbà tàbí ìyìnrere mìíràn yàtọ̀ sí èyí tí ẹ ti gbà, tí ẹ sì ti yára tẹ́wọ́ gbà á.
5 I reckon for in nothing to have been inferior to those most eminent most eminent apostles.
Nítorí mo rò pé èmi kò rẹ̀yìn nínú ohunkóhun sí àwọn àgbà Aposteli.
6 If however even unpolished in speech [I am], yet not in knowledge, but in every [way] (were manifested *N+kO) in all things to you.
Bí mo tilẹ̀ jẹ́ òpè nínú ọ̀rọ̀ sísọ, kì í ṣe nínú ìmọ̀; ní ọ̀nàkọnà ni àwa ti fi èyí hàn dájúdájú fún yín nínú ohun gbogbo.
7 Or a sin did I commit myself humbling so that you yourselves may be exalted, because freely the of God gospel I evangelised to you?
Tàbí ẹ̀ṣẹ̀ ni mo dá bí èmi ti ń rẹ ara mí sílẹ̀ kí a lè gbé yín ga, nítorí tí mo wàásù ìyìnrere Ọlọ́run fún un yín lọ́fẹ̀ẹ́.
8 Other churches I robbed having received support for the toward you service,
Èmí ń ja ìjọ mìíràn ni olè nípa gbígba ìpèsè owó ki èmi bà á lè sìn yín.
9 And being present with you and having been in need not I did burden no [one]; for the need of mine completely filled up the brothers having come from Macedonia, and in everything unburdensome myself to you I kept and will keep.
Nígbà tí mo sì wà pẹ̀lú yín, tí mo sì ṣe aláìní, èmi kò dẹ́rù pa ẹnikẹ́ni, nítorí ohun tí mo ṣe aláìní ni àwọn ará tí ó ti Makedonia wá ti mú wá. Bẹ́ẹ̀ ni nínú ohun gbogbo mo pa ara mi mọ́ láti má ṣe jẹ́ ẹrù fún yín, èmi yóò sì pa ara mi mọ́ bẹ́ẹ̀.
10 Is [the] truth of Christ in me myself that boasting this not (will be stopped *N+kO) of mine in the regions of Achaia.
Ó jẹ́ òtítọ́, Kristi tí ń bẹ nínú mi pé kò sí ẹni tí ó lè dá mi lẹ́kun ìṣògo yìí ni gbogbo ẹkùn Akaia.
11 Because of why? Because surely I do love you? God knows [I do]!
Nítorí kín ni? Nítorí èmi kò fẹ́ràn yín ni bí? Ọlọ́run mọ̀.
12 What however I do, also I will do, so that I may cut off the opportunity of those desiring an opportunity that in what they are boasting, they may be found even as also we ourselves.
Èmi yóò tẹ̀síwájú láti máa ṣe ohun ti èmi ń ṣe láti le mú ìjákulẹ̀ bá àwọn tí wọn ń wá ọ̀nà láti bá wa dọ́gba nínú èyí ti àwa ń ṣògo lé lórí.
13 For such [are] false apostles, workers deceitful, disguising themselves as apostles of Christ;
Nítorí irú àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ ni àwọn èké Aposteli àwọn ẹni ti ń ṣiṣẹ́ ẹ̀tàn, tí ń pa wọ́n dà di aposteli Kristi.
14 And no (wonder; *N+kO) himself for Satan masquerades as an angel of light;
Kì í sì í ṣe ohun ìyanu; nítorí Satani, tìkára rẹ̀ ń pa ara rẹ̀ dàbí angẹli ìmọ́lẹ̀.
15 [It is] not surprising therefore if even the servants of him masquerade as servants of righteousness whose end will be according to the deeds of them.
Nítorí náà kì í ṣe ohun ńlá bí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú bá pa ara wọn dàbí àwọn ìránṣẹ́ òdodo; ìgbẹ̀yìn àwọn ẹni tí yóò rí gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn.
16 Again I say, no one me may think a fool to be; lest then except indeed even even as a fool do receive me, that I myself also I myself also little a may boast.
Mo sì tún wí pé, kí ẹnikẹ́ni má ṣe rò pé òmùgọ̀ ni mí; ṣùgbọ́n bí bẹ́ẹ̀ bá ni, ẹ gbà mí bí òmùgọ̀ kí èmi lè gbé ara mi ga díẹ̀.
17 What I am saying, not according to [the] Lord am I saying but as in foolishness, in this the confidence of boasting.
Ohun tí èmi ń sọ, èmi kò sọ ọ́ nípa ti Olúwa, ṣùgbọ́n bí òmùgọ̀ nínú ìgbẹ́kẹ̀lé ìṣògo yìí.
18 Since many boast according to (the *ko) flesh, I myself also I myself also will boast.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀, ni ó ń ṣògo nípa ti ara, èmi ó ṣògo pẹ̀lú.
19 Gladly for you bear with fools, wise being!
Nítorí ẹ̀yin fi inú dídùn gba àwọn òmùgọ̀ nígbà tí ẹ̀yin tìkára yín jẹ́ ọlọ́gbọ́n.
20 You bear [it] for if anyone you enslaves, if anyone devours [you], if anyone takes [from you], if anyone exalts himself, if anyone in [the] face you strikes.
Nítorí ẹ̀yin faradà á bí ẹnìkan bá sọ yín dí òǹdè, bí ẹnìkan bá jẹ́ yín run, bí ẹnìkan bá gbà lọ́wọ́ yín, bí ẹnìkan bá gbé ara rẹ̀ ga, bí ẹnìkan bá gbá yín lójú.
21 As to dishonor I speak, as that we ourselves (have been weak! *N+kO) In whatever however maybe anyone may be daring — in foolishness I speak — am daring I myself also. I myself also.
Èmi ń wí lọ́nà ẹ̀gàn, bí ẹni pé àwa jẹ́ aláìlera! Ṣùgbọ́n nínú ohunkóhun tí ẹnìkan ti ní ìgboyà, èmi ń sọ̀rọ̀ bí òmùgọ̀, èmi ní ìgboyà pẹ̀lú.
22 Hebrews are they? I myself also; I myself also; Israelites are they? I myself also; I myself also; Descendants of Abraham are they? I myself also; I myself also;
Heberu ni wọ́n bí? Bẹ́ẹ̀ ni èmi. Israẹli ni wọ́n bí? Bẹ́ẹ̀ ni èmi. Irú-ọmọ Abrahamu ní òun bí? Bẹ́ẹ̀ ni èmi.
23 Servants of Christ are they? As being beside myself I speak; above [measure] I myself[am]. in labors more abundantly in imprisonments more abundantly, in beatings above measure, in deaths often.
Ìránṣẹ́ Kristi ni wọ́n bí? Èmi ń sọ bí òmùgọ̀, mo ta wọ́n yọ; ní ti làálàá lọ́pọ̀lọ́pọ̀, ní ti pàṣán, mo rékọjá, ní ti túbú nígbàkígbà, ní ti fífẹ́rẹ kú nígbà púpọ̀.
24 From [the] Jews five times forty [lashes] minus one I received,
Nígbà márùn-ún ni mo gba pàṣán ogójì dín ẹyọ kan lọ́wọ́ àwọn Júù.
25 Three times I was beaten with rods, once I was stoned, three times I was shipwrecked, a night and a day in the deep [sea] I have passed;
Nígbà mẹ́ta ni a fi ọ̀gọ̀ lù mí, ẹ̀ẹ̀kan ṣoṣo ni a sọ mí ní òkúta, ẹ̀ẹ̀mẹta ni ọkọ̀ ojú omi mi rì, ọ̀sán kan àti òru kan ni mo wà nínú ibú.
26 in journeyings often, in perils of rivers, in perils of robbers, in perils from [my own] race, in perils from [the] Gentiles, in perils in [the] city, in perils in [the] wilderness, in perils on [the] sea, in perils among false brothers,
Ní ìrìnàjò nígbàkígbà, nínú ewu omi, nínú ewu àwọn ọlọ́ṣà, nínú ewu àwọn ará ìlú mi, nínú ewu àwọn aláìkọlà, nínú ewu ni ìlú, nínú ewu ní aginjù, nínú ewu lójú Òkun, nínú ewu láàrín àwọn èké arákùnrin.
27 (in *k) labor and toil, in watchings often, in hunger and thirst, in fastings often, in cold and nakedness;
Nínú làálàá àti ìrora, nínú ìṣọ́ òru nígbàkígbà, nínú ebi àti òǹgbẹ, nínú àwẹ̀ nígbàkígbà, nínú òtútù àti ìhòhò.
28 Besides the [things] external the (stoppage on me *N+kO) on every day [is my] care for all the churches.
Pẹ̀lú nǹkan wọ̀nyí tí ó jẹ́ tí òde, ọ̀pọ̀ ni èyí tí ń wọn n dúró tì mí lójoojúmọ́, àní àníyàn fún gbogbo ìjọ.
29 Who is weak, and not I am weak? Who is led into sin, and surely I myself do burn inwardly?
Ta ni ó ṣe àìlera, tí èmi kò ṣe àìlera? Tàbí a mú kọsẹ̀, tí ara mi kò gbiná?
30 If to boast it behooves [me], [in] the [things] of the weakness of mine I will boast.
Bí èmi yóò bá ṣògo, èmi ó kúkú máa ṣògo nípa àwọn nǹkan tí ó jẹ́ ti àìlera mi.
31 The God and Father of the Lord (of us *k) Jesus (Christ *K) knows, who is being blessed to the ages, that not I am lying. (aiōn g165)
Ọlọ́run àti Baba Olúwa wá Jesu Kristi, ẹni tí ó jẹ́ olùbùkún jùlọ láéláé mọ̀ pé èmi kò ṣèké. (aiōn g165)
32 In Damascus the governor under Aretas the king was guarding the city of the Damascenes to seize me (wishing *KO)
Ní Damasku, baálẹ̀ tí ó wà lábẹ́ ọba Areta fi ẹgbẹ́ ogun ká ìlú àwọn ará Damasku mọ́, ó ń fẹ́ láti mú mi bí arúfin.
33 But through a window in a basket I was let down through the wall and I escaped the hands of him.
Láti ojú fèrèsé nínú agbọ̀n ni a sì ti sọ̀ mí kalẹ̀ lẹ́yìn odi, tí mo sì bọ́ lọ́wọ́ rẹ̀.

< 2 Corinthians 11 >