< Psalms 24 >

1 The earth and everything in it belongs to Yahweh; all the people in the world belong to him, too,
Ti Dafidi. Saamu. Ti Olúwa ni ilẹ̀, àti ẹ̀kún rẹ̀, ayé àti àwọn tí ó tẹ̀dó sínú rẹ̀;
2 because he caused the ground to be above the water, above the water that was deep below the surface of the earth.
nítorí ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ lórí òkun ó sì gbé e kalẹ̀ lórí àwọn ìṣàn omi.
3 Who will be allowed to go up on Zion Hill [in Jerusalem], in order to stand [and worship] in Yahweh’s holy temple?
Ta ni yóò gun orí òkè Olúwa lọ? Ta ni yóò dúró ní ibi mímọ́ rẹ̀?
4 [Only] those whose actions [MTY] and thoughts are pure, who have not worshiped idols, and who do not tell lies when they have solemnly promised [to tell the truth].
Ẹni tí ó ní ọwọ́ mímọ́ àti àyà funfun, ẹni tí kò gbé ọkàn rẹ̀ sókè sí asán tí kò sì búra èké.
5 (They will be blessed by Yahweh/Yahweh will bless them). When God [judges them], he, who has saved them, will say that they (have done nothing wrong/are without fault).
Òun ni yóò rí ìbùkún gbà láti ọ̀dọ̀ Olúwa, àti òdodo lọ́wọ́ Ọlọ́run ìgbàlà rẹ̀.
6 They are the ones who approach God, they are the ones who may worship God, the one [we] Israelis worship.
Èyí ni ìran àwọn tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, Ọlọ́run Jakọbu. (Sela)
7 Open up [APO] the [temple] gates in order that our glorious king may enter!
Ẹ gbé orí yín sókè, háà! Ẹ̀yin ọ̀nà; kí á sì gbe yín sókè, ẹyin ìlẹ̀kùn ayérayé! Kí ọba ògo le è wọlé.
8 [Do you know] who the glorious king is? He is Yahweh, the one who is very strong [DOU]; He is Yahweh, who conquers [all his enemies] in battles!
Ta ni ọba ògo náà? Olúwa tí ó lágbára tí ó sì le, Olúwa gan an, tí ó lágbára ní ogun.
9 Open up the [temple] gates in order that our glorious king may enter!
Gbé orí yín sókè, ẹyin ọ̀nà; kí a sì gbé e yín sókè, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé, kí Ọba ògo le è wọlé wá.
10 [Do you know] who the glorious king is? He is Yahweh almighty; he is our glorious king!
Ta ni Ọba ògo náà? Olúwa àwọn ọmọ-ogun Òun ni Ọba ògo náà. (Sela)

< Psalms 24 >