< Zephaniah 1 >

1 [I am] Zephaniah, the son of Cushi, the grandson of Gedaliah, and the great-grandson of Amariah, whose father was [King] Hezekiah. Yahweh gave this message to me during the time when [King] Amon’s son Josiah was the King of Judah.
Sí olórí akọrin lórí ohun èlò orin olókùn mi. Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Sefaniah ọmọ Kuṣi, ọmọ Gedaliah, ọmọ Amariah, ọmọ Hesekiah, ní ìgbà Josiah ọmọ Amoni ọba Juda.
2 Yahweh says, “I will (sweep away/destroy) everything [HYP] that is on the earth.
“Èmi yóò mú gbogbo nǹkan kúrò lórí ilẹ̀ náà pátápátá,” ni Olúwa wí.
3 I will sweep away people and animals. I will sweep away birds and fish. I will get rid of wicked people; there will be no more [wicked] [HYP] people on the earth.”
“Èmi yóò mú ènìyàn àti ẹranko kúrò; èmi yóò mú àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run kúrò, àti ẹja inú Òkun, àti ohun ìdìgbòlù pẹ̀lú àwọn ènìyàn búburú; èmi yóò ké ènìyàn kúrò lórí ilẹ̀ ayé,” ni Olúwa wí.
4 “[These are some of the things that I will do]: I will punish the people who live in Jerusalem and [other places in] Judah. I will destroy everything that has been used in the worship of Baal. I will cause [people] to no longer remember the names of the pagan priests or the [other] priests [who have turned away from me].
“Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Juda àti sórí gbogbo àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jerusalẹmu. Èmi yóò sì ké kúrò níhìn-ín yìí ìyókù àwọn Baali, àti orúkọ àwọn abọ̀rìṣà pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà,
5 [I will get rid of] those who go up on the roofs [of their houses] and worship the sun and moon and stars, those who claim that they worship me but [also] worship [their god] Molech.
àti àwọn tí ń foríbalẹ̀ lórí òrùlé, àwọn tí ń sin ogun ọ̀run, àwọn tó ń foríbalẹ̀, tí wọ́n sì ń fi Olúwa búra, tí wọ́n sì ń fi Moleki búra.
6 I will get rid of all those who previously worshiped me but no longer do, those who no [longer] seek my [help or ask me to tell them what they should do.”]
Àwọn tí ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa; àti àwọn tí kò tí wá Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì béèrè rẹ̀.”
7 Be silent in front of Yahweh the Lord, because it will soon be the time/day when Yahweh [will judge and punish people]. Yahweh has prepared to get rid of [the people of Judah]; they will be like [MET] animals that are slaughtered for sacrifices, and he has chosen [their enemies] to be the ones who will get rid of them.
Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa Olódùmarè, nítorí tí ọjọ́ Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀. Olúwa ti pèsè ẹbọ kan sílẹ̀, ó sì ti ya àwọn alápèjẹ rẹ̀ sí mímọ́.
8 Yahweh says, “On that day when I will get rid of [the people of Judah], [I will punish] their officials and the king’s sons, and [I will punish] all those who worship foreign gods [MTY].
“Ní ọjọ́ ẹbọ Olúwa, Èmi yóò bẹ àwọn olórí wò, àti àwọn ọmọ ọba ọkùnrin, pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó wọ àjèjì aṣọ.
9 I will punish those who [show that they revere their god Dagan] by avoiding stepping on the threshold [of his temple], and those who do violent things and tell lies in the temples of their gods.”
Ní ọjọ́ náà, èmi yóò fi ìyà jẹ gbogbo àwọn tí ó yẹra láti rìn lórí ìloro ẹnu-ọ̀nà, tí wọ́n sì kún tẹmpili àwọn ọlọ́run wọn pẹ̀lú ìwà ipá àti ẹ̀tàn.
10 Yahweh [also] says, “On that day, people will cry [out] at the Fish Gate [of Jerusalem]. People will wail in the newer part of the city, and [people will hear] a loud crash [of buildings collapsing] in the hills.
“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí, “Ohùn ẹkún yóò wà láti ìhà ibodè ẹja, híhu láti ìhà kejì wá àti ariwo ńlá láti òkè kékeré wá.
11 [So, all you] people who live in the market area [of Jerusalem] should wail, because all those who sell goods and weigh out silver will be slaughtered.
Ẹ hu, ẹ̀yin tí ń gbé ní agbègbè ọjà, gbogbo àwọn oníṣòwò rẹ̀ ni a ó mú kúrò, gbogbo àwọn ẹni tí ó ń ra fàdákà ni a ó sì parun.
12 [It will be as though] I will light lanterns to search in [dark places in] Jerusalem for those who have become very satisfied with their behavior and complacent [about their sins]. They think that [I], Yahweh, will do nothing to them, neither good things nor bad things.
Ní àkókò wọ̀n-ọn-nì, èmi yóò wá Jerusalẹmu kiri pẹ̀lú fìtílà, èmi ó sì fi ìyà jẹ àwọn tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn, tí wọn sì dàbí àwọn ènìyàn tí ó sinmi sínú gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ wọn, àwọn tí wọn sì ń wí ní ọkàn wọn pé, ‘Olúwa kì yóò ṣe nǹkan kan tí ó jẹ́ rere tàbí tí ó jẹ́ búburú.’
13 [But I say that] their valuable possessions will be plundered/stolen [by their enemies], and their houses will be destroyed. They will build [new] homes, but they will not live in them; they will plant vineyards, but they will never drink [any] wine [made from grapes that grow there].”
Nítorí náà, ọrọ̀ wọn yóò di ìkógun, àti ilé wọn yóò sì run. Àwọn yóò sì kọ́ ilé pẹ̀lú, ṣùgbọ́n wọn kì yóò gbé nínú ilé náà, wọn yóò gbin ọgbà àjàrà, ṣùgbọ́n wọn kì yóò mu ọtí wáìnì láti inú rẹ̀.”
14 It will soon be the day/time when Yahweh [will punish people]. It will be here quickly. It will be a time [when people cry] bitterly, a time when [even] brave soldiers will cry loudly.
“Ọjọ́ ńlá Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀, ó kù sí dẹ̀dẹ̀ ó sì ń yára bọ̀ kánkán. Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ohùn ẹkún àwọn alágbára; ní ọjọ́ Olúwa yóò korò púpọ̀,
15 It will be a time when [God shows that he is] very angry, a time when [people experience much] distress/suffering and trouble. [It will be] a time [when many things are] ruined and destroyed [DOU]. It will be a time when it is very gloomy and dark [DOU], when the clouds are very black.
ọjọ́ náà yóò jẹ́ ọjọ́ ìbínú, ọjọ́ ìrora àti ìpọ́njú, ọjọ́ òfò àti idà ọjọ́ ìdahoro ọjọ́ òkùnkùn àti ìtẹ̀ba, ọjọ́ kurukuru àti òkùnkùn biribiri,
16 It will be a time when [soldiers] will blow trumpets [to call other soldiers] to battle. [Your enemies] will tear down the walls around your cities and the high towers [at the corners of those walls].
ọjọ́ ìpè àti ìpè ogun sí àwọn ìlú olódi àti sí àwọn ilé ìṣọ́ gíga.
17 Because you sinned against Yahweh, he will cause you to experience great distress; you will walk [around groping] like [SIM] blind people do. Your blood will flow [from your bodies] like [SIM] water, and your corpses will lie on the ground and rot [SIM].
“Èmi yóò sì mú ìpọ́njú wá sórí ènìyàn, wọn yóò sì máa rìn gẹ́gẹ́ bí afọ́jú, nítorí àwọn ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa. Ẹ̀jẹ̀ wọn ni a ó sì tú jáde bí eruku àti ẹran-ara wọn bí ìgbẹ́.
18 At the time that [Yahweh shows that he] is very angry [with you], you will not be able to save yourselves by [giving] silver or gold [to your enemies]. Because Yahweh (is very jealous/does not want people to worship any other god), he will send a fire to burn up the entire world, and he will suddenly get rid of all the [wicked] people who live on the earth.
Bẹ́ẹ̀ ni fàdákà tàbí wúrà wọn kì yóò sì le gbà wọ́n là ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.” Ṣùgbọ́n gbogbo ayé ni a ó fi iná ìjowú rẹ̀ parun, nítorí òun yóò fi ìyára fi òpin sí gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilẹ̀ ayé.

< Zephaniah 1 >