< Acts 23 >

1 Then Paul, fixing a steady gaze on the Sanhedrin, said, "Brethren, it is with a perfectly clear conscience that I have discharged my duties before God up to this day."
Paulu tẹjúmọ́ ìgbìmọ̀, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin arákùnrin mi, èmi tí ń fi gbogbo ẹ̀rí ọkàn rere lo ayé mi níwájú Ọlọ́run títí fi di òní yìí.”
2 On hearing this the High Priest Ananias ordered those who were standing near Paul to strike him on the mouth.
Nígbà yìí ni Anania olórí àlùfáà pàṣẹ fún àwọn tí ó dúró tí Paulu pé, kí wọn ó gbá a lẹ́nu.
3 "Before long," exclaimed Paul, "God will strike you, you white-washed wall! Are you sitting there to judge me in accordance with the Law, and do you yourself actually break the Law by ordering me to be struck?"
Nígbà náà ni Paulu wí fún un pé, “Ọlọ́run yóò lù ọ́, ìwọ ògiri tí a kùn lẹ́fun: ìwọ jókòó láti dá mi lẹ́jọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin, ṣùgbọ́n ìwọ gan an rú òfin nípa pípàṣẹ pé kí a lù mí!”
4 "Do you rail at God's High Priest?" cried the men who stood by him.
Àwọn tí ó dúró tì Paulu sì wí pé, “Ìwọ́ ń gan olórí àlùfáà Ọlọ́run?”
5 "I did not know, brethren," replied Paul, "that he was the High Priest; for it is written, 'Thou shalt not speak evil of a ruler of Thy people.'"
Paulu sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin arákùnrin mi, èmi kò mọ̀ pé olórí àlùfáà ni: nítorí a tí kọ ọ́ pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ sọ̀rọ̀ olórí àwọn ènìyàn rẹ̀ ní búburú.’”
6 Noticing, however, that the Sanhedrin consisted partly of Sadducees and partly of Pharisees, he called out loudly among them, "Brethren, I am a Pharisee, the son of Pharisees. It is because of my hope of a resurrection of the dead that I am on my trial."
Ṣùgbọ́n nígbà tí Paulu ṣàkíyèsí pé, apá kan wọn jẹ́ Sadusi, apá kan sì jẹ́ Farisi, ó kígbe ní ìgbìmọ̀ pé, “Ẹ̀yin arákùnrin mi, èmi jẹ́ Farisi, ọmọ Farisi sì ni èmi. Mo dúró ní ìdájọ́ nítorí ìrètí mi nínú àjíǹde òkú.”
7 These words of his caused an angry dispute between the Pharisees and the Sadducees, and the assembly took different sides.
Nígbà tí ó sì tí wí èyí, ìyapa dé láàrín àwọn Farisi àti àwọn Sadusi: àjọ sì pín sì méjì.
8 For the Sadducees maintain that there is no resurrection, and neither angel nor spirit; but the Pharisees acknowledge the existence of both.
Nítorí tí àwọn Sadusi wí pé, kò sì àjíǹde, tàbí angẹli, tàbí ẹ̀mí: ṣùgbọ́n àwọn Farisi jẹ́wọ́ méjèèjì.
9 So there arose a great uproar; and some of the Scribes belonging to the sect of the Pharisees sprang to their feet and fiercely contended, saying, "We find no harm in the man. What if a spirit has spoken to him, or an angel----!"
Ó sì di ariwo ńlá, nínú àwọn olùkọ́ òfin tí ó wà ni apá tí àwọn Farisi dìde, wọ́n ń jà, wí pé, “Àwa kò rí ohun búburú kan lára ọkùnrin yìí,” wọ́n wí “àwa kò sì mọ̀ nítòótọ́ bí angẹli kan tàbí ẹ̀mí kan ń ba à sọ̀rọ̀?”
10 But when the struggle was becoming violent, the Tribune, fearing that Paul would be torn to pieces by the people, ordered the troops to go down and take him from among them by force and bring him into the barracks.
Nígbà tí ìyapa sì di ńlá, tí olórí ogun bẹ̀rù kí Paulu má ba à di fífàya lọ́wọ́ wọn, ó pàṣẹ pé ki àwọn ọmọ-ogun sọ̀kalẹ̀ lọ láti fi ipá mú un kúrò láàrín wọn, kí wọn sì mú un wá sínú àgọ́ àwọn ológun.
11 The following night the Lord came and stood at Paul's side, and said, "Be of good courage, for as you have borne faithful witness about me in Jerusalem, so you must also bear witness in Rome."
Ní òru ọjọ́ náà Olúwa dúró tì Paulu, ó wí pé, “Mú ọkàn le! Bí ìwọ ti jẹ́rìí fún mi ní Jerusalẹmu, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò lè ṣàìjẹ́rìí ni Romu pẹ̀lú.”
12 Now, when daylight came, the Jews formed a conspiracy and solemnly swore not to eat or drink till they had killed Paul.
Nígbà tí ilẹ̀ mọ́, àwọn Júù kan dìtẹ̀, wọ́n fi ara wọn bú pé, àwọn kì yóò jẹ, bẹ́ẹ̀ ní àwọn kì yóò mú títí àwọn ó fi pa Paulu.
13 There were more than forty of them who bound themselves by this oath.
Àwọn tí ó dìtẹ̀ yìí sì ju ogójì ènìyàn lọ.
14 They went to the High Priests and Elders and said to them, "We have bound ourselves under a heavy curse to take no food till we have killed Paul.
Wọ́n sì tọ olórí àwọn àlùfáà àti àwọn alàgbà lọ, wọn sì wí pé, “Àwa tí fi ara wa sínú ìdè ìbúra pé, a kì yóò tọ́ oúnjẹ kan wò títí àwa ó fi pa Paulu.
15 Now therefore you and the Sanhedrin should make representations to the Tribune for him to bring him down to you, under the impression that you intend to inquire more minutely about him; and we are prepared to assassinate him before he comes near the place."
Ǹjẹ́ nísinsin yìí kí ẹ̀yin pẹ̀lú àjọ ìgbìmọ̀ wí fún olórí ogun, kí ó mú un sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá, bí ẹni pé ẹ̀yin ń fẹ́ wádìí ọ̀ràn rẹ̀ dájúdájú. Kí ó tó súnmọ́ tòsí, àwa ó ti múra láti pa á.”
16 But Paul's sister's son heard of the intended attack upon him. So he came and went into the barracks and told Paul about it;
Nígbà tí ọmọ arábìnrin Paulu sí gbúròó ìdìtẹ̀ wọn, ó lọ, ó sì wọ inú àgọ́ àwọn ológun lọ, ó sì sọ fún Paulu.
17 and Paul called one of the Captains and said, "Take this young man to the Tribune, for he has information to give him."
Paulu sì pé ọ̀kan nínú àwọn balógun ọ̀run sọ́dọ̀ rẹ̀, ó ní, “Mú ọmọkùnrin yìí tọ olórí ogun lọ, nítorí ó ní nǹkan láti sọ fún un.”
18 So he took him and brought him to the Tribune, and said, "Paul, the prisoner, called me to him and begged me to bring this youth to you, because he has something to say to you."
Ó mú un, ó sì sìn ín lọ sọ́dọ̀ olórí ogun. Balógun ọ̀rún náà wí pé, “Paulu òǹdè pè mi sọ́dọ̀ rẹ̀, ó síbẹ̀ mí pé ki èmi mú ọmọkùnrin yìí tọ̀ ọ́ wá, ẹni tí ó ní nǹkan láti sọ fún ọ.”
19 Then the Tribune, taking him by the arm, withdrew out of the hearing of others and asked him, "What have you to tell me?"
Alábojútó-ogun fà á lọ́wọ́, ó sì lọ si apá kan, ó sì bi í léèrè níkọ̀kọ̀ pé, “Kín ni ohun tí ìwọ ní sọ fún mi?”
20 "The Jews," he replied, "have agreed to request you to bring Paul down to the Sanhedrin to-morrow for the purpose of making yourself more accurately acquainted with the case.
Ó sì wí pé, “Àwọn Júù fi ìmọ̀ ṣọ̀kan láti wá bẹ̀ ọ́, kí o mú Paulu sọ̀kalẹ̀ wá sí àjọ ìgbìmọ̀ ní ọ̀la, bí ẹni pé àwọn ń fẹ́ béèrè nǹkan dájúdájú nípa rẹ̀.
21 I beg you not to comply; for more than forty men among them are lying in wait for him, who have solemnly vowed that they will neither eat nor drink till they have assassinated him; and even now they are ready, in anticipation of receiving that promise of you."
Nítorí náà má ṣe gbọ́ tiwọn, nítorí àwọn tí ó dènà dè é nínú wọn ju ogójì ọkùnrin lọ, tí wọ́n fi ara wọn bú pé, àwọn kì yóò jẹ, bẹ́ẹ̀ ni àwọn kì yóò mu títí àwọn o fi pa á. Wọ́n sì ti múra tan nísinsin yìí, wọ́n ń retí ìdáhùn lọ́dọ̀ rẹ.”
22 So the Tribune sent the youth home, cautioning him. "Do not let any one know that you have given me this information," he said.
Nígbà náà ni olórí ogun fi ọmọ náà sílẹ̀ láti lọ, ó sí kìlọ̀ fún un pé, “Má ṣe wí fún ẹnìkan pé, ìwọ fi nǹkan wọ̀nyí hàn mi.”
23 Then, calling to him two of the Captains, he gave his orders. "Get ready two hundred men," he said, "to march to Caesarea, with seventy cavalry and two hundred light infantry, starting at nine o'clock to-night."
Ó sì pe méjì nínú àwọn balógun ọ̀run sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ múra igba ọmọ-ogun sílẹ̀, láti lọ sí Kesarea, àti àádọ́rin ẹlẹ́ṣin, àti igba ọlọ́kọ̀, ní wákàtí kẹta òru.
24 He further told them to provide horses to mount Paul on, so as to bring him safely to Felix the Governor.
Ó sì wí pé, kí wọn pèsè ẹṣin, kí wọ́n gbé Paulu gùn ún; kí wọ́n sì lè mú un dé ọ̀dọ̀ Feliksi baálẹ̀ ní àlàáfíà.”
25 He also wrote a letter of which these were the contents:
Ó sì kọ ìwé kan báyìí pé,
26 "Claudius Lysias to his Excellency, Felix the Governor: all good wishes.
Kilaudiu Lisia, sí Feliksi baálẹ̀ ọlọ́lá jùlọ, àlàáfíà.
27 This man Paul had been seized by the Jews, and they were on the point of killing him, when I came upon them with the troops and rescued him, for I had been informed that he was a Roman citizen.
Àwọn Júù mú ọkùnrin yìí, wọ́n sì ń pète láti pa á, nígbà náà ni mo dé pẹ̀lú ogun, mo sì gbà á lọ́wọ́ wọn nígbà tí mo gbọ́ pé ará Romu ni í ṣe.
28 And, wishing to know with certainty the offense of which they were accusing him, I brought him down into their Sanhedrin,
Nígbà tí mo sì ń fẹ́ mọ ìdí ọ̀ràn tí wọn fi ẹ̀sùn kàn án sí, mo mú un sọ̀kalẹ̀ lọ sí àjọ ìgbìmọ̀ wọn.
29 and I discovered that the charge had to do with questions of their Law, but that he was accused of nothing for which he deserves death or imprisonment.
Ẹni tí mo rí pé, wọ́n fi sùn nítorí ọ̀ràn òfin wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò dá ọ̀ràn ohun kan tí ó tọ́ sí ikú àti sí ẹ̀wọ̀n.
30 But now that I have received information of an intended attack upon him, I immediately send him to you, directing his accusers also to state before you the case they have against him."
Nígbà tí a sì tí jí i sọ fún mi pé, wọn yóò dènà de ọkùnrin náà, mo rán an sí ọ lọ́gán, mo sì pàṣẹ fún àwọn olùfisùn rẹ̀ pẹ̀lú, láti sọ ohun tí wọ́n bá rí wí sí i níwájú rẹ̀.
31 So, in obedience to their orders, the soldiers took Paul and brought him by night as far as Antipatris.
Nígbà náà ni àwọn ọmọ-ogun gbe Paulu, wọ́n sì mú un lóru lọ si Antipatrisi, gẹ́gẹ́ bí a tí pàṣẹ fún wọn.
32 The next day the infantry returned to the barracks, leaving the cavalry to proceed with him;
Ní ọjọ́ kejì wọ́n sì fi àwọn ẹlẹ́ṣin sílẹ̀ láti máa bá a lọ, àwọn sì padà wá sínú àgọ́ àwọn ológun.
33 and, the cavalry having reached Caesarea and delivered the letter to the Governor, they brought Paul also to him.
Nígbà tí wọ́n dé Kesarea, tí wọ́n sí fi ìwé fún baálẹ̀, wọ́n mú Paulu pẹ̀lú wá síwájú rẹ̀.
34 Felix, after reading the letter, inquired from what province he was; and being told "from Cilicia,"
Nígbà tí ó sì ti ka ìwé náà, ó béèrè pé agbègbè ìlú wo ni tirẹ̀. Nígbà tí ó sì gbọ́ pé ará Kilikia ni;
35 he said, "I will hear all you have to say, when your accusers also have come." And he ordered him to be detained in custody in Herod's Palace.
Ó wí pé, “Èmi yóò gbọ́ ẹjọ́ rẹ, nígbà tí àwọn olùfisùn rẹ pẹ̀lú bá dé.” Ó sì pàṣẹ pé kí wọn pa Paulu mọ́ ní abẹ́ àbojútó àwọn olùṣọ́ ní gbọ̀ngàn ìdájọ́ ààfin Herodu.

< Acts 23 >