< Nahum 2 >

1 Il est monté Celui qui délivre de l'affliction, te soufflant au visage. Observe la voie; ceins-toi les reins; agis en homme selon ta force.
Àwọn apanirun ti dìde sí ọ, ìwọ Ninefe. Pa ilé ìṣọ́ mọ́, ṣọ́ ọ̀nà náà, di àmùrè, ẹ̀gbẹ́ rẹ kí ó le múra gírí.
2 Le Seigneur a détourné l'outrage fait à Jacob, ainsi que l'outrage fait à Israël; car les envahisseurs les ont arrachés, et ils ont détruit leurs plantations.
Olúwa yóò mú ọláńlá Jakọbu padà sípò gẹ́gẹ́ bí ọláńlá Israẹli bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn apanirun ti pa ibẹ̀ run, tí wọ́n sì ba ẹ̀ka àjàrà wọn jẹ́.
3 Ils ont détruit les armes qui les rendaient puissants parmi les hommes, et leurs vaillants qui se jouaient de la flamme; mais au jour de Sa venue, les rênes de leurs chars et leurs cavaliers seront en désordre.
Asà àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sì di pupa; àwọn ológun wọn sì wọ aṣọ òdòdó. Idẹ tí ó wà lórí kẹ̀kẹ́ ogun ń kọ mọ̀nàmọ́ná ní ọjọ́ tí a bá pèsè wọn sílẹ̀ tán; igi firi ni a ó sì mì tìtì.
4 Dans les rues, les chars s'entrechoqueront; ils s'embarrasseront les uns les autres au milieu des places. leurs aspect sera comme des lampes de feu, ou des éclairs sillonnant la nue.
Àwọn kẹ̀kẹ́ ogun yóò ya bo àwọn pópónà, wọn yóò sì máa sáré síwá àti sẹ́yìn ní àárín ìgboro. Wọn sì dàbí ètùfù iná; tí ó sì kọ bí i mọ̀nàmọ́ná.
5 Et leurs grands se souviendront alors, et ils fuiront le jour, et ils défailliront en leur chemin, et ils se hâteront de courir à leurs remparts, et ils y placeront des sentinelles.
Ninefe yóò ṣe àṣàrò àwọn ọlọ́lá rẹ̀; síbẹ̀ wọ́n ń kọsẹ̀ ní ojú ọ̀nà wọn; wọn sáré lọ sí ibi odi rẹ̀, a ó sì pèsè ààbò rẹ̀.
6 Mais les portes des villes ont été forcées, et les palais du roi ont croulé;
A ó ṣí ìlẹ̀kùn àwọn odò wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀, a ó sì mú ààfin náà di wíwó palẹ̀.
7 et les fondations en ont été mises à découvert, et n'ont plus été qu'un monceau de ruines, et les femmes ont été emmenées comme des colombes, gémissant en leurs cœurs.
A pa á láṣẹ pé ìlú náà, èyí tí a ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ ni a ó sì kó ní ìgbèkùn lọ. A ó sì mú un gòkè wá àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ yóò kérora bí ti ẹyẹ àdàbà, wọn a sì máa lu àyà wọn.
8 Et les eaux de Ninive ont été comme un étang plein d'eau, et ses habitants ont fui, et ils ne s'y sont pas arrêtés, et pas un n'a regardé en arrière.
Ninefe dàbí adágún omi, tí omi rẹ̀ sì ń gbẹ́ ẹ lọ. “Dúró! Dúró!” ni wọ́n ó máa kígbe, ṣùgbọ́n ẹnìkankan kì yóò wo ẹ̀yìn.
9 Les vainqueurs ont pillé l'argent, ils ont pillé l'or; car ses ornements étaient sans nombre; ils sont accablés sous le poids des vases qu'elle avait convoités.
“Ẹ kó ìkógun fàdákà! Ẹ kó ìkógun wúrà! Ìṣúra wọn ti kò lópin náà, àti ọrọ̀ kúrò nínú gbogbo ohun èlò ti a fẹ́!”
10 Ce n'est partout que coups et contrecoups, tumulte et brisement du cœur, défaillance des genoux et violentes douleurs de reins; toute face est comme le fond noir d'une chaudière.
Òun ti ṣòfò, ó si di asán, ó sì di ahoro: ọkàn pami, eékún ń lu ara wọn, ìrora púpọ̀ sì wà nínú gbogbo ẹgbẹ́ àti ojú gbogbo wọ́n sì rẹ̀wẹ̀sì.
11 Où est le repaire des lions, et le pâturage des lionceaux? Où est allé le lion pour que le lionceau y entre avec lui? Et n'y avait-il personne pour les effrayer?
Níbo ni ihò àwọn kìnnìún wà àti ibi ìjẹun àwọn ọmọ kìnnìún, níbi tí kìnnìún, àní abo kìnnìún tí ń rìn, àti ọmọ kìnnìún, láìsí ohun ìbẹ̀rù.
12 Le lion ravissait ce qui convenait à ses lionceaux, et pour eux il multipliait les meurtres; il remplissait de gibier son antre, et de rapines son repaire.
Kìnnìún tipa ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì fún un ẹran ọdẹ ní ọrùn pa fún àwọn abo kìnnìún rẹ̀, ó sì fi ohun pípa kún ibùgbé rẹ̀ àti ihò rẹ̀ fún ohun ọdẹ.
13 Voilà que je viens à toi, dit le Seigneur tout-puissant, et Je brûlerai au milieu de la fumée ton peuple nombreux, et le glaive dévorera tes lions, et Je détruirai sur la terre le fruit de tes rapines, et l'on n'entendra plus parler de tes œuvres.
“Kíyèsi i èmi dojúkọ ọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi yóò sì fi kẹ̀kẹ́ rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì jóná nínú èéfín, idà yóò sì jẹ ọmọ kìnnìún rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì run. Èmi yóò sì ké ohun ọdẹ rẹ kúrò lórí ilẹ̀ ayé. Ohùn àwọn ìránṣẹ́ rẹ ni a kì yóò sì tún gbọ́ mọ́.”

< Nahum 2 >