< Sophonie 3 >

1 Malheur à la réfractaire et souillée, à la cité qui opprime!
Ègbé ni fún ìlú aninilára, ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́.
2 Elle n'est docile à aucune voix, ne reçoit pas instruction, en l'Éternel elle ne se confie pas, de son Dieu elle ne s'approche pas.
Òun kò gbọ́rọ̀ sí ẹnikẹ́ni, òun kò gba ìtọ́ni, òun kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni òun kò súnmọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀.
3 Ses princes dans son sein sont des lions rugissants, ses juges des loups du soir, ils ne réservent rien pour le lendemain.
Àwọn olórí rẹ̀ jẹ́ kìnnìún tí ń ké ramúramù, àwọn onídàájọ́ rẹ̀, ìkookò àṣálẹ́ ni wọn, wọn kò sì fi nǹkan kan kalẹ̀ fún òwúrọ̀.
4 Ses prophètes sont des fanfarons, des hommes perfides, ses sacrificateurs profanent le sanctuaire, violent la loi.
Àwọn wòlíì rẹ̀ gbéraga, wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn. Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti ba ibi mímọ́ jẹ́, wọ́n sì rú òfin.
5 L'Éternel est juste au milieu d'elle, Il ne fait rien d'injuste, chaque matin Il produit au jour ses lois, Il n'y manque point; mais le méchant ne connaît point de pudeur.
Olúwa ni àárín rẹ̀ jẹ́ olódodo; kì yóò ṣe ohun tí kò tọ̀nà. Àràárọ̀ ni ó máa ń mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sí ìmọ́lẹ̀, kì í sì kùnà ní gbogbo ọjọ́ tuntun, síbẹ̀ àwọn aláìṣòótọ́ kò mọ ìtìjú.
6 J'ai exterminé des peuples; leurs tours ont été dévastées; j'ai désolé leurs rues, tellement qu'il n'y a plus de passants; leurs villes ont été détruites, dépeuplées, privées d'habitants.
“Èmi ti ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, ilé gíga wọn sì ti bàjẹ́. Mo ti fi ìgboro wọn sílẹ̀ ní òfo tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnìkankan kò kọjá níbẹ̀. Ìlú wọn parun tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí yóò ṣẹ́kù, kò sì ní sí ẹnìkan rárá.
7 J'ai dit: « Pourvu que tu me craignes, que tu reçoives instruction, » la ruine de sa demeure n'arriverait pas, tout le châtiment que je lui avais destiné. Mais dès le matin ils ont perverti toutes leurs œuvres.
Èmi wí fún ìlú náà wí pé, ‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi, ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’ Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúrò bí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n ní yà tó. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtara láti ṣe ìbàjẹ́.
8 Aussi attendez-moi, dit l'Éternel, pour le jour où je me lèverai pour faire du butin; car j'ai arrêté de rassembler les peuples, de réunir les royaumes pour verser sur eux ma fureur, toute l'ardeur de ma colère, car au feu de mon courroux toute la terre sera consumée.
Nítorí náà ẹ dúró dè mí,” ni Olúwa wí, “títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò fi jẹ́rìí sí yin. Nítorí ìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ kí èmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ àti láti da ìbínú mi jáde sórí wọn, àní gbogbo ìbínú gbígbóná mi. Nítorí gbogbo ayé ni a ó fi iná owú mi jẹ run.
9 Car alors je donnerai aux peuples des lèvres nouvelles, afin qu'ils invoquent tous le nom de l'Éternel et le servent unanimement.
“Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́, nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa, láti fi ọkàn kan sìn ín.
10 De par-delà les fleuves de l'Ethiopie mes adorateurs, les enfants de mes dispersés, apporteront mes offrandes.
Láti òkè odò Etiopia, àwọn olùjọsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká, yóò mú ọrẹ wá fún mi.
11 En ce temps-là tu n'auras plus à rougir de tous les faits dont tu t'es rendue coupable envers moi, car alors j'éloignerai de toi tes insolents triomphants, et désormais tu ne t'enorgueilliras plus sur ma sainte montagne.
Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútì nítorí gbogbo iṣẹ́ ibi ni tí ó ti ṣẹ̀ sí mi, nígbà náà ni èmi yóò mu kúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn. Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́ ní òkè mímọ́ mi.
12 Et je laisserai au milieu de toi un peuple pauvre et chétif, qui se confie dans le nom de l'Éternel.
Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútù àti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárín rẹ̀, wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.
13 Les restes d'Israël ne commettront pas l'iniquité ni ne proféreront le mensonge, et il ne se trouvera dans leur bouche point de langue trompeuse, mais on les fera paître, et ils reposeront sans être troublés.
Àwọn ìyókù Israẹli kì yóò hùwà ibi, wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké. Bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí ahọ́n àrékérekè ní ẹnu wọn. Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rùbà wọ́n.”
14 Jubile, fille de Sion! chante victoire, Israël! livre à la joie et à l'allégresse ton cœur tout entier, fille de Jérusalem!
Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Sioni, kígbe sókè, ìwọ Israẹli! Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.
15 L'Éternel retire la sentence portée contre toi, Il éloigne ton ennemi: le Roi d'Israël au milieu de toi, c'est l'Éternel; désormais tu ne connaîtras plus les maux.
Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nì kúrò, ó sì ti ti àwọn ọ̀tá rẹ padà sẹ́yìn. Olúwa, ọba Israẹli wà pẹ̀lú rẹ; ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.
16 En ce jour on dira à Jérusalem: Ne crains point! Sion, que tes bras ne défaillent point!
Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jerusalẹmu pé, “Má ṣe bẹ̀rù Sioni; má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.
17 L'Éternel, ton Dieu, est au milieu de toi, héros sauveur; tu feras sa joie et ses délices; dans son amour Il gardera le silence, tu feras son allégresse et son ravissement.
Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, Ó ní agbára láti gbà ọ là. Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀; Yóò tún ọ ṣe nínú ìfẹ́ rẹ̀, Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ.”
18 Je recueille ceux qui s'attristent éloignés de l'assemblée; ils t'appartiennent, ils sont sous le poids de l'opprobre.
“Èmi ó kó àwọn tí ó ń banújẹ́ fún àjọ̀dún tí a yàn jọ, àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀; àwọn tí ẹ̀gàn rẹ̀ jásí ẹ̀rù.
19 Voici, j'aurai affaire à tous tes oppresseurs en ce temps-là, et je sauverai ce qui boite et recueillerai ce qui sera dispersé, et leur ferai obtenir de la louange et de la gloire dans tous les pays où ils subissent l'opprobre.
Ní àkókò náà ni èmi yóò dojúkọ àwọn tí ń ni yín lára, èmi yóò gba àtiro là, èmi yóò sì ṣa àwọn tí ó ti fọ́nká jọ, èmi yóò fi ìyìn àti ọlá fún wọn ní gbogbo ilẹ̀ tí a bá ti dójútì wọ́n.
20 Dans ce temps-là je vous ramènerai, et en ce même temps je vous recueillerai, car je vous rendrai célèbres et illustres auprès de tous les peuples de la terre, en ramenant vos captifs, sous vos yeux, dit l'Éternel.
Ní àkókò náà ni èmi yóò ṣà yín jọ; nígbà náà ni èmi yóò mú un yín padà wá sílé. Èmi yóò fi ọlá àti ìyìn fún un yín láàrín gbogbo ènìyàn àgbáyé, nígbà tí èmi yóò yí ìgbèkùn yín padà bọ sípò ní ojú ara yín,” ni Olúwa wí.

< Sophonie 3 >