< II Na Lii 1 >

1 A LAILA kipi ae la ka Moaba i ka Iseraela, mahope o ka make ana o Ahaba.
Lẹ́yìn ikú Ahabu, Moabu ṣọ̀tẹ̀ sí Israẹli.
2 A haule iho la o Ahazia ilalo i kona papaholo, mailuna mai o ka pahale ma Samaria, a mai iho la: a hoouna aku la ia i na elele, a i aku la ia lakou, E hele oukou e ninau aku ia Baalazebuba, ke akua o Ekerona, i ko'u ola ana i keia mai.
Nísinsin yìí Ahasiah ti ṣubú láàrín fèrèsé láti òkè yàrá rẹ̀ tí ó wà ní Samaria, ó sì fi ara pa. Ó sì rán oníṣẹ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni, bóyá èmi ó lè rí ìwòsàn ìfarapa yìí.”
3 Olelo mai la ka anela o Iehova ia Elia no Tiseba, E ku, a hele aku e halawai me na elele o ke alii o Samaria, a e i aku ia lakou, No ka nele anei o ka Iseraela i ke Akua, nolaila hele ai oukou e ninau ia Baalazebuba, ke akua o Ekerona?
Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa wí fún Elijah ará Tiṣibi pé, “Lọ sókè kí o lọ bá ìránṣẹ́ ọba Samaria kí o sì béèrè lọ́wọ́ wọn, ‘Ṣé nítorí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli ni ẹ̀yìn fi jáde lọ ṣèwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu òrìṣà Ekroni?’
4 Ano hui, ke olelo mai nei o Iehova peneia, Aole oe e iho ilalo, mai kahi moe mai au i pii aku ai; aka, e make io no oe. A hoi aku la o Elia.
Nítorí náà ohun tí Olúwa sọ ní èyí, ‘Ìwọ kò ní kúrò lórí ibùsùn tí o dùbúlẹ̀ lé. Dájúdájú ìwọ yóò kú!’” Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ.
5 A i ka hoi ana'ku o na elele, ninau mai la kela ia lakou, No ke aha la oukou i hoi hou mai nei?
Nígbà tí ìránṣẹ́ náà padà sí ọ̀dọ̀ ọba, ó béèrè ní ọwọ́ wọn pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi tètè padà wá?”
6 I aku la lakou ia ia, I hele mai kekahi kanaka e halawai me makou, a i mai la ia makou, Ou haele, e hoi hou i ke alii, nana oukou i hoouna mai nei, a e olelo aku ia ia, Ke olelo mai nei o Iehova peneia, No ka nele anei o ka Iseraela i ke Akua, nolaila anei i hoouna aku ai oe e ninau ia Baalazebuba ke akua o Ekerona? no ia mea, aole oe e iho ilalo mai kahi moe mai au i pii aku ai, aka, e make io no oe.
Wọ́n dáhùn pé, “Ọkùnrin kan wá láti pàdé wa, ó sì wí fún wa pé, ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ ọba tí ó rán an yín kí ẹ sì wí fún un pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Ṣé nítorí wí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli ni o fi ń rán àwọn ènìyàn láti lọ ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni? Nítorí náà ìwọ kò ní fi orí ibùsùn tí ìwọ dùbúlẹ̀ lé sílẹ̀. Láìsí àní àní ìwọ yóò kùú!”’”
7 Ninau mai la oia ia lakou, Heaha la ke ano o ke kanaka i pii mai ai e halawai me oukou, a i hai mai hoi ia oukou i keia mau olelo?
Ọba béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Irú ọkùnrin wo ni ó wá pàdé yín, tí ó sì sọ irú èyí fún un yín?”
8 I aku la lakou ia ia, He kanaka huluhulu, a na kaeiia kona puhaka i ke kaei ili. I mai la ia, O Elia no ia no Tiaeba.
Wọ́n dáhùn pé, “Ó jẹ́ ọkùnrin tí ó wọ ẹ̀wù onírun lára pẹ̀lú ọ̀já àmùrè aláwọ tí ó gbà yíká ìbàdí rẹ̀.” Ọba sì wí pé, “Elijah ará Tiṣibi ni.”
9 Alaila hoouna aku ke alii io na la i lunakanalima me kona poe he kanalima; a pii aku la ia io na la; aia hoi, e noho ana ia maluna pono o kekahi puu; i aku la oia ia ia, E ke kanaka o ke Akua, ua i mai ke alii, E iho oe ilalo.
Ó sì rán balógun pẹ̀lú àwọn ẹgbẹ́ ogun àádọ́ta rẹ̀. Balógun náà sì gòkè tọ Elijah lọ, ẹni tí ó jókòó ní orí òkè, wọ́n sì wí fún un pé, “Ènìyàn Ọlọ́run, ọba wí pé, ‘Sọ̀kalẹ̀ wá!’”
10 Olelo mai la o Elia, i mai la i ka lunakanalima, Ina he kanaka wau no ke Akua, e haule mai ke ahi mai ka lani mai, a e hoopau ia oe, a me kou poe he kanalima. Alaila haule mai ke ahi mai ka lani mai, a hoopau iho la ia ia, a me kona poe he kanalima.
Elijah sì dá balógun lóhùn pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ènìyàn Ọlọ́run ni mí, kí iná kí ó sọ̀kalẹ̀ láti òkè ọ̀run wá kí ó sì jó ìwọ àti àwọn àádọ́ta ọkùnrin rẹ!” Nígbà náà iná náà sì sọ̀kalẹ̀ wá láti òkè ọ̀run ó sì jó balógun àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
11 Hoouna hou aku la ia io na la i lunakanalima e ae, me kona poe he kanalima; a olelo aku la ia ia, i aku la, E ke kanaka o ke Akua, ua i mai ke alii peneia, E iho koke oe ilalo.
Ọba sì tún rán balógun àádọ́ta pẹ̀lú àwọn ènìyàn àádọ́ta rẹ̀ sí Elijah. Balógun náà sì wí fún un pé, “Ènìyàn Ọlọ́run, èyí ni ohun tí ọba sọ, ‘Sọ̀kalẹ̀ kánkán!’”
12 Olelo mai la o Elia, i mai la ia lakou, Ina he kanaka wau no ke Akua, e haule mai ke ahi mai ka lani mai, a e hoopau ia oe, a me kou poe he kanalima. A haule mai ke ahi a ke Akua mai ka lani mai, a hoopau ia ia, a me kona poe he kanalima.
“Tí èmi bá jẹ́ ènìyàn Ọlọ́run,” Elijah sì dáhùn, “Ǹjẹ́ kí iná kí ó sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run kí ó sì jó ọ run àti àwọn àádọ́ta ènìyàn rẹ!” Nígbà náà iná Ọlọ́run sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run ó sì jó o run pẹ̀lú àwọn àádọ́ta ènìyàn rẹ̀.
13 A hoouna hou aku la ia i luna o ke kolu o ke kanalima me kona poe he kanalima; a pii aku la ke kolu o ka lunakanalima, a hele aku a kukuli iho la imua o Elia, a nonoi aku ia ia, i aku la ia ia, E ke kanaka o ke Akua, ke nonoi aku nei au ia oe, e malamaia ko'u oia, a me ke ola o keia kanalima, kau poe kauwa imua o kou maka.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba tún rán balógun kẹta pẹ̀lú àwọn àádọ́ta ọkùnrin. Balógun ẹ̀ẹ̀kẹ́ta lọ sí òkè, ó sì kúnlẹ̀ lórí orókún rẹ̀ níwájú Elijah. “Ènìyàn Ọlọ́run,” Ó sì bẹ̀bẹ̀ pé, “Ìwọ ènìyàn Ọlọ́run, jọ̀wọ́ jẹ́ kí ẹ̀mí mi àti ẹ̀mí àwọn àádọ́ta ìránṣẹ́ rẹ wọ̀nyí ṣọ̀wọ́n ní ojú rẹ!
14 Aia hoi, i haule mai ke ahi mai ka lani mai, a hoopau iho la i na lunakanalima elua mamua, a me ko laua mau kanalima: ano hoi, e malamaia ko'u oia imua ou maka.
Wò ó, iná ti sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run láti jó àwọn balógun méjì àràádọ́ta àkọ́kọ́ pẹ̀lú àràádọ́ta wọn. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ní ojúrere fún ẹ̀mí mi!”
15 Olelo mai la ka anela o Iehova ia Elia, E iho oe ilalo me ia; mai makau ia ia. Ku ae la ia, a iho pu iho la me ia i ke alii.
Angẹli Olúwa sọ fún Elijah pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ pẹ̀lú rẹ̀; má ṣe bẹ̀rù rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni Elijah dìde ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ pẹ̀lú rẹ̀ sí ọ̀dọ̀ ọba.
16 I aku la oia ia ia, Ke olelo mai nei o Iehova peneia, No kou hoouna ana'ku i na elele e ninau ia Baalazebuba ke akua o Ekerona, no ka nele anei o ka Iseraela i ke Akua e ninau ai ma kana olelo? no ia mea, aole oe e iho ilalo mai kahi moe au i pii aku ai, aka, e make io no oe.
Ó sọ fún ọba pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ‘Ṣé nítorí wí pé kò sí Ọlọ́run ní Israẹli fún ọ láti pè ni ìwọ fi rán ìránṣẹ́ lọ sí ọ̀dọ̀ Baali-Sebubu, òrìṣà Ekroni láti lọ ṣe ìwádìí?’ Nítorí pé o ṣe èyí, ìwọ kò ní dìde lórí ibùsùn tí o dùbúlẹ̀ lé láìsí àní àní ìwọ yóò kú!”
17 A make iho la no ia, e like me ka Iehova olelo a Elia i olelo ai; a noho alii iho la o Iehorama ma kona hakahaka, i ka lua o ka makahiki o Iehorama ke keiki a Iehosapata ke alii o ka Iuda; no ka mea, aohe ana keiki.
Bẹ́ẹ̀ ó sì kú, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí Elijah ti sọ. Nítorí Ahasiah kò ní ọmọ, Jehoramu jẹ ọba ní ọdún kejì tí Jehoramu ọmọ Jehoṣafati ọba Juda.
18 A o na mea i koe a Ahazia ana i hana'i, aole anei i kakauia lakou iloko o ka buke oihanaalii a na'lii o ka Iseraela?
Àti ní ti gbogbo àwọn ohun tí ó ṣẹlẹ̀ nígbà ìjọba Ahasiah, àti ohun tí ó ṣe, ṣe a kò ha kọ wọ́n sí inú ìwé ọdọọdún ti àwọn ọba Israẹli?

< II Na Lii 1 >