< Ieremia 15 >

1 A LAILA, olelo mai la o Iehova ia'u, Ina i ku mai o Mose, a me Samuela imua o'u, aole no e kau ko'u manao ma keia poe kanaka. E kiola ia lakou mai ko'u alo aku, a e puka aku lakou iwaho.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé: “Kódà kí Mose àti Samuẹli dúró níwájú mi, ọkàn mi kì yóò lọ sọ́dọ̀ àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Mú wọn kúrò níwájú mi! Jẹ́ kí wọn ó lọ!
2 A ina e olelo mai lakou ia oe, Mahea makou e puka aku ai? Alaila, e olelo oe ia lakou, Ke olelo mai nei o Iehova penei, O ka poe no ka make, i ka make no; a o ka poe no ka pahikaua, i ka pahikaua no; a o ka poe no ka wi, i ka wi no; a o ka poe no ka lawepioia, i ka lawepioia no.
Tí wọ́n bá sì bi ọ́ pé, ‘Níbo ni kí a lọ?’ Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: “‘Àwọn tí a kọ ikú mọ́, sí ikú; àwọn tí a kọ idà mọ́, sí idà; àwọn tí a kọ ìyàn mọ́, sí ìyàn; àwọn tí a kọ ìgbèkùn mọ́ sí ìgbèkùn.’
3 A e hookau aku au maluna o lakou i na mea eha, wahi a Iehova; o ka pahikaua e pepehi; o na ilio e haehae; o na manu o ka lani, a me na holoholona o ka honua, e ai, a e hoopau.
“Èmi yóò rán oríṣìí ìjìyà mẹ́rin láti kọlù wọ́n,” ni Olúwa wí, “Idà láti pa, àwọn ajá láti wọ́ wọn lọ, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹranko orí ilẹ̀ láti jẹ àti láti parun.
4 A e haawi no wau e laweia lakou i na aina a pau o ka honua nei, no Manase, ke keiki a Hezekia, ke alii o ka Iuda, no ka mea ana i hana'i ma Ierusalema.
N ó sọ wọ́n di ẹni ìkórìíra níwájú gbogbo ìjọba ayé torí ohun tí Manase ọmọ Hesekiah ọba Juda ṣe ní Jerusalẹmu.
5 No ka mea, owai ka mea aloha aku ia oe, e Ierusalema? Owai ka mea kumakena ia oe? Owai auanei ka mea e huli ae, e ninau i kou noho ana?
“Ta ni yóò ṣàánú rẹ, ìwọ Jerusalẹmu? Ta ni yóò dárò rẹ? Ta ni yóò dúró béèrè àlàáfíà rẹ?
6 Ua haalele mai oe ia'u, wahi a Iehova, ua hoi hope oe. Nolaila, e kikoo ku e aku au i ko'u lima ia oe, a e luku ia oe; no ka mea, ua uluhua wau i ka mihi ana.
O ti kọ̀ mí sílẹ̀,” ni Olúwa wí, “Ìwọ sì wà nínú ìpadàsẹ́yìn. Nítorí náà, Èmi yóò dáwọ́lé ọ, èmi ó sì pa ọ́ run, Èmi kò sì ní fi ojú àánú wò ọ́ mọ́.
7 E hoolulu aku au ia lakou i ka peahi lulu ma na pukapa o ka aina; e hoonele au ia lakou i na keiki, e luku aku no au i ko'u poe kanaka; aole lakou i huli, mai ko lakou aoao mai.
Èmi kò tún lè fi ìfẹ́ hàn si ọ, Èmi yóò fi àtẹ fẹ́ wọn sí ẹnu-ọ̀nà ìlú náà. Èmi yóò mú ìṣọ̀fọ̀ àti ìparun bá àwọn ènìyàn mi nítorí pé wọn kò tí ì yípadà kúrò lọ́nà wọn.
8 E oi aku ka nui o ko lakou wahinekanemake ia'u i ko ke one o ke kai. I ke awakea, e hoopuka no au maluna o lakou, maluna hoi o ka makuwahine o ka poe ui, i poe luku. E hoopuka no au maluna ona me ka hoohikilele ka makau a me ka weliweli.
Èmi yóò jẹ́ kí àwọn opó wọn pọ̀ ju yanrìn Òkun lọ. Ní ọjọ́-kanrí ni èmi ó mú apanirun kọlu àwọn ìyá ọmọkùnrin wọn. Lójijì ni èmi yóò mú ìfòyà àti ìbẹ̀rù bá wọn.
9 Mae wale aku ka mea i hanau i na mea ehiku, e kaili ana ke ea. Ua napoo kona la i ke ao okoa; ua hilahila oia, ua hoopalaimaka hoi. A e haawi no wau i ke koena o lakou i ka pahikaua imua o ko lakou poe enemi, wahi a Iehova.
Ìyá ọlọ́mọ méje yóò dákú, yóò sì mí ìmí ìgbẹ̀yìn. Òòrùn rẹ yóò wọ̀ lọ́sàn án gangan, yóò di ẹni ẹ̀tẹ́ òun àbùkù. Èmi yóò fi àwọn tí ó bá yè síwájú àwọn ọ̀tá wọn tí idà wà lọ́wọ́ wọn,” ni Olúwa wí.
10 Auwe hoi au, e kuu makuwahine, no ka mea, ua hanau mai oe ia'u, he kanaka hakaka, he kanaka paio no ko ka honua a pau! Aole au i hoolimalima kala ma ke kuala, aole hoi i aie kala ma ke kuala; aka, ke hailiili mai nei kela mea keia mea o lakou ia'u.
Háà! Ó ṣe tí ìyá mi bí mi, ọkùnrin tí gbogbo ilẹ̀ dojúkọ tí wọ́n sì bá jà! Èmi kò wínni, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò yá lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, síbẹ̀, gbogbo ènìyàn ló ń fi mí ré.
11 I mai la o Iehova, He oiaio, e pomaikai ana kou poe i koe; oiaio, na'u no e mea aku, a e hana maikai ae ka enemi ia oe i ka manawa poino, a i ka manawa popilikia.
Olúwa sọ pé, “Dájúdájú èmi ò dá ọ sí fún ìdí kan pàtó; dájúdájú mo mú kí àwọn ọ̀tá rẹ tẹríba níwájú rẹ nígbà ibi àti ìpọ́njú.
12 Na ka hao anei e uhaki i ka hao o ke kukulu akau, a me ke keleawe?
“Ǹjẹ́ ẹnìkan lè fi ọwọ́ ṣẹ́ irin irin láti àríwá tàbí idẹ?
13 A e haawi no wau i kou waiwai, a me kou ukana, no ka hoopio me ka uku ole ia mai, a oia hoi no kou hewa a pau, a aia no ia ma kou mau mokuna a pau.
“Gbogbo ọlá àti ìṣúra rẹ ni èmi ó fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìkógun láìgba nǹkan kan nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jákèjádò orílẹ̀-èdè rẹ.
14 A na'u no e hoohele ia oe, me kou poe enemi a iloko o ka aina au i ike ole ai; no ka mea, ua hoaia ke ahi i kuu inaina, a e a no ia maluna o oukou.
Èmi yóò fi ọ́ ṣẹrú fún àwọn ọ̀tá rẹ ní ìlú tí ìwọ kò mọ̀ nítorí ìbínú mi yóò rán iná tí yóò jó ọ.”
15 E Iehova, ua ike no oe: e hoomanao mai oe ia'u, a e ike mai hoi ia'u, a e hooponopono mai oe ia'u i ka poe hoomaau mai ia'u. Mai lawe aku oe ia'u, i kou ahonui ana. E ike oe, nou no wau i kaikai ai i ka hilahila.
Ó yé ọ, ìwọ Olúwa; rántí mi kí o sì ṣe ìtọ́jú mi. Gbẹ̀san mi lára àwọn tó dìtẹ̀ mi. Ìwọ ti jìyà fún ìgbà pípẹ́, má ṣe mú mi lọ; nínú bí mo ṣe jìyà nítorí tìrẹ.
16 Ua loaa no kau mau olelo, a ai no wau ia mau mea; a lilo kau olelo ia'u i mea olioli, a i mea hoi e hauoli ai ko'u naau: no ka mea, ua kapaia wau ma kou inoa, E Iehova, ke Akua o na kaua.
Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ dé, mo jẹ wọ́n, àwọn ni ìdùnnú àti ayọ̀ ọkàn mi, nítorí pé orúkọ rẹ ni a fi ń pè mí, Ìwọ Olúwa Ọlọ́run Alágbára.
17 Aole au i noho ma ka aha o ka poe hoowahawaha, aole hoi au i olioli; noho kaawale au, no kou lima; no ka mea, ua hoopiha mai oe ia'u i ka ukiukiia.
Èmi kò fìgbà kan jókòó láàrín àwọn ẹlẹ́gàn, n ko bá wọn yọ ayọ̀ pọ̀; mo dá jókòó torí pé ọwọ́ rẹ wà lára mi, ìwọ sì ti fi ìbínú rẹ kún inú mi.
18 No ke aha la i mau ai ko'u eha, a ola ole hoi ko'u hahauia, a hoole hoi i ka hoolaia? E lilo anei oe ia'u e like loa me na wai hoopunipuni, mau ole?
Èéṣe tí ìrora mi kò lópin, tí ọgbẹ́ mi kò sì ṣe é wòsàn? Ní òtítọ́ ìwọ yóò dàbí kànga ẹ̀tàn sí mi, gẹ́gẹ́ bí ìsun tó kọ̀ tí kò sun?
19 Nolaila, ke olelo mai nei o Iehova penei, Ina hoi mai oe, alaila, e hoihoi mai no wau ia oe, a e ku no oe imua o'u: a ina e lawe aku oe i ka mea pono, mai ka mea hewa aku, alaila, e like auanei no oe me ko'u waha. E hoi mai lakou ia oe, aka, mai hoi aku oe ia lakou.
Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, “Tí o bá ronúpìwàdà, Èmi ó dá ọ padà wá kí o lè máa sìn mí; tí ó bá sọ ọ̀rọ̀ tó dára, ìwọ yóò di agbẹnusọ mi. Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí kọjú sí ọ; ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ kọjú sí wọn.
20 A e hoolilo wau ia oe i pa keleawe paa loa no keia poe kanaka; a e kaua mai no lakou ia oe, aka, aole lakou e lanakila mai maluna ou; no ka mea, owau pu no me oe, e hoola ia oe, a e hoopakele ia oe, wahi a Iehova.
Èmi fi ọ́ ṣe odi idẹ tí ó lágbára, sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí; wọn ó bá ọ jà ṣùgbọ́n wọn kò ní lè borí rẹ, nítorí pé, mo wà pẹ̀lú rẹ láti gbà ọ́ là, kí n sì dáàbò bò ọ́,” ni Olúwa wí.
21 A e hoopakele aku au ia oe, mai ka lima aku o ka poe hewa, a e hoolapanai aku au ia oe, mai loko aku o ka lima o ka poe hooweliweli.
“Èmi yóò gbà ọ́ sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ìkà ènìyàn, Èmi yóò sì rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.”

< Ieremia 15 >