< Ieremia 17 >

1 U A palapalaia ka hewa o ka Iuda, me ka peni hao, me kahi oi hoi o ka daimana; ua kahakahaia hoi ma ka papa o ko lakou naau, a ma na pepeiaohao o ke kuahu;
“Ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a fi kálámù irin kọ, èyí tí a fi ṣóńṣó òkúta adamante gbẹ́ ẹ, sórí wàláà oókan àyà wọn, àti sórí ìwo pẹpẹ yín.
2 I ka hoomanao ana o ka lakou keiki i ko lakou kuahu, a me ko lakou ululaau ma na laau uliuli maluna o na puu kiekie.
Kódà àwọn ọmọ wọn rántí pẹpẹ àti ère Aṣerah lẹ́bàá igi tí ó tẹ́ rẹrẹ àti àwọn òkè gíga.
3 E kuu mauna ma ke kula, e haawi no wau i kou waiwai, a me kou ukana a pau i pio, a me kou mau wahi kiekie i hewa, ma kou mau mokuna a pau.
Àwọn òkè nínú ilẹ̀ àti àwọn ọrọ̀ rẹ̀ àti ọlá rẹ̀ ni èmi yóò fi sílẹ̀ bí ìjẹ pẹ̀lú àwọn ibi gíga, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀ káàkiri orílẹ̀-èdè yín.
4 A o oe, e hele aku no oe, mai kou hooilina aku, ka mea a'u i haawi aku ai ia oe; a e hoolilo aku au ia oe i kauwa na kou poe enemi ma ka aina au i ike ole ai: no ka mea, ua hoa oukou i ke ahi ma kuu ukiuki, a e a mau loa aku no ia.
Láti ipasẹ̀ àìṣedéédéé yín ni ẹ̀yin yóò ti sọ ogún tí mo fún un yín nù. Èmi yóò fi yín fún ọ̀tá yín bí ẹrú ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò mọ̀, nítorí ẹ̀yin ti mú inú bí mi, èyí tí yóò sì wà títí ayé.”
5 Ke olelo mai nei o Iehova penei, E poino ana ke kanaka i hilinai i ke kanaka, a manao iho la i ka io i ikaika nona, a haalele kona naau ia Iehova.
Báyìí ni Olúwa wí: “Ègbé ni fún àwọn tí ó fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú ènìyàn, tí ó fi agbára rẹ̀ sínú ẹran-ara, àti tí ọkàn rẹ̀ kò sí lọ́dọ̀ Olúwa.
6 E like auanei ia me kahi i haaleleia maloko o ka waonahele, aole ia e ike i ka wa e hiki mai ai ka maikai; aka, e noho no oia ma na wahi maloo ma ka waonahele, ma ka aina hua ole, a noho ole ia.
Yóò dàbí igbó tí ó wà ní ilẹ̀ aláìlọ́ràá, kò ní rí ìre, nígbà tí ó bá dé, yóò máa gbé ní ibi ìyàngbẹ ilẹ̀ aginjù, ní ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé.
7 Pomaikai ke kanaka i hilinai aku ia Iehova, a o Iehova hoi kona mea e manaolana'i.
“Ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, tí ó sì fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.
8 E like auanei ia me ka laau i kanuia ma na wai, a kupu ae la kona mau aa ma kahi mau; aole hoi ia e ike i ka hiki ana mai o ka wela; aka, e uliuli no kona lau; a i ka makahiki wi, aole ia e makau, aole hoi e hooki oia i ka hoohua ana mai i ka hua.
Yóò dàbí igi tí a gbìn sí ipadò tí ó ta gbòǹgbò rẹ̀ ká etí odò kò sí ìbẹ̀rù fún un nígbà ooru, gbogbo ìgbà ni èwe rẹ̀ máa ń tutù kò sí ìjayà fún un ní ọdún ọ̀dá bẹ́ẹ̀ ni kò ní dẹ́kun láti máa so èso.”
9 He hoopunipuni ka naau mamua o na mea a pau, a ua hewa loa hoi ia; owai ka mea hiki ke hoomaopopo?
Ọkàn ènìyàn kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ, ó kọjá ohun tí a lè wòsàn. Ta ni èyí lè yé?
10 Owau, o Iehova, ke huli nei au i ka naau, ke hoao nei au i ka opu, e haawi i kela kanaka keia kanaka e like me kona mau aoao, e like hoi me ka hua o kana mau hana.
“Èmi Olúwa ń wo ọkàn àti èrò inú ọmọ ènìyàn, láti san èrè iṣẹ́ rẹ̀ fún un gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.”
11 E like me ka manu aihue i hoopunana i na hua ana i hanau ole ai; pela no ka mea i loaa ka waiwai ma ka pono ole, iwaenakonu o kona mau la, e waiho oia ia mea, a i kona hope, e lapuwale oia.
Bí àparò tó pa ẹyin tí kò yé ni ọmọ ènìyàn tí ó kó ọrọ̀ jọ ni ọ̀nà àìṣòdodo. Yóò di ẹni ìkọ̀sílẹ̀ ní agbede-méjì ayé rẹ̀, àti ní òpin rẹ̀ yóò wá di aṣiwèrè.
12 He nohoalii nani kiekie loa, mai kinohi mai, oia kahi o ko makou keenakapu.
Ìtẹ́ ògo; ibi gíga láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ní ibi ilé mímọ́ wa.
13 E Iehova, ka mea e manaolana'i o ka Iseraela, o ka poe a pau e haalele ia oe, e hilahila auanei lakou, a o ka poe e haalele ia'u, e kahakahaia lakou ma ka honua, no ka mea, ua haalele lakou ia Iehova, i ke kumu o na wai ola.
Olúwa ìwọ ni ìrètí Israẹli; gbogbo àwọn tí ó kọ̀ ọ́ sílẹ̀ ni ojú ó tì. Àwọn tí ó padà sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ ni a ó kọ orúkọ wọn sínú ekuru, nítorí wọ́n ti kọ Olúwa, orísun omi ìyè sílẹ̀.
14 E hoola mai oe ia'u, e Iehova, a e hoolaia mai no wau; e hoopakele mai oe ia'u a e hoopakeleia mai no wau; no ka mea, o oe no ka'u e kaena ai.
Wò mí sàn Olúwa, èmi yóò di ẹni ìwòsàn, gbà mí là, èmi yóò di ẹni ìgbàlà, nítorí ìwọ ni ìyìn mi.
15 Aia hoi, ke olelo mai nei lakou ia'u, Auhea ka olelo a Iehova? E hele mai ia, ano.
Wọ́n sọ fún mi wí pé: “Níbo ni ọ̀rọ̀ Olúwa wà? Jẹ́ kí ó di ìmúṣẹ báyìí.” Ni Olúwa wí.
16 Aole au i hoolalelale ia'u iho mai ka noho kahuhipa ana, e hahai mamuli ou, aole hoi au i makemake ia la kaumaha, ua ike no oe. O ka mea i puka aku iwaho o ko'u mau lehelehe, ua pololei no ia imua ou.
Èmi kò sá kúrò láti máa jẹ́ olùṣọ àgùntàn rẹ, ìwọ mọ̀ wí pé èmi kò kẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ ìpọ́njú. Ohun tí ó jáde ní ètè mi jẹ́ èyí tí ó hàn sí ọ.
17 Mai lilo oe i mea makau no'u; o oe no ko'u mea e manaolana'i, i ka la o ka hewa.
Má ṣe di ìbẹ̀rù fún mi, ìwọ ni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú.
18 E hoohilahilaia ka poe hoomaau mai ia'u, mai hookuu ia'u i ka hoohilahilaia. E hoopilihua ia lakou, mai hookuu ia'u i ka hoopilihuaia. E lawe mai oe maluna o lakou i ka la o ka hewa, a e luku hoi oe ia lakou i ka luku papalua.
Jẹ́ kí ojú ti àwọn ẹni tí ń lépa mi, ṣùgbọ́n pa mí mọ́ kúrò nínú ìtìjú, jẹ́ kí wọn kí ó dààmú. Mú ọjọ́ ibi wá sórí wọn, fi ìparun ìlọ́po méjì pa wọ́n run.
19 Ke olelo mai nei o Iehova ia'u penei, O hele, e ku ma ka pukapa o na keiki a ko'u poe kanaka, kahi e komo mai ai na'lii o ka Iuda, ma kahi hoi e puka aku ai lakou iwaho, a ma na pukapa a pau hoi o Ierusalema;
Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ dúró ní ẹnu-ọ̀nà àwọn ènìyàn níbi tí àwọn ọba Juda ń gbà wọlé tí wọ́n ń gbà jáde àti ní gbogbo ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
20 A e i aku ia lakou, E hoolohe oukou i ka olelo a Iehova, e na'lii o ka Iuda, a me ka Iuda a pau, a me ka poe a pau e noho ana ma Ierusalema, ka poe komo iloko, ma keia mau pukapa.
Sọ fún wọ́n pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba Juda àti gbogbo ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé ní Jerusalẹmu tí ń wọlé láti ẹnu ibodè yìí.
21 Ke olelo mai nei o Iehova penei, E malama oukou i ko oukou kino iho; mai halihali oukou i ka mea halihali i ka la Sabati, aole hoi e lawe mai iloko, ma na pukapa o Ierusalema.
Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ kíyèsi láti máa ru ẹrù lọ́jọ́ ìsinmi tàbí kí ẹ gbé wọlé láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.
22 Mai lawe aku hoi i ka haawe mawaho aku o ko oukou mau hale i ka la Sabati; mai hana hoi i kekahi hana; aka, e hoano oukou i ka la Sabati, me au i kauoha aku ai i ko oukou poe kupuna.
Má ṣe gbé ẹrù jáde kúrò nínú ilé yín, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ṣùgbọ́n kí ẹ pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ fún àwọn baba ńlá yín.”
23 Aole lakou i hoolohe, aole hoi i haliu mai i ko lakou mau pepeiao, aka, hooolea lakou i ko lakou a-i i mea e lohe ole ai lakou, i mea hoi, e loaa ole ai ia lakou ka naauao.
Síbẹ̀ wọn kò gbọ́ tàbí tẹ́tí sílẹ̀, wọ́n jẹ́ ọlọ́rùn líle; wọn kì í fẹ́ gbọ́ tàbí gba ìbáwí.
24 A ina e hoolohe pono mai oukou ia'u, wahi a Iehova, a lawe ole i ka mea lawe maloko o na pukapa o ke kulanakauhale i ka la Sabati: aka, hoano oukou i ka la Sabati, a hana ole i kekahi hana ia la;
Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kíyèsi láti gbọ́ tèmi ní Olúwa wí, tí ẹ kò sì gbe ẹrù gba ẹnu-bodè ìlú ní ọjọ́ ìsinmi, ṣùgbọ́n tí ẹ ya ọjọ́ ìsinmi, sí mímọ́, nípa pé ẹ kò ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà.
25 Alaila, e komo mai no iloko o na pukapa o keia kulanakauhale, na'lii, a me na luna, e noho ana ma ka nohoalii o Davida, e holo ana hoi maloko o na halekaa, a maluna o na lio, o lakou, a me ko lakou luna, o na kanaka o ka Iuda, a me ka poe noho ma Ierusalema; a e hoomau loa ia aku no keia kulanakauhale.
Nígbà náà ni ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba ẹnu ibodè wọlé pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀. Àwọn àti ìjòyè wọn yóò gun ẹṣin àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wá, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu yóò tẹ̀lé wọn; ìlú yìí yóò sì di ibi gbígbé títí láéláé.
26 A e hele mai no lakou, mai na kulanakauhale o ka Iuda mai, a no na wahi mawaho o Ierusalema a puni, a mai ka aina o Beniamina mai, a mai na papu mai, a mai na mauna mai, a mai ke kukuluhema mai, e lawe ana i na mohnikuni, a me na alana, a me na mohai makana, a me ka mea ala, e lawe ana hoi i na mea aloha, a i ka hale o Iehova.
Àwọn ènìyàn yóò wá láti ìlú Juda àti ní agbègbè Jerusalẹmu, láti ilẹ̀ Benjamini, láti pẹ̀tẹ́lẹ̀, àti láti òkè, àti láti gúúsù wá, wọn yóò wá pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, àti ọrẹ ẹran, àti tùràrí, àti àwọn tó mú ìyìn wá sí ilé Olúwa.
27 Aka, ina aole oukou e hoolohe mai ia'u, e hoano i ka la Sabati, a e lawe ole hoi i ka mea lawe, e komo ana hoi iloko ma na pukapa o Ierusalema i ka la Sabati; alaila, e hoa no wau i ke ahi ma kona mau pukapa, a e hoopau no ia i na hale alii o Ierusalema, aole hoi ia e kinaiia.
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá pa òfin mi mọ́ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́, kí ẹ má sì ṣe ru ẹrùkẹ́rù bí ẹ̀yin yóò ṣe máa gba ẹnu ibodè Jerusalẹmu wọlé ní ọjọ́ ìsinmi, nígbà náà ni èmi yóò da iná tí kò ní ṣe é parun ní ẹnu-bodè Jerusalẹmu tí yóò sì jó odi agbára rẹ̀.’”

< Ieremia 17 >