< Oihanakahuna 15 >

1 OLELO mai la hoi o Iehova ia Mose a me Aarona, i mai la,
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
2 E olelo olua i na mamo a Iseraela, e i aku ia lakou, O ke kanaka, he mai kahe mailoko aku o kona io; e haumia no ia, no kona hilo.
“Ẹ bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, kí ẹ wí fún wọn pé, ‘Bí ìsunjáde bá ń jáde lára ọkùnrin kan lójú ara, ìsunjáde náà jẹ́ àìmọ́.
3 O kona haumia no ia iloko o kono hilo; ina e kahe ana kona io i kona hilo, a ina i paa paha kona io, aole kahe i kona hilo, o kona haumia no ia.
Yálà ó ń jáde léraléra tàbí ó dúró, èyí yóò sọ ọ́ di aláìmọ́. Báyìí ni ìsunjáde rẹ̀ ṣe le è sọ ọ́ di aláìmọ́:
4 O kela moe keia moe a ka mea hilo e moe ai maluna iho, e haumia no ia; a o ka mea ana e noho ai maluna iho, e haumia no ia.
“‘Gbogbo ibùsùn tí irú ẹni tí ó ní ìsunjáde náà bá sùn di àìmọ́.
5 A o ka mea i pai kona moe, e holoi oia i kona mau kapa, a e auau i ka wai, a e haumia a hiki i ke ahiahi.
Bí ẹnikẹ́ni bá fi ara kan ibùsùn rẹ̀, ó gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀. Yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
6 O ka mea e noho ma ka mea a ka mea hilo i noho ai, e auau oia i ka wai, a e haumia ia a hiki i ke ahiahi.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá jókòó lórí ohunkóhun tí ọkùnrin tí ó ní ìsunjáde bá jókòó le gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, kí ó sì wà láìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
7 A o ka mea i pa i ka io o ka mea hilo, e holoi oia i kona kapa, a e auau i ka wai, a e haumia a hiki i ke ahiahi.
“‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ọkùnrin náà tí ó ní ìsunjáde gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
8 A ina e kuha ka mea hilo maluna o ka mea maemae; alaila e holoi oia i kona mau kapa, a e auau i ka wai, a e haumia a hiki i ke ahiahi.
“‘Bí ẹni tí ó ní ìsunjáde bá tu itọ́ sí ẹni tí ó mọ́ lára, ẹni tí ó mọ́ náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
9 A o ka noho lio a ka mea hilo e holo ai, e haumia ia.
“‘Gàárì ẹranko tí ẹni náà bá gùn yóò di àìmọ́.
10 A o ka mea i pa i kekahi mea malalo oua, e haumia ia a hiki i ke ahiahi; a o ka mea e hali i kauwahi o ia mau mea, e holoi oia i kona mau kapa, a e auau hoi i ka wai, a e haumia no a hiki i ke ahiahi.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí ó wà lábẹ́ ọkùnrin náà di aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́. Ẹnikẹ́ni tí ó bá mú irú nǹkan bẹ́ẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó wẹ ara rẹ̀. Yóò sì jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
11 A o ka mea a ka mea hilo e hoopa aku ai, aole hoi i holoi kona lima i ka wai, e holoi oia i kona mau kapa, a e auau i ka wai, a e haumia hoi ia a hiki i ke ahiahi.
“‘Ẹnikẹ́ni tí ọkùnrin tí ó ní ìsunjáde ní ara rẹ̀ bá fi ara kàn láìfi omi fọ ọwọ́ rẹ̀, gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀. Yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
12 A o ka ipu lepo a ka mea hilo i pa ai, e wawahiia ia; a o na ipu laau, e holoiia ia i ka wai.
“‘Ìkòkò amọ̀ tí ọkùnrin náà bá fọwọ́ kàn ni kí ẹ fọ́, gbogbo ohun èlò igi tí ó fọwọ́ kàn ni kí ẹ fi omi sàn.
13 A i ka wa e maemae ai ka mea hilo i kona hilo, alaila e hela oia nona i na la ehiku no kona hoomaomaeia'na, a e holoi i kona mau kapa, a o hoauau i kona io i ka wai kahe, a e maemae hoi ia.
“‘Ẹnikẹ́ni tí a bá wẹ̀nù kúrò nínú ìsunjáde rẹ̀ gbọdọ̀ ka ọjọ́ méje fún àwọn ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́: kí ó fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì fi omi wẹ ara rẹ̀, yóò sì di mímọ́.
14 A i ka walu o ka la, e lawe oia nona i na kuhukuku elua, a i ole ia, i elua manu nunu opiopio, a e hele mai imua o ke alo o Iehova, ma ka puka o ka halelewa o ke anaina, a e haawi ia mau mea i ke kahuna.
Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àdàbà méjì tàbí ọmọ ẹyẹlé méjì, kí ó sì wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé níwájú Olúwa, kí ó sì kó wọn fún àlùfáà.
15 A e kaumaha aku ke kahuna ia mau mea, hookahi i mohailawehala, a i kekahi i mohaikuni; a e hana ke kahuna i kalahala nona ma ke alo o Iehova, no kona hilo.
Kí àlùfáà fi wọ́n rú ẹbọ: ọ̀kan fún ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ọrẹ ẹbọ sísun níwájú Olúwa ní ipò ọkùnrin náà nítorí ìsunjáde rẹ̀.
16 A ina e puka aku ka anoano o ke kanaka mailoko aku ona, alaila e holoi oia i kona kino okoa i ka wai, a e haumia hoi a hiki i ke ahiahi.
“‘Bí nǹkan ọkùnrin kan bá tú jáde, kí ó wẹ gbogbo ara rẹ̀, kí ó wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
17 A o ke kapa, a o ka ili, he anoano kanaka maluna iho, e holoiia ia i ka wai, a e haumia hoi a hiki i ke ahiahi.
Yálà àwọ̀ tàbí aṣọ tí nǹkan ọkùnrin bá dà sí lórí ni kí ẹ fọ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ di ìrọ̀lẹ́.
18 A o ka wahine hoi a ke kanaka i moe aku ai, me ka anoano, e auau no laua i ka wai, a e haumia hoi a hiki i ke ahiahi.
Bí ọkùnrin kan bá bá obìnrin lòpọ̀ tí nǹkan ọkùnrin sì tú jáde lára rẹ̀. Àwọn méjèèjì gbọdọ̀ fi omi wẹ̀, kí wọ́n sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
19 A ina he mai kahe ko ka wahine, a he koko ka mea kahe o kona io, e hookaawaleia'e oia i na la ehiku; a o ka mea i hoopa ia ia, e haumia oia a hiki i ke ahiahi.
“‘Bí obìnrin bá ń ṣe nǹkan oṣù rẹ̀, obìnrin yìí wà ní àìmọ́ títí di ọjọ́ méje. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn án yóò wà ní ipò àìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.
20 A o ka mea ana e moe ai maluna iho, i kona kaawale ana, e haumia ia; a o ka mea ana e noho ai maluna iho, e haumia no ia.
“‘Gbogbo ohun tí ó bá sùn lé ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ di àìmọ́.
21 O ka mea i pa i kona wahi moe, e holoi oia i kona mau kapa, a e auau i ka wai, a e haumia hoi ia a hiki i ke ahiahi.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ibùsùn rẹ̀ gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
22 O ka mea hoi i pa i ka mea ana i noho ai maluna iho, e holoi no hoi oia i kona mau kapa, a e auau i ka wai, a e haumia hoi a hiki i ke ahiahi.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí ó bá jókòó lé gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀, yóò sì wà ní ipò àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
23 Ina hoi he mea maluna o ka moe, a maluna o kahi ana i noho ai maluna iho, aia pa aku ke kanaka ia, e haumia ia a hiki i ke ahiahi.
Ìbá à ṣe ibùsùn tàbí ohunkóhun tí ó jókòó lé. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn án yóò jẹ́ aláìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
24 A ina e moe ke kanaka me ia a pili kona koko ia ia, a haumia no ia i na la ehiku; a o ka moe a pau a ia kanaka i moe ai maluna iho, e haumia ia.
“‘Bí ọkùnrin kan bá bá a lòpọ̀, tí nǹkan oṣù rẹ̀ sì kàn án lára, yóò jẹ́ aláìmọ́ fún ọjọ́ méje, gbogbo ibùsùn tí ọkùnrin náà bá sùn yóò jẹ́ aláìmọ́.
25 A ina he heekoko ko ka wahine i na la he nui mawaho o ka wa o kona kaawale ana, a ina e kahe hou no ia mahope o ka pau ana o kona wa kaawale, e like no hoi na la a pau o kona haumia me na la o kona kaawale ana, e haumia no ia.
“‘Bí obìnrin bá ní ìsun ẹ̀jẹ̀ fún ọjọ́ púpọ̀ yálà sí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀ tàbí tí nǹkan oṣù rẹ̀ bá kọjá ìgbà tí ó yẹ. Gbogbo ìgbà tí ó bá fi ń ní ìsun ẹ̀jẹ̀ náà ni yóò fi wà ní àìmọ́ gẹ́gẹ́ bí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀.
26 O kela moe keia moe ana e moe ai i na la a pau o kona heekoko ana, e like no ia ia ia me ka moe o kona kaawale ana; a o ka mea ana i noho ai maluna iho, e haumia ia, e like me ka haumia o kona kaawale ana.
Ibùsùn tí ó wù kí ó sùn sí ní gbogbo ìgbà tí ẹ̀jẹ̀ náà ń wá yóò jẹ́ àìmọ́ bí ibùsùn rẹ̀ ṣe jẹ́ ní àkókò nǹkan oṣù rẹ̀. Gbogbo ohun tí ó bá jókòó lé yóò wà ní àìmọ́, gẹ́gẹ́ bí àkókò nǹkan oṣù rẹ̀.
27 A o ka mea i pa ia mau mea, e haumia no ia, a e holoi i kona mau kapa, a e auau i ka wai, a e haumia hoi a hiki i ke ahiahi.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́ kàn wọ́n yóò wà ní àìmọ́. Ó gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ̀ kí ó sì wà ní àìmọ́ títí di ìrọ̀lẹ́.
28 Aka ina i hoomaemaeia oia i kona heekoko ana, alaila e helu oia nona i na la ehiku, a mahope iho e maemae no ia.
“‘Nígbà tí ó bá di mímọ́ kúrò nínú ìsun rẹ̀, kí ó ka ọjọ́ méje lẹ́yìn náà, a ó kà á sí mímọ́.
29 A i ka walu o ka la, e lawe oia nana i elua kuhukuku, a i ole ia, i elua manu nunu opiopio, a e hali mai i ke kahuna ma ka puka o ka halelewa o ke anaina.
Ní ọjọ́ kẹjọ kí ó mú àdàbà méjì àti ọmọ ẹyẹlé wá síwájú àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
30 A e kaumaha aku ke kahuna i kekahi i mohailawehala, a o kekahi i mohaikuni; a e hana ke kahuna i kalahala nona imua o Iehova no kona heekoko haumia.
Kí àlùfáà fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun. Báyìí ni yóò ṣe ètùtù fún un, níwájú Olúwa fún àìmọ́ ìsun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
31 Pela e hookaawale ai oukou i na mamo a Iseraela mai ko lakou haumia ana, i ole ai lakou e make iloko o ko lakou haumia, i ko lakou hoohaumia ana i kuu halelewa iwaena o lakou.
“‘Ẹ ya ará Israẹli sọ́tọ̀ kúrò nínú ohun tí ó ń sọ wọ́n di aláìmọ́, kí wọ́n má bá a kú nínú àìmọ́ wọn nípa bíba ibùgbé mímọ́ mi jẹ́, èyí tí ó wà láàrín wọn.’”
32 Oia ke kanawai no ka mea hilo, a no ka mea ua puka mailoko ae ona kona anoano i haumia ai oia;
Ìwọ̀nyí ni àwọn òfin fún ọkùnrin tí ó ni ìsunjáde fún ẹnikẹ́ni tí a sọ di àìmọ́ nípa ìsunjáde nǹkan ọkùnrin rẹ̀.
33 A no ka wahine mai heekoko hoi, a me ka mea hilo; o ke kanaka, a o ka wahine, a me ka mea moe me ka wahine haumia.
Fún obìnrin ní nǹkan oṣù rẹ̀, fún ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó ní ìsunjáde, àti fún ọkùnrin tí ó ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin tí ó jẹ́ aláìmọ́.

< Oihanakahuna 15 >