< Oihanakahuna 23 >

1 OLELO mai la hoi o Iehova ia Mose, i mai la,
Olúwa sọ fún Mose wí pé,
2 E olelo aku i na mamo a Iseraela, a e i aku ia lakou, o na ahaaina a oukou e kala ai he mau houluulu hoano, no'u no ia mau ahaaina.
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ìwọ̀nyí ni àwọn àjọ̀dún tí a yàn, àwọn àjọ̀dún ti Olúwa èyí tí ẹ gbọdọ̀ kéde gẹ́gẹ́ bí àjọ̀dún tí a yàn.
3 I na la eono, e hanaia'i ka hana, aka o ka hiku o ka la, he Sabati e hoomaha'i ia, he houluulu hoano: aole oukou e hana: he Sabati ia no Iehova maloko o ko oukou mau hale a pau.
“‘Ọjọ́ mẹ́fà ni ẹ le fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje ni ọjọ́ ìsinmi. Ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn. Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé. Ọjọ́ ìsinmi Olúwa ni.
4 Eia na ahaaina a Iehova, na houluulu hoano a oukou e kala ai i ko lakou wa pono.
“‘Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọdún tí Olúwa yàn, àjọ̀dún tí a yàn tí ẹ gbọdọ̀ kéde lákokò wọn.
5 I ka la umikumamaha o ka malama mua, i ke ahiahi, ilaila ka moliaola a Iehova.
Àjọ ìrékọjá Olúwa bẹ̀rẹ̀ ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní.
6 A i ka la umikumamalima o ia malama no, ka ahaaina o ka berena huole, no Iehova; ehiku la e ai ai oukou i ka berena huole.
Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ni àjọ̀dún àkàrà àìwú tí Olúwa yó bẹ̀rẹ̀, fún ọjọ́ méje ni ẹ gbọdọ̀ fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà.
7 I ka la mua, he houluulu hoano ko oukou, aole oukou e hana i ka hana e luhi ai ilaila:
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní kí àpéjọ mímọ́ kí ó wà; ẹ́yin kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ agbára kankan nínú rẹ̀.
8 Aka e kaumaha oukou i ka mohai puhi ia Iehova i na la ehiku: a i ka hiku o ka la, he houluulu hoano, aole oukou e hana i ka hana e luhi ai.
Ọjọ́ méje ni kí ẹ fi mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa. Ní ọjọ́ keje, ẹ pe ìpàdé àjọ mímọ́, ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan.’”
9 Olelo mai la hoi o Iehova ia Mose, i mai la,
Olúwa sọ fún Mose pe,
10 E olelo aku i na mamo a Iseraela, a e i aku ia lakou, Aia komo oukou i ka aina a'u e haawi aku ai ia oukou, a okioki hoi i ka ai ona, alaila e lawe mai oukou i ka pua hua mua o ka oukou ai i ke kahuna.
“Sọ fún àwọn ará Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí èmi yóò fún yín, tí ẹ bá ń ṣe ìkórè, kí ẹ mú síírí ọkà àkọ́kọ́ tí ẹ kórè wá fún àlùfáà.
11 A e hoali ae oia i ka pua imua i ke alo o Iehova, e maliuia'i ia no oukou: i ka la e noa ai ka Sabati, e hoali ai ke kahuna.
Kí ó fi síírí ọkà náà níwájú Olúwa, kí ó le jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín: kí àlùfáà fì í ní ọjọ́ kejì ìsinmi.
12 A e kaumaha oukou ia la o oukou i hooluli ai i ka pua, i keikihipakane kina ole o ka makahiki hookahi, i mohaikuni no Iehova.
Ní ọjọ́ tí ẹ bá fi síírí ọkà náà, kí ẹ mú ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan láìní àbùkù rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
13 A o kona mohai ai, elua hapa umi dila o ka palaoa wali i hui pu me ka aila, he mohai puhi no Iehova, i mea ala ono: a o kona mohai inu, he waina, he hapa ha o ka hina.
Pẹ̀lú ọrẹ ọkà rẹ tí ó jẹ́ ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n efa (èyí jẹ́ lita mẹ́rin ààbọ̀) ti ìyẹ̀fun, tí a fi òróró pò ọrẹ tí a fi iná ṣe fún Olúwa òórùn dídùn pẹ̀lú ọrẹ ohun mímu rẹ̀ tí í ṣe ìdámẹ́rin òsùwọ̀n hínì (èyí jẹ́ lita kan).
14 A o ka berena, a o ka hua palaoa moa, a o ka hua maka, aole oukou e ai a hiki i ka la i lawe mai ai oukou i ka mohai i ko oukou Akua; he kanawai mau loa ia i ko oukou mau hanauna, iloko o ko oukou mau hale a pau loa,
Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ àkàrà kankan tàbí kí ẹ sun ọkà tuntun títí di ọjọ́ tí ẹ fi mú ọrẹ yín wá fún Ọlọ́run yín. Èyí ni ìlànà ayérayé fún ìran tí ń bọ̀, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé.
15 A e helu oukou no oukou iho mai ka la e noa ai ka Sabati, mai ka la i lawe mai ai oukou i ka pua i mohai hoali; ehiku Sabati e pau ai.
“‘Ẹ ka ọ̀sẹ̀ méje gbangba, láti ọjọ́ kejì ọjọ́ ìsinmi, àní ọjọ́ tí ẹ mú ìdì ọkà fífì wá.
16 A hiki i ka la e noa ai ka Sabati ahiku, e helu ai oukou i na la he kanalima, a e haawi hou i mohaiai hou ia Iehova.
Ẹ ka àádọ́ta ọjọ́ títí dé ọjọ́ kejì ọ̀sẹ̀ méjèèje, kí ẹ sì mú ọrẹ ọkà tuntun wá fún Olúwa.
17 E lawe mai hoi oukou i elua popo berena hooluli elua hapa umi dila, he palaoa wali ia, e hoomoaia ia me ka hu; he mau hua mua ia no Iehova.
Láti ibikíbi tí ẹ bá ń gbé, ẹ mú ìṣù àkàrà méjì tí a fi òsùwọ̀n ìdá méjì nínú mẹ́wàá tí efa (èyí jẹ́ lita mẹ́rin ààbọ̀) ti ìyẹ̀fun, tí a fi ìwúkàrà ṣe, gẹ́gẹ́ bí ọrẹ fífì àkọ́so sí Olúwa.
18 A e kaumaha oukou me ka berena, i ehiku keikihipa kina ole o ka makahiki mua, a i hookahi bipikane opiopio, a i elua hipakane: e lilo ia i mohaikuni no Iehova, me ko lakou mohai ai, me ko lakou mohai inu, he alana e kaumahaia ma ke ahi, he mea ala ono no Iehova.
Ẹ fi akọ ọ̀dọ́-àgùntàn méje ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan tí kò ní àbùkù, ọmọ màlúù kan àti àgbò méjì kún àkàrà yìí, wọn yóò jẹ́ ẹbọ sísun sí Olúwa, pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu wọn, àní ẹbọ tí a fi iná ṣe, olóòórùn dídùn ni sí Olúwa.
19 Alaila e kaumaha oukou i hookahi keikikao, i mohailawehala, a i elua keikihipa o ka makahiki mua, i alana o ua mohaihoomalu.
Lẹ́yìn náà kí ẹ fi akọ ewúrẹ́ kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àti ọ̀dọ́-àgùntàn méjì ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan fún ọrẹ àlàáfíà.
20 A e hoali ke kahuna ia mau mea me ka berena o na hua mua i mohai hoali ma ke alo o Iehova, me na keikihipa elua: e laa ia no Iehova na ke kahuna.
Kí àlùfáà fi ọ̀dọ́-àgùntàn méjèèjì náà níwájú Olúwa bí i ọrẹ fífì pẹ̀lú oúnjẹ àkọ́so wọn jẹ́ ọrẹ mímọ́ sí Olúwa fún àlùfáà.
21 E hai aku oukou ia la i'houluulu hoano no oukou: aole oukou e hana i ka hana e luhi ai. He kanawai mau loa iloko o ko oukou mau hale a pau, i ko oukou mau hanauna.
Ní ọjọ́ yìí náà ni kí ẹ kéde ìpàdé àjọ mímọ́: ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀ níbi yówù tí ẹ ń gbé.
22 Aia e okioki oukou i ka ai o ko oukou aina, mai oki loa i na kihi o kau mahinaai, i kou oki ana. aole hoi oe e ohi i na haulena o kau ai: e waiho no oe pela na ka poe ilihune, a na ka malihini; owau no Iehova ko oukou Akua.
“‘Nígbà tí ẹ bá kórè ilẹ̀ yín ẹ má ṣe kórè dé ìkangun oko yín, tàbí kí ẹ padà gé èyí tí ó ṣẹ́kù sílẹ̀ nínú ìkórè yín. Ẹ fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn tálákà àti àwọn àlejò. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
23 Olelo mai la hoi o Iehova ia Mose, i mai la,
Olúwa sọ fún Mose pé,
24 E olelo aku oe i na mamo a Iseraela, penei, I ka hiku o ka malama, i ka la mua o ka malama, he Sabati ko oukou, he la laa e hookani ai i na pu, he houluulu hoano:
“Sọ fún àwọn ará Israẹli, ‘Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù keje, kí ẹ ní ọjọ́ ìsinmi, ìpàdé àjọ mímọ́ tí a fi fèrè fífọn ṣe ìrántí.
25 Mai hana i ka hana e luhi ai, aka e kaumaha i ka mohai puhi ia Iehova.
Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ ojúmọ́, ṣùgbọ́n ẹ mú ọrẹ tí a fi iná sun wá síwájú Olúwa.’”
26 Olelo mai la hoi o Iehova ia Mose, i mai la,
Olúwa sọ fún Mose pé,
27 A i ka umi o ka la o ua malama ahiku nei, he la kalahala; he houluulu hoano ia no oukou, a e hookaumaha oukou i ko oukou mau uhane, a e kaumaha i ka mohai puhi ia Iehova.
“Ọjọ́ kẹwàá oṣù keje yìí ni ọjọ́ ètùtù. Ẹ ni ìpàdé àjọ mímọ́, kí ẹ sì ṣẹ́ ara yín kí ẹ sì mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa.
28 Aole hana a oukou e hana'i i ua la la; no ka mea, he la kalahala ia, e hana'i i kalahala no oukou ma ke alo o Iehova ko oukou Akua.
Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ kankan ní ọjọ́ náà, torí pé ọjọ́ ètùtù ni, nínú èyí tí a ń ṣe ètùtù fún yín níwájú Olúwa Ọlọ́run yín.
29 O kela uhane keia uhane i hookaumaha ole ia i ua la la, e okiia'ku ia maiwaena aku o kona poe kanaka.
Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣẹ́ ara rẹ̀ ní ọjọ́ náà ni a ó gé kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
30 A o kela kanaka keia kanaka e hana i ka hana i ua la la, o ia kanaka ka'u e hooki aku ai maiwaena aku o kona poe kanaka.
Èmi yóò pa ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣiṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà run kúrò láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
31 Mai hana iki oukou i ka hana: he kanawai mau loa i ko oukou mau hanauna iloko o ko oukou mau hale a pau.
Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan rárá. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀, níbikíbi tí ẹ bá ń gbé.
32 E lilo ia i Sabati e hoomaha ai, a e hookaumaha oukou i ko oukou mau uhane; i ka iwa o ka la o ka malama, i ke ahiahi, mai ke ahiahi a hiki i ke ahiahi, e malama ai oukou i ko oukou Sabati.
Ọjọ́ ìsinmi ni fún un yín, ẹ gbọdọ̀ ṣẹ́ ara yín, láti ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹsànán oṣù náà, títí di ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ tí ó tẹ̀lé e, ni kí ẹ fi sinmi.”
33 Olelo mai la hoi o Iehova ia Mose, i mai la,
Olúwa sọ fún Mose pé,
34 E olelo aku oe i na mamo a Iseraela, penei, I ka la umikumamalima o ua malama ahiku nei, he ahaaipa kauhalelewa i na la ehiku no Iehova.
“Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù keje ni kí àjọ̀dún ọdún àgọ́ ti Olúwa bẹ̀rẹ̀ kí ó sì wà títí di ọjọ́ méje.
35 I ka la mua, he houluulu hoano, mai hana oukou i ka hana e luhi ai.
Ọjọ́ kìn-ín-ní jẹ́ ọjọ́ ìpàdé mímọ́, ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ ojúmọ́.
36 I na la ehiku e kaumaha ai oukou i ka mohai puhi ia Iehova: i ka walu o ka la he houluulu hoano ia oukou, a e kaumaha oukou i ka mohai puhi ia Iehova, he anaina hoano, aole hoi oukou e hana i ka hana e luhi ai.
Ọjọ́ méje ni kí ẹ fi mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá, ní ọjọ́ kẹjọ, ẹ pe ìpàdé mímọ́ kí ẹ sì mú ọrẹ tí a fi iná ṣe wá fún Olúwa, èyí jẹ́ ìpàdé tí ó gbẹ̀yìn; ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́ ojoojúmọ́.
37 Oia na ahaaina a Iehova, a oukou e hai aku ai he mau houluulu hoano, e kaumaha ai i ka mohai puhi ia Iehova, i ka mohaikuni, i ka mohaiai, i ka alana a me na mohaiinu, kela mea keia mea i kona la iho:
(“‘Ìwọ̀nyí ni àwọn àjọ̀dún tí Olúwa ti yàn tí ẹ gbọdọ̀ kéde gẹ́gẹ́ bí i àjọ̀dún tí a yàn fún mímu àwọn ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa wá—ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà, ọrẹ ẹbọ àti ọrẹ ohun mímu, fún ọjọ́ kọ̀ọ̀kan.
38 Okoa na Sabati o Iehova; okoa hoi ko oukou mea haawi; okoa hoi ka oukou mau mea hoohiki a pau; okoa hoi ka oukou mau mohai na ka makemake, a oukou e haawi wale ia Iehova.
Àwọn ọrẹ wọ̀nyí wà ní àfikún pẹ̀lú àwọn ọrẹ ọjọ́ ìsinmi Olúwa, àti pẹ̀lú ẹ̀bùn yín àti ohunkóhun tí ẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ àti gbogbo ọrẹ àtinúwá yín fún Olúwa.)
39 A i ka la umikumamalima o ka malama ahiku, aia houluulu oukou i ka hua o ka aina, e ahaaina oukou no Iehova i na la ehiku; i ka la mua, he Sabati, a i ka la awalu, he Sabati.
“‘Torí náà, bẹ̀rẹ̀ láti ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù keje lẹ́yìn ìgbà tí ẹ ti kórè ilẹ̀ náà, ẹ ṣe àjọ̀dún yìí fún Olúwa ní ọjọ́ méje. Ọjọ́ kìn-ín-ní jẹ́ ọjọ́ ìsinmi, ọjọ́ kẹjọ pẹ̀lú si tún jẹ́ ọjọ́ ìsinmi.
40 E lawe hoi oukou no oukou iho i ka la mua i na lala o na laau maikai, i na lala o na laau pama, a me na lala o na laau momona, a me na wilou o ke kahawai; a e hauoli ae oukou ma ke alo o Iehova ko oukou Akua i na la ehiku.
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, kí ẹ mú àṣàyàn èso láti orí igi dáradára, imọ̀ ọ̀pẹ, àti ẹ̀ka igi tó rúwé, àti igi wílò odò, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín fún ọjọ́ méje.
41 E malama oukou ia i ahaaina no. Iehova, i na la ehiku o ka makahiki; he kanawai mau loa i ko oukou mau hanauna; i ka hiku o ka malama e ahaaina ai oukou ia.
Ẹ ṣe èyí ní àjọ̀dún sí Olúwa fún ọjọ́ méje lọ́dọọdún. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀, ẹ ṣe é ní oṣù keje.
42 E noho oukou iloko o na halelalalaau i na la ehiku; o na mea a pau i hanau he poe Iseraela, e noho no lakou iloko o ua halelalalaau:
Ẹ gbé inú àgọ́ fún ọjọ́ méje. Kí gbogbo ọmọ bíbí Israẹli gbé nínú àgọ́.
43 I ike ko oukou mau hanauna, ua hoonoho au i na mamo a Iseraela iloko o na halelalalaan, i ka wa i lawe mai ai au ia lakou mai ka aina mai o Aigupita: owau no Iehova ko oukou Akua.
Kí àwọn ìran yín le mọ̀ pé mo mú kí Israẹli gbé nínú àgọ́, nígbà tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
44 A hai aku la o Mose i na ahaaina a Iehova i na mamo a Iseraela.
Báyìí ni Mose kéde àwọn àjọ̀dún tí a yàn Olúwa fún àwọn ọmọ Israẹli.

< Oihanakahuna 23 >