< Salmi 91 >

1 CHI dimora nel nascondimento dell'Altissimo, Alberga all'ombra dell'Onnipotente.
Ẹni tí ó gbé ibi ìkọ̀kọ̀ Ọ̀gá-ògo ni yóò sinmi ní ibi òjìji Olódùmarè.
2 Io dirò al Signore: [Tu sei] il mio ricetto e la mia fortezza; Mio Dio, in cui mi confido.
Èmi yóò sọ nípa ti Olúwa pé, “Òun ni ààbò àti odi mi, Ọlọ́run mi, ẹni tí èmi gbẹ́kẹ̀lé”.
3 Certo egli ti riscoterà dal laccio dell'uccellatore, Dalla pestilenza mortifera.
Nítòótọ́ òun yóò gbà mí nínú ìdẹ̀kùn àwọn pẹyẹpẹyẹ àti nínú àjàkálẹ̀-ààrùn búburú.
4 Egli ti farà riparo colle sue penne, E tu ti ridurrai in salvo sotto alle sue ale; La sua verità [ti sarà] scudo e targa.
Òun yóò fi ìyẹ́ rẹ̀ bò mí, àti ni abẹ́ ìyẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò ti rí ààbò; òtítọ́ rẹ̀ ni yóò ṣe ààbò àti odi mi.
5 Tu non temerai di spavento notturno, [Nè] di saetta volante di giorno;
Ìwọ kì yóò bẹ̀rù nítorí ẹ̀rù òru, tàbí fún ọfà tí ń fò ní ọ̀sán,
6 [Nè] di pestilenza [che] vada attorno nelle tenebre; [Nè] di sterminio [che] distrugga in [pien] mezzodì.
tàbí fún àjàkálẹ̀-ààrùn tí ń rìn kiri ní òkùnkùn, tàbí fún ìparun tí ń rìn kiri ní ọ̀sán gangan.
7 Mille te [ne] caderanno al lato [manco], E diecimila al destro; [E pur quello] non ti aggiungerà.
Ẹgbẹ̀rún yóò ṣubú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ, ṣùgbọ́n kì yóò súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ.
8 Sol riguarderai con gli occhi, E vedrai la retribuzione degli empi,
Ìwọ yóò máa wò ó pẹ̀lú ojú rẹ àti wo ìjìyà àwọn ẹni búburú.
9 Perciocchè, o Signore, tu [sei] il mio ricetto; Tu hai costituito l'Altissimo [per] tuo abitacolo.
Nítorí ìwọ fi Olúwa ṣe ààbò rẹ, ìwọ fi Ọ̀gá-ògo ṣe ibùgbé rẹ.
10 Male alcuno non ti avverrà, E piaga alcuna non si accosterà al tuo tabernacolo.
Búburú kan ki yóò ṣubú lù ọ́, Bẹ́ẹ̀ ni ààrùnkárùn kì yóò súnmọ́ ilé rẹ.
11 Perciocchè egli comanderà a' suoi Angeli intorno a te, Che ti guardino in tutte le tue vie.
Nítorí yóò fi àṣẹ fún àwọn angẹli nípa tìrẹ láti pa ọ́ mọ́ ní gbogbo ọ̀nà rẹ;
12 Essi ti leveranno in palma di mano, Che talora il tuo piè non s'intoppi in alcuna pietra.
wọn yóò gbé ọ sókè ní ọwọ́ wọn, nítorí kí ìwọ má ba à fi ẹsẹ̀ rẹ gún òkúta.
13 Tu camminerai sopra il leone, e sopra l'aspido; Tu calcherai il leoncello e il dragone.
Ìwọ yóò rìn lórí kìnnìún àti paramọ́lẹ̀; ìwọ yóò tẹ kìnnìún ńlá àti ejò ńlá ni ìwọ yóò fi ẹsẹ̀ tẹ̀ mọ́lẹ̀.
14 Perciocchè egli ha posta in me tutta la sua affezione, [dice il Signore], io lo libererò; [E] lo leverò ad alto, perchè egli conosce il mio Nome.
“Nítorí ti ìfẹ́ rẹ sí mi, èmi yóò gbà ọ́; èmi yóò pa ọ́ mọ́, nítorí ìwọ jẹ́wọ́ orúkọ mi.
15 Egli m'invocherà, e io gli risponderò; Io [sarò] con lui [quando sarà] in distretta; Io lo riscoterò e lo glorificherò.
Òun yóò pè mí, èmi yóò sì dá a lóhùn; èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú ìpọ́njú, èmi yóò gbà á, èmi yóò sì bu ọlá fún un.
16 Io lo sazierò di lunga vita, E gli farò veder la mia salute.
Pẹ̀lú ẹ̀mí gígùn ni èmi yóò fi tẹ́ ẹ lọ́rùn, èmi yóò sì fi ìgbàlà mi hàn án.”

< Salmi 91 >