< Esekiel 24 >

1 Og Herrens ord kom til mig i det niende år, i den tiende måned, på den tiende dag i måneden, og det lød så:
Ní ọdún kẹsànán, oṣù kẹwàá, ọjọ́ kẹwàá, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Menneskesønn! Skriv op for dig navnet på denne dag, just denne dag! Babels konge har leiret sig mot Jerusalem just på denne dag.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ọjọ́ náà sílẹ̀, ọjọ́ náà gan an, nítorí ọba Babeli náà ti da ojú ti Jerusalẹmu ní ọjọ́ yìí gan an.
3 Og sett frem en lignelse for den gjenstridige ætt og si til dem: Så sier Herren, Israels Gud: Sett gryten på, sett den på og øs så vann i den!
Sì pa òwe yìí fún ilé ọlọ́tẹ̀ náà, sọ fún wọn pé: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Gbé ìkòkò ìdáná náà ka iná, gbé e ka iná kí o sì da omi sí i nínú.
4 Legg kjøttstykkene sammen i den, alle gode stykker, lår og bog! Fyll den med de beste ben!
Kó àwọn ègé ẹran tí a gé náà sínú rẹ̀, gbogbo àwọn ègé ẹran tí ó tóbi, itan àti apá. Kó àwọn egungun tí ó dára jù sínú rẹ̀,
5 Ta det beste av småfeet og legg så et bål under den for å koke benene! La det koke til gagns! Benene koker allerede i den.
mú àwọn tí ó jọjú nínú agbo ẹran. Kó àwọn egungun sí abẹ́ ẹ rẹ̀; sì jẹ́ kí ó hó dáradára sì jẹ́ kí àwọn egungun náà bọ̀ nínú rẹ̀.
6 Derfor sier Herren, Israels Gud, så: Ve blodstaden, den rustne gryte, som rusten ikke er gått av! Ta stykke for stykke ut av den! Det blir ikke kastet lodd derom.
Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà, fún ìkòkò náà tí èérí rẹ̀ wà nínú rẹ̀, tí èérí kò dà kúrò lójú rẹ̀! Mú ẹran náà jáde ní ekìrí ekìrí má ṣe ṣà wọ́n mú.
7 For det blod den har utøst, er ennu i den; den har helt det ut på nakne berget, den har ikke utøst det på jorden, så mulden kunde dekke over det.
“‘Nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ó ta sílẹ̀ wà ní àárín rẹ̀; à á sí orí àpáta kan lásán kò dà á sí orí ilẹ̀, níbi ti erùpẹ̀ yóò ti bò ó.
8 For å la min harme ha fritt løp, for å ta hevn lot jeg dens blod komme på nakne berget, så det ikke skulde bli tildekket.
Láti bá à le jẹ́ kí ìbínú kí ó dé láti gbẹ̀san mo da ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sí orí àpáta kan lásán, kí o ma bà á wà ni bíbò.
9 Derfor sier Herren, Israels Gud, så: Ve blodstaden! Også jeg vil gjøre bålet stort.
Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà! Èmi pàápàá yóò jẹ́ kí òkìtì iná náà tóbi.
10 Legg meget ved på, tend op ilden! La kjøttet bli mørt og suppen koke inn, så benene blir forbrent,
Nítorí náà kó igi náà jọ sí i, kí o sì fi iná sí i. Ṣe ẹran náà dáradára, fi tùràrí dùn ún; kí o sì jẹ́ kí egungun náà jóná.
11 og la den bli stående tom på sine glør, forat den kan bli het, og dens kobber bli glødende, og dens urenhet smeltes bort og dens rust fortæres!
Lẹ́yìn náà gbé òfìfo ìkòkò náà lórí ẹyin iná kí idẹ rẹ̀ lè gbóná, kí ó lè pọ́n àti ki ìfófó rẹ̀ le di yíyọ́ nínú rẹ̀ kí èérí rẹ̀ le jó dànù.
12 Trettende arbeid har den voldt mig, og allikevel er dens tykke rust ikke gått av den. I ilden med dens rust!
Ó ti ba gbogbo akitiyan jẹ: èérí rẹ̀ kò sì jáde kúrò lára rẹ̀, èérí náà gan an yóò wà nínú iná.
13 Din urenhet er en skam; fordi jeg har renset dig, men du ikke er blitt ren, skal du ikke mere bli fri for din urenhet før jeg får stilt min harme på dig.
“‘Nísinsin yìí èérí rẹ̀ ni ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wà. Nítorí mo gbìyànjú láti wẹ̀ ọ́ mọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò sì mọ́ kúrò nínú ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, a kì yóò sì tún wẹ̀ ọ mọ́ kúrò nínú èérí rẹ, títí èmi yóò fi jẹ́ kí ìbínú mi balẹ̀ sórí rẹ̀.
14 Jeg, Herren, har talt; det kommer, og jeg vil gjøre det; jeg lar det ikke være og sparer ikke og angrer ikke; efter din ferd og dine gjerninger skal du bli dømt, sier Herren, Israels Gud.
“‘Èmi Olúwa ni ó sọ ọ́, yóò sì ṣe, èmi yóò sì ṣe é. Èmi kì yóò padà sẹ́yìn; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá sí i, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọkàn mi padà; gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ, ni wọn yóò dá ọ lẹ́jọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
15 Og Herrens ord kom til mig, og det lød så:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá pé:
16 Menneskesønn! Se, jeg tar dine øines lyst fra dig ved en brå død; men du skal ikke klage og ikke gråte, og dine tårer skal ikke rinne.
“Ọmọ ènìyàn, kíyèsi i, mo mú ìfẹ́ ojú rẹ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, nípa lílù kan. Ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ gbààwẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sọkún, bẹ́ẹ̀ ni omijé ojú rẹ kò gbọdọ̀ kán sílẹ̀.
17 Sukk i stillhet og hold ikke sørgefest som efter en død! Bind din hue på dig og ta dine sko på dine føtter og dekk ikke skjegget til og et ikke mat som folk sender dig!
Má ṣe sọkún, má ṣe gbààwẹ̀ fún òkú. Wé ọ̀já sí orí rẹ, sì bọ bàtà sí ẹsẹ̀ rẹ, má ṣe bo ètè ìsàlẹ̀ rẹ, ma ṣe jẹ oúnjẹ tí àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.”
18 Så talte jeg til folket om morgenen, og min hustru døde om aftenen; og morgenen efter gjorde jeg som det var sagt mig.
Báyìí ni mo sọ̀rọ̀ fún àwọn ènìyàn ní òwúrọ̀, ní àṣálẹ́ ìyàwó mi sì kú. Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo ṣe bí a ti pàṣẹ fún mi.
19 Da sa folket til mig: Vil du ikke si oss hvad det betyr at du gjør så?
Lẹ́yìn náà àwọn ènìyàn bi mí léèrè pé, “Ṣe o kò ni sọ fún wa ohun ti nǹkan wọ̀nyí ní láti ṣe pẹ̀lú wa?”
20 Jeg svarte dem: Herrens ord kom til mig, og det lød så:
Mo sọ báyìí fún wọn pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
21 Si til Israels hus: Så sier Herren, Israels Gud: Se, jeg vanhelliger min helligdom, eders herlige stolthet, eders øines lyst og eders sjels lengsel, og eders sønner og døtre, som I har latt tilbake, skal falle for sverdet.
Sọ fún ilé Israẹli, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, èmi yóò sọ ibi mímọ́ mi di ibi àìmọ́ tayọ agbára yín, ìfẹ́ ojú yín, ìkáàánú yín, àti ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin tí ẹ̀yin fi sílẹ̀ sẹ́yìn yóò ṣubú nípa idà.
22 Da skal I gjøre som jeg har gjort: Eders skjegg skal I ikke tildekke, og den mat som folk sender eder, skal I ikke ete;
Ẹyin yóò sì ṣe bí mo ti ṣe. Ẹ̀yin kì yóò bo ìsàlẹ̀ ojú yín tàbí jẹ oúnjẹ ti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.
23 eders huer skal I ha på hodet og eders sko på føttene; I skal ikke klage og ikke gråte; men I skal visne bort i eders misgjerninger og sukke med hverandre.
Ẹ̀yin yóò fi àwọn ọ̀já wé àwọn orí yín àti àwọn bàtà ni ẹsẹ̀ yín, ẹ̀yin kì yóò ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò ṣòfò dànù nítorí àwọn àìṣedéédéé yín, ẹ̀yin yóò sì máa kérora láàrín ara yín.
24 Esekiel skal være til et tegn for eder; aldeles som han har gjort, skal I gjøre. Når det kommer, da skal I kjenne at jeg er Herren, Israels Gud.
Esekiẹli yóò jẹ àmì fún un yín; ẹ̀yin yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe. Nígbà tí èyí bá ṣẹlẹ̀, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’
25 Og du menneskesønn! På den dag da jeg tar deres vern, deres herlige fryd, deres øines lyst og deres sjels lengsel, deres sønner og døtre, fra dem,
“Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ, Ọmọ ènìyàn, kì yóò ha jẹ́ pé, ní ọjọ́ náà, nígbà ti mo bá gba agbára wọn, ayọ̀ wọn àti ògo wọn, ìfẹ́ ojú wọn, ohun tí wọn gbé ọkàn wọn lé, àti àwọn ọmọ ọkùnrin wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ obìnrin wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn,
26 på den dag skal det komme flyktninger til dig og forkynne det for folk.
ní ọjọ́ náà ẹni tí ó bá sálà yóò tọ̀ ọ́ wá láti sọ ìròyìn náà fún ọ.
27 Den dag skal din munn åpnes, når flyktningene er kommet, og du skal tale og ikke mere være målløs, og du skal være til et tegn for dem, og de skal kjenne at jeg er Herren.
Ní ọjọ́ náà ẹnu rẹ yóò sì ṣí; ìwọ yóò sọ̀rọ̀, ìwọ kì yóò sì yadi mọ́. Báyìí ìwọ yóò jẹ́ àmì fún wọn; wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ní Olúwa.”

< Esekiel 24 >