< اشعیا 49 >

ای جزیره‌ها از من بشنوید! و‌ای طوایف از جای دور گوش دهید! خداوند مرا از رحم دعوت کرده واز احشای مادرم اسم مرا ذکر نموده است. ۱ 1
Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin erékùṣù: gbọ́ èyí, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè jíjìnnà réré: kí a tó bí mi Olúwa ti pè mí; láti ìgbà bíbí mi ni ó ti dá orúkọ mi.
و دهان مرا مثل شمشیر تیز ساخته، مرا زیر سایه دست خودپنهان کرده است. و مرا تیر صیقلی ساخته درترکش خود مخفی نموده است. ۲ 2
Ó ṣe ẹnu mi bí idà tí a pọ́n, ní abẹ́ òjìji ọwọ́ rẹ̀ ni ó ti pa mí mọ́: ó ṣe mí ní ọfà tí a ti dán, ó sì fi mí pamọ́ sínú àpò rẹ̀.
و مرا گفت: ای اسرائیل تو بنده من هستی که از تو خویشتن راتمجید نموده‌ام! ۳ 3
Ó sọ fún mi pé, “Ìránṣẹ́ mi ni ìwọ í ṣe, Israẹli nínú ẹni tí n ó ti fi ògo mi hàn.”
اما من گفتم که عبث زحمت کشیدم و قوت خود را بی‌فایده و باطل صرف کردم لیکن حق من با خداوند و اجرت من با خدای من می‌باشد. ۴ 4
Ṣùgbọ́n èmi sọ pé, “Mo ti ṣe wàhálà lórí asán; mo ti lo gbogbo ipá mi lórí asán àti ìmúlẹ̀mófo. Síbẹ̀síbẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí mi ṣì wà lọ́wọ́ Olúwa, èrè mi sì ń bẹ pẹ̀lú Ọlọ́run mi.”
و الان خداوند که مرا از رحم برای بندگی خویش سرشت تا یعقوب را نزد اوبازآورم و تا اسرائیل نزد وی جمع شوند می‌گوید(و در نظر خداوند محترم هستم و خدای من قوت من است ). ۵ 5
Nísinsin yìí Olúwa wí pé ẹni tí ó mọ̀ mí láti inú wá láti jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ láti mú Jakọbu padà tọ̀ mí wá àti láti kó Israẹli jọ sọ́dọ̀ ara rẹ̀, nítorí pé a bọ̀wọ̀ fún mi ní ojú Olúwa Ọlọ́run mi sì ti jẹ́ agbára mi,
پس می‌گوید: این چیز قلیلی است که بنده من بشوی تا اسباط یعقوب را برپاکنی و ناجیان اسرائیل را باز آوری. بلکه تو را نورامت‌ها خواهم گردانید و تا اقصای زمین نجات من خواهی بود. ۶ 6
Òun wí pé: “Ó jẹ́ ohun kékeré fún ọ láti jẹ́ ìránṣẹ́ mi láti mú ẹ̀yà Jakọbu padà bọ̀ sípò àti láti mú àwọn ti Israẹli tí mo ti pamọ́. Èmi yóò sì fi ọ́ ṣe ìmọ́lẹ̀ fún àwọn kèfèrí, kí ìwọ kí ó lè mú ìgbàlà mi wá sí òpin ilẹ̀ ayé.”
خداوند که ولی و قدوس اسرائیل می‌باشد به او که نزد مردم محقر و نزد امت ها مکروه و بنده حاکمان است چنین می‌گوید: پادشاهان دیده برپا خواهند شد و سروران سجده خواهند نمود، به‌سبب خداوند که امین است وقدوس اسرائیل که تو را برگزیده است. ۷ 7
Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Olùdáǹdè àti Ẹni Mímọ́ Israẹli— sí ẹni náà tí a gàn tí a sì kórìíra lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, sí ìránṣẹ́ àwọn aláṣẹ: “Àwọn ọba yóò rí ọ wọn yóò sì dìde sókè, àwọn ọmọ ọba yóò rí i wọn yóò sì wólẹ̀, nítorí Olúwa ẹni tí í ṣe olóòtítọ́, Ẹni Mímọ́ Israẹli tí ó ti yàn ọ́.”
خداوند چنین می‌گوید: «در زمان رضامندی تو را اجابت نمودم و در روز نجات تو را اعانت کردم. و تو را حفظ نموده عهد قوم خواهم ساخت تا زمین را معمور سازی و نصیب های خراب شده را (به ایشان ) تقسیم نمایی. ۸ 8
Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Ní àkókò ojúrere mi, èmi yóò dá ọ lóhùn, àti ní ọjọ́ ìgbàlà, èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́; Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́ láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, láti mú ilẹ̀ padà bọ̀ sípò àti láti ṣe àtúnpín ogún rẹ̀ tí ó ti dahoro,
و به اسیران بگویی: بیرون روید و به آنانی که درظلمتند خویشتن را ظاهر سازید. و ایشان درراهها خواهند چرید و مرتعهای ایشان بر همه صحراهای کوهی خواهد بود. ۹ 9
láti sọ fún àwọn ìgbèkùn pé, ‘Ẹ jáde wá,’ àti fún àwọn tí ó wà nínú òkùnkùn pé, ‘Ẹ gba òmìnira!’ “Wọn yóò máa jẹ ní ẹ̀bá ọ̀nà àti koríko tútù lórí òkè aláìléwéko.
گرسنه و تشنه نخواهند بود و حرارت و آفتاب به ایشان ضررنخواهد رسانید زیرا آنکه بر ایشان ترحم داردایشان را هدایت خواهد کرد و نزد چشمه های آب ایشان را رهبری خواهد نمود. ۱۰ 10
Ebi kì yóò pa wọ́n bẹ́ẹ̀ ni òǹgbẹ kì yóò gbẹ wọ́n, tàbí kí ooru inú aṣálẹ̀ tàbí oòrùn kí ó pa wọ́n. Ẹni tí ó ṣàánú fún wọn ni yóò máa tọ́ wọn, tí yóò sì mú wọn lọ sí ibi orísun omi.
و تمامی کوههای خود را طریق‌ها خواهم ساخت وراههای من بلند خواهد شد. ۱۱ 11
Èmi yóò sọ gbogbo àwọn òkè ńlá mi di ojú ọ̀nà àti gbogbo òpópónà mi ni a ó gbé sókè.
اینک بعضی ازجای دور خواهند آمد و بعضی از شمال و ازمغرب و بعضی از دیار سینیم.» ۱۲ 12
Kíyèsi i, wọn yóò wá láti ọ̀nà jíjìn àwọn díẹ̀ láti àríwá àti àwọn díẹ̀ láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn díẹ̀ láti ẹkùn Siene.”
‌ای آسمانهاترنم کنید! و‌ای زمین وجد نما! و‌ای کوهها آوازشادمانی دهید! زیرا خداوند قوم خود را تسلی می‌دهد و بر مظلومان خود ترحم می‌فرماید. ۱۳ 13
Ẹ hó fún ayọ̀, ẹyin ọ̀run; yọ̀, ìwọ ilẹ̀ ayé; bú sórin, ẹ̀yin òkè ńlá! Nítorí Olúwa tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú yóò sì ṣàánú fún àwọn ẹni tí a ń pọ́n lójú.
اما صهیون می‌گوید: «یهوه مرا ترک نموده و خداوند مرا فراموش کرده است.» ۱۴ 14
Ṣùgbọ́n Sioni sọ pé, “Olúwa ti kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa ti gbàgbé è mi.”
آیا زن بچه شیر خواره خود را فراموش کرده بر پسر رحم خویش ترحم ننماید؟ اینان فراموش می‌کنند امامن تو را فراموش نخواهم نمود. ۱۵ 15
“Ǹjẹ́ abiyamọ ha le gbàgbé ọmọ ọmú rẹ̀ kí ó má sì ṣàánú fún ọmọ rẹ̀ tí ó ti bí? Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun le gbàgbé, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ!
اینک تو را برکف دستهای خود نقش نمودم و حصارهایت دائم در نظر من است. ۱۶ 16
Kíyèsi i, mo ti kọ ọ́ sí àtẹ́lẹwọ́ mi ògiri rẹ wà níwájú mi nígbà gbogbo.
پسرانت به تعجیل خواهند آمد و آنانی که تو را خراب و ویران کردند از تو بیرون خواهند رفت. ۱۷ 17
Àwọn ọmọ rẹ ti kánjú padà, àti àwọn tí ó sọ ọ́ dahoro ti padà lẹ́yìn rẹ.
چشمان خودرا به هر طرف بلند کرده، ببین جمیع اینها جمع شده، نزد تو می‌آیند. خداوند می‌گوید: «به حیات خودم قسم که خود را به جمیع اینها مثل زیورملبس خواهی ساخت و مثل عروس خویشتن رابه آنها خواهی آراست. ۱۸ 18
Gbójú rẹ sókè kí o sì wò yíká; gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ kórajọ wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ. Níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Ìwọ yóò wọ gbogbo wọ́n gẹ́gẹ́ bí ohun ọ̀ṣọ́; ìwọ yóò wọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí ìyàwó.
زیرا خرابه‌ها وویرانه های تو و زمین تو که تباه شده بود، اما الان تو از کثرت ساکنان تنگ خواهی شد و هلاک کنندگانت دور خواهند گردید. ۱۹ 19
“Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a tí run ọ́, a sì sọ ọ́ di ahoro tí gbogbo ilẹ̀ rẹ sì di ìparun, ní ìsinsin yìí, ìwọ yóò kéré jù fún àwọn ènìyàn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó jẹ ọ́ run ni yóò wà láti ọ̀nà jíjìn réré.
پسران تو که بی‌اولاد می‌بودی در سمع تو (به یکدیگر)خواهند گفت: این مکان برای من تنگ است، مراجایی بده تا ساکن شوم. ۲۰ 20
Àwọn ọmọ tí a bí ní àkókò ọ̀fọ̀ rẹ yóò sọ ní etígbọ̀ọ́ rẹ, ‘Ibi yìí ti kéré jù fún wa; ẹ fún wa láyè sí i tí a ó máa gbé.’
و تو دردل خودخواهی گفت: کیست که اینها را برای من زاییده است و حال آنکه من بی‌اولاد و نازاد و جلای وطن و متروک می‌بودم. پس کیست که اینها راپرورش داد. اینک من به تنهایی ترک شده بودم پس اینها کجا بودند؟» ۲۱ 21
Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní ọkàn rẹ pé, ‘Ta ló bí àwọn yìí fún mi? Mo ti ṣọ̀fọ̀ mo sì yàgàn; a sọ mi di àtìpó a sì kọ̀ mí sílẹ̀. Ta ló wo àwọn yìí dàgbà? A fi èmi nìkan sílẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí níbo ni wọ́n ti wá?’”
خداوند یهوه چنین می‌گوید: «اینک من دست خود را بسوی امت هادراز خواهم کرد و علم خویش را بسوی قوم هاخواهم برافراشت. و ایشان پسرانت را درآغوش خود خواهند‌آورد و دخترانت بر دوش ایشان برداشته خواهند شد. ۲۲ 22
Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyìí, “Kíyèsi i, Èmi yóò ké sí àwọn aláìkọlà, Èmi yóò gbé àsíá mi sókè sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn; wọn yóò kó àwọn ọmọkùnrin yín wá ní apá wọn wọn yóò sì gbé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin ní èjìká wọn.
و پادشاهان لالاهای تو و ملکه های ایشان دایه های توخواهند بود و نزد تو رو به زمین افتاده، خاک پای تو را خواهند لیسید و تو خواهی دانست که من یهوه هستم و آنانی که منتظر من باشند خجل نخواهند گردید. ۲۳ 23
Àwọn ọba ni yóò jẹ́ alágbàtọ́ baba fún ọ, àwọn ayaba wọn ni yóò sì jẹ́ ìyá-alágbàtọ́. Wọn yóò foríbalẹ̀ ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ojú wọn dídàbolẹ̀; wọn yóò máa lá erùpẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; gbogbo àwọn tí wọ́n ní ìrètí nínú mi ni a kì yóò jákulẹ̀.”
آیا غنیمت از جبار گرفته شود یا اسیران ازمرد قاهر رهانیده گردند. ۲۴ 24
Ǹjẹ́ a le gba ìkógun lọ́wọ́ jagunjagun, tàbí kí á gba ìgbèkùn lọ́wọ́ akíkanjú?
زیرا خداوند چنین می‌گوید: «اسیران نیز از جبار گرفته خواهند شد وغنیمت از دست ستم پیشه رهانیده خواهدگردید. زیرا که من با دشمنان تو مقاومت خواهم نمود و من پسران تو را نجات خواهم داد. ۲۵ 25
Ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Bẹ́ẹ̀ ni, a ó gba àwọn ìgbèkùn lọ́wọ́ àwọn jagunjagun, àti ìkógun lọ́wọ́ àwọn akíkanjú; ẹni tí ó bá ọ jà ni èmi ó bá jà, àti àwọn ọmọ rẹ ni èmi ó gbàlà.
و به آنانی که بر تو ظلم نمایند گوشت خودشان راخواهم خورانید و به خون خود مثل شراب مست خواهند شد و تمامی بشر خواهند دانست که من یهوه نجات‌دهنده تو و ولی تو و قدیر یعقوب هستم.» ۲۶ 26
Èmi yóò mú kí àwọn aninilára rẹ̀ jẹ ẹran-ara wọn; wọn yóò mu ẹ̀jẹ̀ ara wọn yó bí ẹni mu wáìnì. Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi, Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ, Olùdáǹdè rẹ, Alágbára kan ṣoṣo ti Jakọbu.”

< اشعیا 49 >