< Kaznodziei 1 >

1 Słowa kaznodziei, syna Dawidowego, króla w Jeruzalemie.
Ọ̀rọ̀ Oniwaasu, ọmọ Dafidi, ọba Jerusalẹmu:
2 Marność nad marnościami, powiedział kaznodzieja; marność nad marnościami, i wszystko marność.
“Asán inú asán!” Oníwàásù náà wí pé, “Asán inú asán! Gbogbo rẹ̀ asán ni.”
3 Cóż za pożytek ma człowiek ze wszystkiej pracy swej, którą prowadzi pod słońcem?
Kí ni ènìyàn rí jẹ ní èrè lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ̀, lórí èyí tí ó ń ṣe wàhálà sí lábẹ́ oòrùn?
4 Jeden rodzaj przemija, a drugi rodzaj nastaje; lecz ziemia na wieki stoi.
Bí ìran kan ti wá ni ìran mìíràn ń kọjá lọ, síbẹ̀ ayé dúró títí láé.
5 Słońce wschodzi i słońce zachodzi, a spieszy się do miejsca swego, kędy wschodzi;
Oòrùn ń ràn, oòrùn sì ń wọ̀, ó sì sáré padà sí ibi tí ó ti yọ.
6 Idzie na południe, a obraca się na północy; wiatr ustawicznie krążąc idzie, a po okręgach swoich wraca się wiatr.
Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ lọ sí ìhà gúúsù, Ó sì ń fẹ́ yípo sí ìhà àríwá, a sì tún padà sí ọ̀nà rẹ̀.
7 Wszystkie rzeki idą do morza, wszakże morze nie wylewa; do miejsca, z którego rzeki płyną, wracają się, aby zaś stamtąd wychodziły.
Gbogbo odò ń sàn sí inú Òkun, síbẹ̀síbẹ̀ Òkun kò kún. Níbi tí àwọn odò ti wá, níbẹ̀ ni wọ́n tún padà sí.
8 Wszystkie rzeczy są pełne zabaw, a człowiek nie może ich wymówić; oko nie nasyci się widzeniem, a ucho nie napełni się słyszeniem.
Ohun gbogbo ni ó ń mú àárẹ̀ wá, ju èyí tí ẹnu le è sọ. Ojú kò tí ì rí ìrírí tí ó tẹ́ ẹ lọ́rùn, bẹ́ẹ̀ ni, etí kò tí ì kún fún gbígbọ́.
9 Co było, jest to, co być ma; a co się teraz dzieje, jest to, co się dziać będzie, a niemasz nic nowego pod słońcem.
Ohun tí ó ti wà tẹ́lẹ̀ náà ni yóò sì máa wà, ohun tí a ti ṣe sẹ́yìn òun ni a ó tún máa ṣe padà kò sí ohun tuntun lábẹ́ oòrùn.
10 Jestże jaka rzecz, o którejby kto rzec mógł: Wej! to coś nowego? I toć już było za onych wieków, które były przed nami.
Ǹjẹ́ ohun kan wà tí ẹnìkan le è sọ wí pé, “Wò ó! Ohun tuntun ni èyí”? Ó ti wà tẹ́lẹ̀ rí ní ọjọ́ tó ti pẹ́, o ti wà ṣáájú tiwa.
11 Niemasz pamiątki pierwszych rzeczy; także też i potomnych, które będą, nie będzie pamiątki u tych, którzy potem nastaną.
Kò sí ìrántí ohun ìṣáájú bẹ́ẹ̀ ni ìrántí kì yóò sí fún ohun ìkẹyìn tí ń bọ̀ lọ́dọ̀ àwọn tí ń bọ̀ ní ìgbà ìkẹyìn.
12 Ja kaznodzieja byłem królem Izraelskim w Jeruzalemie;
Èmi, Oniwaasu ti jẹ ọba lórí Israẹli ní Jerusalẹmu rí.
13 I przyłożyłem do tego serce swe, abym szukał, i doszedł mądrością swoją wszystkiego, co się dzieje pod niebem.(Tę zabawę trudną dał Bóg synom ludzkim, aby się nią trapili.)
Mo fi àsìkò mi sílẹ̀ láti kọ́ àti láti ṣe àwárí pẹ̀lú ọgbọ́n, gbogbo ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ ọ̀run. Háà! Ẹrù wúwo tí Ọlọ́run ti gbé lé àwọn ènìyàn.
14 Widziałem wszystkie sprawy, które się dzieją pod słońcem, a oto wszystko jest marnością i utrapieniem ducha.
Èmi ti rí ohun gbogbo tí ó ń ṣẹlẹ̀ lábẹ́ oòrùn, gbogbo rẹ̀ kò ní ìtumọ̀ bí ẹní gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.
15 Co jest krzywego, nie może być wyprostowane, a niedostatki nie mogą być policzone.
Ohun tí ó ti wọ́ kò le è ṣe é tọ́ mọ́, ohun tí kò sí kò le è ṣe é kà.
16 Przetoż takiem myślał w sercu swem, mówiąc: Otom ja uwielbił i rozszerzył mądrość nad wszystkich, którzy byli przedemną w Jeruzalemie, a serce moje dostąpiło wielkiej mądrości i umiejętności.
Mo rò nínú ara mi, “Wò ó, mo ti dàgbà, ọgbọ́n mi sì ti pọ̀ ju ti ẹnikẹ́ni tí ó ti ṣe alákòóso Jerusalẹmu síwájú mi lọ, mo ti ní ìrírí púpọ̀ nípa ọgbọ́n àti ìmọ̀.”
17 I przyłożyłem do tego serce moje, abym poznał mądrość i umiejętność, szaleństwo i głupstwo; alem doznał, iż to jest utrapieniem ducha.
Nígbà náà ni mo fi ara jì láti ní ìmọ̀ nípa ọgbọ́n, àti pàápàá àìgbọ́n àti òmùgọ̀, ṣùgbọ́n mo rí, wí pé èyí pẹ̀lú bí ẹni ń gbìyànjú àti mú afẹ́fẹ́ ni.
18 Bo gdzie wiele mądrości, tam jest wiele gniewu; a kto przyczynia umiejętności, przyczynia boleści.
Nítorí pé ọgbọ́n púpọ̀ ìbànújẹ́ púpọ̀ ní ń mú wá, bí ìmọ̀ bá sì ṣe pọ̀ tó náà ni ìbànújẹ́ ń pọ̀ tó.

< Kaznodziei 1 >