< Jozuego 15 >

1 I był los pokolenia synów Judowych według domów ich przy granicach Edom, i przy puszczy Syn na południe od ostatecznej granicy południowej.
Ìpín fún ẹ̀yà Juda, ní agbo ilé agbo ilé, títí dé agbègbè Edomu, títí dé aginjù Sini ní òpin ìhà gúúsù.
2 A była ich granica od południa, od końca morza słonego, i od skały, która jest ku południowi.
Ààlà wọn ní ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ láti etí òpin ìhà gúúsù Òkun Iyọ̀,
3 I wychodzi ku południowi, ku pagórkowi niedźwiadkowemu, a ciągnie się aż do Syn; a idąc od południa do Kades Barny bieży aż ku Efronowi, i ciągnie się aż do Adar, obtaczając Karkaa.
ó sì gba gúúsù Akrabbimu lọ, títí dé Sini àti sí iwájú ìhà gúúsù Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà ó sì tún kọjá Hesroni lọ sí Adari, ó sì tún yípo yíká lọ sí Karka.
4 Stamtąd idąc do Asemona idzie ku rzece Egipskiej, a idzie koniec tych granic na zachód; tać będzie granica na południu.
Ó tún kọjá lọ sí Asmoni, ó sì papọ̀ mọ́ Wadi ti Ejibiti, ó parí sí Òkun. Èyí ni ààlà wọn ní ìhà gúúsù.
5 Granica zasię od wschodu słońca jest morze słone aż do końca Jordanu, a granica z strony północnej jest od skały morskiej, od końca Jordanu.
Ààlà wọn ní ìhà ìlà-oòrùn ní Òkun Iyọ̀ títí dé ẹnu Jordani. Ààlà àríwá bẹ̀rẹ̀ láti etí òkun ní ẹnu Jordani,
6 A ciągnie się ta granica do Betaglu, i bieży od północy aż do Betaraba; a stamtąd idzie ta granica aż do kamienia Boen, syna Rubenowego.
ààlà náà sì tún dé Beti-Hogla, ó sì lọ sí ìhà àríwá Beti-Araba. Ààlà náà sì tún dé ibi Òkúta Bohani ti ọmọ Reubeni.
7 Idzie także ta granica do Dabir od doliny Achor, a ku północy się udawa do Galgal, które jest przeciw górze, gdzie wstępują do Adommim, która jest na południe od rzeki, a idzie ta granica do wód Ensemes, a kończy się u studnicy Rogiel.
Ààlà náà gòkè lọ títí dé Debiri láti àfonífojì Akori, ó sì yípadà sí àríwá Gilgali, èyí tí ń bẹ ní iwájú òkè Adummimu, tí ń bẹ ní ìhà gúúsù odò náà. Ó sì tẹ̀síwájú sí apá omi En-Ṣemeṣi, ó sì jáde sí En-Rogeli.
8 Bieży też ta granica przez dolinę syna Hennomowego po bok Jebuzejczyka od południa, co jest Jeruzalem. Stamtąd bieży ta granica na wierzch góry, która jest przeciwko dolinie Hennom na zachód, a która jest na końcu doliny Refaimitów na północy.
Ààlà náà sì tún gòkè lọ sí àfonífojì Beni-Hinnomu ní ìhà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ gúúsù ti Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu). Ó sì gòkè lọ sí orí òkè tí ó wà lórí àfonífojì Hinnomu tí ń bẹ ní ìpẹ̀kun àfonífojì Refaimu ní ìhà àríwá.
9 Obtacza też ta granica od wierzchu góry aż do źródła wody Neftoa, i bieży aż do miast góry Hefron; potem się ciągnie ta granica ku Baala, które jest Karyjatyjarym.
Ààlà náà sì lọ láti orí òkè lọ sí ìsun omi Nefitoa, ó sì jáde sí ìlú òkè Efroni, ó sì lọ sí apá ìsàlẹ̀ Baalahi (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu).
10 Potem kołem bieży ta granica od Baala na zachód do góry Seir, a stamtąd przechodzi po bok góry Jarym od północy, która jest Cheslon, i spuszcza się do Betsemes, i przychodzi do Tamna.
Ààlà tí ó yípo láti Baalahi lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn sí òkè Seiri, ó sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Jearimu (tí í ṣe, Kesaloni), ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beti-Ṣemeṣi, ó sì kọjá lọ sí Timna.
11 I wychodzi ta granica po bok Akaronu na północy, a idzie kołem ta granica, aż do Sechronu, i bieży przez górę Baala; stamtąd wychodzi do Jabneel, i kończą się te granica u morza.
Ààlà náà sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Ekroni, ó sì yípadà lọ sí Ṣikkeroni, ó sì yípadà lọ sí òkè Baalahi, ó sì dé Jabneeli, ààlà náà sì parí sí Òkun.
12 A granica zachodnia jest przy morzu wielkiem, i przy granicach jego; tać jest granica synów Juda w okrąg podług domów ich.
Ààlà ìwọ̀-oòrùn sì jẹ́ agbègbè Òkun Ńlá. Ìwọ̀nyí ni ààlà àyíká ènìyàn Juda ní agbo ilé wọn.
13 Ale Kalebowi synowi Jefunowemu, dał Jozue dział między syny Juda, jak Pan powiedział Jozuemu, miasto Arba, ojca olbrzymów, to jest Hebron.
Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Olúwa pa fún Joṣua, ó fi ìpín fún Kalebu ọmọ Jefunne, ìpín ní Juda—Kiriati-Arba, tí í ṣe Hebroni. (Arba sì ní baba ńlá Anaki.)
14 I wypędził stamtąd Kaleb trzech synów Enakowych: Sesaja, i Ahymana, i Talmaja, syny Enakowe.
Kalebu sì lé àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta jáde láti Hebroni; Ṣeṣai, Ahimani, àti Talmai, ìran Anaki.
15 A wyszedł stamtąd do mieszkających w Dabir, które zwano przedtem Karyjatsefer.
Ó sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
16 I rzekł Kaleb: Kto by dobył Karyjatsefer, a wziął je, tedy mu dam Achsę, córkę swoję, za żonę.
Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
17 I dobył go Otonijel, syn Keneza, brata Kalebowego; i dał mu Achsę, córkę swoję, za żonę.
Otnieli ọmọ Kenasi, arákùnrin Kalebu, sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
18 I stało się, gdy ona przyszła do niego, namawiała go, aby prosił ojca jej o pole; przetoż zsiadła z osła, i rzekł do niej Kaleb: Cóż ci?
Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
19 A ona odpowiedziała: Daj mi błogosławieństwo; gdyżeś mi dał ziemię suchą, przydaj mi też źródła wód. I dał jej źródła wyższe, i źródła dolne.
Ó sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
20 Toć jest dziedzictwo pokolenia synów Judowych według domów ich.
Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bi ìdílé wọn.
21 I były miasta w granicach pokolenia synów Judowych podle granicy Edom ku południowi: Kabseel, i Eder, i Jagur.
Ìlú ìpẹ̀kun gúúsù ti ẹ̀yà Juda ní gúúsù ní ààlà Edomu nìwọ̀nyí: Kabṣeeli, Ederi, Jaguri,
22 I Cyna, i Dymona, i Adada;
Kina, Dimona, Adada,
23 I Kades, i Hasor, i Jetnan;
Kedeṣi, Hasori, Itina,
24 I Zyf, i Telem, i Balot;
Sifi, Telemu, Bealoti,
25 I Hasor Hadata, i Karyjot Chesron, toć jest Hasor;
Hasori Hadatta, Kerioti Hesroni (tí í ṣe Hasori),
26 Amam, i Sama, i Molada;
Amamu, Ṣema, Molada,
27 I Asorgadda, i Hessemon, i Betfalet;
Hasari Gada, Heṣmoni, Beti-Peleti,
28 I Hasersual, i Beersaba, i Bazotyja;
Hasari-Ṣuali, Beerṣeba, Bisiotia,
29 Baala, i Ijim, i Esem;
Baalahi, Limu, Esemu,
30 I Eltolad, i Kesyl, i Horma;
Eltoladi, Kesili, Horma,
31 I Syceleg, i Medemena, i Sensenna;
Siklagi, Madmana, Sansanna,
32 I Lebaot, i Selim, Ain, i Remmon; wszystkich miast dwadzieścia i dziewięć, i wsi ich.
Leboati, Ṣilhimu, Aini àti Rimoni, àpapọ̀ ìlú mọ́kàndínlọ́gbọ̀n àti àwọn ìletò wọn.
33 W równinach zaś Estaol, i Sarea, i Asena;
Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ẹsẹ̀ òkè: Eṣtaoli, Sora, Aṣna,
34 I Zanoe, i Engannim, Tepnach, i Enaim;
Sanoa, Eni-Gannimu, Tapua, Enamu,
35 Jerymot, i Adullam, Socho, i Aseka;
Jarmatu, Adullamu, Soko, Aseka,
36 I Saraim, i Adytaim, i Gedera, i Gederotaim, miast czternaście, i wsi ich.
Ṣaaraimu, Adittaimu àti Gedera (tàbí Gederotaimu). Ìlú mẹ́rìnlá àti àwọn ìletò wọn.
37 Sanany, i Hadasa, i Mygdalgad;
Senani, Hadaṣa, Migdali Gadi,
38 I Delean, i Mesfa, i Jektel;
Dileani, Mispa, Jokteeli,
39 Lachys, i Bassekat, i Eglon;
Lakiṣi, Boskati, Egloni,
40 I Chabbon, i Lachmas, i Chytlis;
Kabboni, Lamasi, Kitlisi,
41 I Kiederot, Bet Dagon, i Naama, i Maceda, miast szesnaście, i wsi ich.
Gederoti, Beti-Dagoni, Naama àti Makkeda, ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
42 Labana, i Eter, i Asan;
Libina, Eteri, Aṣani,
43 I Iftach, i Esna, i Nesyb;
Hifita, Aṣna, Nesibu,
44 I Ceila, i Achzyb, i Maresa, miast dziewięć, i wsi ich;
Keila, Aksibu àti Meraṣa: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò wọn.
45 Akkaron, i miasteczka jego, i wioski jego;
Ekroni, pẹ̀lú ibùgbé àti àwọn ìletò rẹ̀ tó yí i ká,
46 Od Akkaronu aż do morza wszystko, co leży po bok Asotu, i ze wsiami ich;
ìwọ̀-oòrùn Ekroni, gbogbo èyí tí ń bẹ nítòsí Aṣdodu, pẹ̀lú àwọn ìletò wọn,
47 Azot, miasteczka jego, i wsi jego; Gaza, miasteczka jego, i wsi jego, aż do potoku Egipskiego, i morze wielkie za granicą jego.
Aṣdodu, agbègbè ìlú rẹ̀ àti ìletò; àti Gasa, ìlú rẹ̀ àti ìletò, títí ó fi dé odò Ejibiti àti agbègbè Òkun Ńlá.
48 A na górze leżą Sam, i Jeter, i Soko;
Ní ilẹ̀ òkè náà: Ṣamiri, Jattiri, Soko,
49 I Danna, i Karyjatsenna, które jest Dabir;
Dannah, Kiriati-Sannnah (tí í ṣe Debiri),
50 I Anab, i Istemo, i Anim;
Anabu, Eṣitemo, Animu,
51 I Gosen, i Holon, i Gilo, miast jedenaście, i wsi ich;
Goṣeni, Holoni àti Giloni, ìlú mọ́kànlá àti ìletò wọn.
52 Arab, i Duma, i Esaan;
Arabu, Duma, Eṣani,
53 I Janum, i Bet Tafua, i Afeka;
Janimu, Beti-Tapua, Afeka,
54 I Chumta, i Karyjat Arbe, toć jest Hebron, i Syjor, miast dziewięć, i wsi ich.
Hamuta, Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) àti Ṣiori: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò rẹ̀
55 Maon, Karmel, i Zyf, i Juta.
Maoni, Karmeli, Sifi, Jutta,
56 I Jezrael, i Jukiedam, i Zanoe;
Jesreeli, Jokdeamu, Sanoa,
57 Kain, Gabaa, i Tamna, miast dziesięć, i wsi ich.
Kaini, Gibeah àti Timna: ìlú mẹ́wàá àti àwọn ìletò wọn.
58 Halhul, Betsur i Giedor;
Halhuli, Beti-Suri, Gedori,
59 I Maret, i Bet Anot, i Eltekon, miast sześć, i wsi ich.
Maarati, Beti-Anoti àti Eltekoni: ìlú mẹ́fà àti àwọn ìletò wọn.
60 Karyjat Baal, które jest Karyjatyjarym, i Rabba, miasta dwa, i wsi ich.
Kiriati-Baali (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu) àti Rabba ìlú méjì àti ìletò wọn.
61 A na puszczy: Bet Araba, Meddyn, i Sechacha;
Ní aginjù: Beti-Araba, Middini, Sekaka,
62 I Nebsan, i miasto Soli, i Engaddy, miast sześć, i wsi ich.
Nibṣani, Ìlú Iyọ̀ àti En-Gedi: ìlú mẹ́fà àti ìletò wọn.
63 Ale Jebuzejczyka, obywatela Jeruzalemskiego, nie mogli synowie Judowi wypędzić; przetoż mieszkał Jebuzejczyk z syny Juda w Jeruzalemie aż do dnia tego.
Juda kò lè lé àwọn ọmọ Jebusi jáde, tí wọ́n ń gbé ní Jerusalẹmu. Àwọn ará Jebusi sì ń gbé pẹ̀lú àwọn ènìyàn Juda títí dí òní.

< Jozuego 15 >