< Księga Sędziów 14 >

1 Szedł tedy Samson do Tamnaty, a ujrzał tam niewiastę z córek Filistyńskich.
Nígbà kan Samsoni gòkè lọ sí Timna níbẹ̀ ni ó ti rí ọmọbìnrin Filistini kan.
2 A przyszedłszy oznajmił ojcu swemu i matce swojej, mówiąc; Niewiastem widział w Tamnacie z córek Filistyńskich; przetoż teraz weźmijcie mi ją za żonę.
Nígbà tí ó darí dé, ó sọ fún àwọn òbí rẹ̀ pé, “Mo rí obìnrin Filistini kan ní Timna: báyìí ẹ fẹ́ ẹ fún mi bí aya mi.”
3 I rzekł mu ojciec jego, i matka jego; Azaż nie masz między córkami braci twych, i we wszystkim ludu moim niewiasty, że chcesz iść a wziąć sobie żonę z Filistynów nieobrzezanych? Odpowiedział Samson ojcu swemu: Tę mi weźmijcie, bo się podobała oczom moim.
Baba àti ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Ṣé kò sí obìnrin tí ó dára tí ó sì tẹ́ ọ lọ́rùn ní àárín àwọn ìbátan rẹ, tàbí láàrín gbogbo àwọn ènìyàn wa? Ṣé ó di dandan fún ọ láti lọ sí àárín àwọn Filistini aláìkọlà kí o tó fẹ́ ìyàwó?” Ṣùgbọ́n Samsoni wí fún baba rẹ̀ pé, “Fẹ́ ẹ fún mi torí pé inú mi yọ́ sí i púpọ̀púpọ̀.”
4 A ojciec jego i matka jego nie wiedzieli, że to było od Pana; bo on przyczyny szukał na Filistyny, gdy na on czas Filistyni panowali nad Izraelem.
(Àwọn òbí rẹ̀ kò mọ̀ pé ọ̀dọ̀ Olúwa ni nǹkan yìí ti wá, ẹni tí ń wá ọ̀nà àti bá Filistini jà; nítorí àwọn ni ń ṣe àkóso Israẹli ní àkókò náà.)
5 Tedy szedł Samson z ojcem swym i z matką swoją do Tamnaty, a przychodząc ku winnicom Tamnaty, oto, lew młody ryczący zabieżał mu.
Samsoni sọ̀kalẹ̀ lọ sí Timna òun àti baba àti ìyá rẹ̀. Bí wọ́n ṣe ń súnmọ́ àwọn ọgbà àjàrà tí ó wà ní Timna, láìròtẹ́lẹ̀, ọ̀dọ́ kìnnìún kan jáde síta tí ń ké ramúramù bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀.
6 I przypadł nań Duch Pański, a rozdarł go, jakoby rozdarł koźlę, choć nic nie miał w rękach swych; i nie oznajmił ojcu swemu i matce swojej, co uczynił.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé e pẹ̀lú agbára tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi fa kìnnìún náà ya pẹ̀lú ọwọ́ rẹ̀ lásán bí ẹní ya ọmọ ewúrẹ́, ṣùgbọ́n òun kò sọ ohun tí ó ṣe fún baba tàbí ìyá rẹ̀.
7 Przyszedłszy tedy mówił z oną niewiastą, a podobała się oczom Samsonowym.
Ó sì lọ bá obìnrin náà sọ̀rọ̀, inú Samsoni sì yọ́ sí i.
8 A wróciwszy się po kilku dniach, aby ją pojął, zstąpił, aby oglądał on ścierw lwi, a oto, rój pszczół był w ścierwie lwim, i miód.
Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, nígbà tí ó padà lọ láti gbé e níyàwó, ó yà lọ láti wo òkú kìnnìún náà. Inú rẹ̀ ni ó ti bá ọ̀pọ̀ ìṣù oyin àti oyin,
9 A wziąwszy go w ręce swoje szedł drogą i jadł, a przyszedłszy do ojca swego i do matki swojej, dał im, i jedli; ale im nie powiedział, że z ścierwu lwiego nabrał miodu.
ó fi ọwọ́ ha jáde, ó sì ń jẹ ẹ́ bí ó ti ń lọ. Nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ àwọn òbí rẹ̀, ó fún wọn ní díẹ̀, àwọn náà sì jẹ, ṣùgbọ́n kò sọ fún wọn pé ara òkú kìnnìún ni òun ti rí oyin náà.
10 tedy szedł ojciec jego do onej niewiasty, i sprawił tam Samson wesele; bo tak czyniwali młodzieńcy.
Baba rẹ̀ sì sọ̀kalẹ̀ lọ láti kí obìnrin náà. Samsoni sì ṣe àsè gẹ́gẹ́ bí àṣà ọkọ ìyàwó ní àkókò náà.
11 A gdy go ujrzeli Filistyni, wzięli trzydzieści towarzyszów, aby byli przy nim.
Nígbà tí ó fi ara hàn, tí àwọn ènìyàn náà rí i wọ́n fún un ní ọgbọ̀n àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ láti wá bá a kẹ́gbẹ́.
12 Do których rzekł Samson: Zadam wam zagadkę, a jeźli ją zgadniecie przez siedem dni wesela i wyłożycie mi ją, tedy wam dam trzydzieści prześcieradeł, i trzydzieści szat odmiennych.
Samsoni sọ fún wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí n pa àlọ́ kan fún un yín, bí ẹ̀yin bá lè fún mi ní ìtumọ̀ rẹ̀ láàrín ọjọ́ méje àsè yìí, tàbí ṣe àwárí àlọ́ náà èmi yóò fún un yín ní ọgbọ̀n aṣọ tí a fi òwú ọ̀gbọ̀ hun, àti ọgbọ̀n ìpààrọ̀ aṣọ ìyàwó.
13 A jeźliż mi jej nie zgadniecie, tedy wy mnie dacie trzydzieści prześcieradeł, i trzydzieści szat odmiennych; którzy mu odpowiedzieli: Zadaj zagadkę twoję; a będziemy jej słuchali.
Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin kò bá le sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi, ẹ̀yin yóò fún mi ní ọgbọ̀n aṣọ tí a fi òwú ọ̀gbọ̀ hun àti ọgbọ̀n ìpààrọ̀ aṣọ ìgbéyàwó.” Wọ́n dáhùn pé, “Sọ àlọ́ rẹ fún wa jẹ́ kí a gbọ́.”
14 I rzekł do nich: Z pożerającego wyszedł pokarm, a z mocnego wyszła słodkość; i nie mogli zgadnąć onej zagadki przez trzy dni.
Ó dáhùn pé, “Láti inú ọ̀jẹun ni ohun jíjẹ ti jáde wá; láti inú alágbára ni ohun dídùn ti jáde wá.” Ṣùgbọ́n fún odidi ọjọ́ mẹ́ta ni wọn kò fi rí ìtumọ̀ sí àlọ́ náà.
15 I rzekli dnia siódmego do żony Samsonowej: Namów męża twego, aby nam powiedział zagadkę, byśmy snać nie spalili ciebie, i domu ojca twego ogniem; na tożeście nas wezwali, abyście posiedli majętność naszę, czy nie na to?
Ní ọjọ́ kẹrin, wọ́n wí fún ìyàwó Samsoni, pé, “Tan ọkọ rẹ kí ó lè ṣe àlàyé àlọ́ náà fún wa, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ àwa yóò sun ìwọ àti ìdílé baba rẹ̀ ní iná. Tàbí ṣe o pè wá sí ibi àsè yìí láti sọ wá di òtòṣì tàbí kó wa lẹ́rú ni?”
16 Płakała tedy żona Samsonowa nań, mówiąc: Zaprawdę mię masz w nienawiści, a nie miłujesz mię; zadałeś zagadkę synom ludu mego, a nie chcesz mi jej oznajmić. I rzekł do niej: Otom jej ojcu memu i matce mojej nie oznajmił, a tobie bym miał oznajmić?
Nígbà náà ni ìyàwó Samsoni ṣubú lé e láyà, ó sì sọkún ní iwájú rẹ̀ pé, “O kórìíra mi! O kò sì ní ìfẹ́ mi nítòótọ́, o pàlọ́ fún àwọn ènìyàn mi, ìwọ kò sì sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi.” “Èmi kò tí ì ṣe àlàyé rẹ̀ fún baba àti ìyá mi, báwo ni èmi ó ṣe sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún ọ.”
17 I płakała nań przez one siedem dni, póki mieli wesele. Stało się tedy dnia siódmego, że jej oznajmił, bo mu się uprzykrzała. A ona powiedziała onę zagadkę synom ludu swego.
Fún gbogbo ọjọ́ méje tí wọ́n fi ṣe àsè náà ni ó fi sọkún, nítorí náà ní ọjọ́ keje ó sọ ìtumọ̀ àlọ́ fún un nítorí pé ó yọ ọ́ lẹ́nu ní ojoojúmọ́. Òun náà sì sọ ìtumọ̀ àlọ́ náà fún àwọn ènìyàn rẹ̀.
18 Przetoż rzekli do niego mężowie onego miasta siódmego dnia przed zachodem słońca: Cóż słodszego nad miód, a co mocniejszego nad lwa? którym on odpowiedział: Byście byli nie orali jałowicą moją, nie zgadlibyście byli zagadki mojej.
Kí ó tó di àṣálẹ́ ọjọ́ keje àwọn ọkùnrin ìlú náà sọ fún un pé, “Kí ni ó dùn ju oyin lọ? Kí ni ó sì lágbára ju kìnnìún lọ?” Samsoni dá wọn lóhùn pé, “Bí kì í bá ṣe pé ẹ fi ọ̀dọ́ abo màlúù mi kọ ilẹ̀, ẹ̀yin kò bá tí mọ ìtumọ̀ sí àlọ́ mi.”
19 I przypadł nań Duch Pański, a szedłszy do Aszkalonu, zabił z nich trzydzieści mężów a wziąwszy łupy z nich, dał szaty odmienne onym, którzy zgadli zagadkę, i rozgniewawszy się bardzo poszedł do domu ojca swego.
Lẹ́yìn èyí, ẹ̀mí Olúwa bà lé e pẹ̀lú agbára. Ó lọ sí Aṣkeloni, ó pa ọgbọ̀n nínú àwọn ọkùnrin wọn, ó gba àwọn ohun ìní wọn, ó sì fi àwọn aṣọ wọn fún àwọn tí ó sọ ìtumọ̀ àlọ́ náà. Ó sì padà sí ilé baba rẹ̀ pẹ̀lú ìbínú ríru.
20 I dostała się żona Samsonowa towarzyszowi jego, z którym miał towarzystwo.
Wọ́n sì fi ìyàwó Samsoni fún ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, tí ó jẹ́ ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ rẹ̀ nígbà ìgbéyàwó rẹ̀.

< Księga Sędziów 14 >