< Psalmów 77 >

1 Przedniejszemu śpiewakowi dla Jedytuna psalm Asafowy. Głos mój podnoszę do Boga, kiedy wołam; głos mój podnoszę do Boga, aby mię wysłuchał.
Fún adarí orin. Fún Jedutuni. Ti Asafu. Saamu. Mó kígbe sí Ọlọ́run fún ìrànlọ́wọ́; mo kígbe sí Ọlọ́run láti gbọ́ tèmi.
2 W dzień utrapienia mego szukałem Pana: wyciągałem w nocy ręce moje bez przestania, a nie dała się ucieszyć dusza moja.
Nígbà tí mo wà nínú ìpọ́njú, mo wá Olúwa; ní òru ni mo na ọwọ́ mi jáde ní àìkáárẹ̀ ọkàn mí sì kọ̀ láti tù ú nínú.
3 Wspominałem na Boga, a trwożyłem sobą; rozmyślałem, a utrapieniem ściśniony był duch mój. (Sela)
Èmi rántí rẹ, Ọlọ́run, mo sì kẹ́dùn; mo ṣe àròyé, ẹ̀mí mi sì rẹ̀wẹ̀sì. (Sela)
4 Zatrzymywałeś oczy moje, aby czuły; potartym był, ażem nie mógł mówić.
Ìwọ kò fẹ́ kí èmi fi ojú ba oorun, mo dààmú tó bẹ́ẹ̀ tí ń kò le sọ̀rọ̀.
5 Przychodziły mi na pamięć dni przeszłe i lata dawne.
Mo ronú nípa ọjọ́ ìgbàanì; ọdún pípẹ́ sẹ́yìn;
6 Wspominałem sobie na śpiewanie moje; w nocym w sercu swem rozmyślał, i wywiadywał się o tem duch mój, mówiąc:
mo rántí orin mi ní òru. Èmi ń bá àyà mi sọ̀rọ̀, ọkàn mi sì ń ṣe àwárí jọjọ.
7 Izali mię na wieki odrzuci Pan, a więcej mi już łaski nie ukaże?
“Olúwa yóò ha kọ̀ títí láé? Ki yóò ha ṣe ojúrere rẹ̀ mọ́?
8 Izali do końca ustanie miłosierdzie jego, i koniec weźmie słowo od rodzaju aż do rodzaju? Izali zapomniał Bóg zmiłować się?
Ṣe ìfẹ́ rẹ̀ àti àánú rẹ̀ ti kú lọ láéláé? Ìlérí rẹ̀ ha kùnà títí ayé?
9 Izali zatrzymał w gniewie litości swoje? (Sela)
Ọlọ́run ha gbàgbé láti máa ṣàánú? Ní ìbínú rẹ̀, ó ha sé ojúrere rẹ̀ mọ́?” (Sela)
10 I rzekłem: Toć jest śmierć moja; wszakże prawica Najwyższego uczyni odmianę.
Èmi wí pé, “Èyí ní ẹ̀dùn ọkàn mi, pé ọwọ́ ọ̀tún Ọ̀gá-ògo jùlọ ti yípadà”.
11 Wspominać sobie będę na sprawy Pańskie, a przypominać sobie będę dziwne sprawy twoje, zdawna uczynione.
Èmi ó rántí iṣẹ́ Olúwa: bẹ́ẹ̀ ni, èmi ó rántí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ ọjọ́ pípẹ́.
12 I będę rozmyślał o wszelkiem dziele twojem, i o uczynkach twoich będę mówił:
Èmi ṣàṣàrò lórí iṣẹ́ rẹ gbogbo, pẹ̀lú, ènìyàn sì máa sọ̀rọ̀ gbogbo iṣẹ́ agbára rẹ.
13 Boże! święta jest droga twoja. Któryż Bóg jest tak wielki, jako Bóg nasz?
Ọlọ́run, ọ̀nà rẹ jẹ́ mímọ́. Ọlọ́run wo ni ó sì tóbi bí Ọlọ́run wa?
14 Tyś jest Bóg, który czynisz cuda; podałeś do znajomości między narody moc twoję.
Ìwọ ni Ọlọ́run tó ń ṣe ìyanu; ìwọ fi agbára rẹ hàn nínú àwọn ènìyàn.
15 Odkupiłeś ramieniem twojem lud swój, syny Jakóbowe i Józefowe. (Sela)
Pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ ra àwọn ènìyàn padà, àwọn ọmọ Jakọbu àti Josẹfu. (Sela)
16 Widziały cię wody, o Boże! widziały cię wody, i ulękły się, i wzruszyły się przepaści.
Nígbà tí àwọn omi rí Ọlọ́run, nígbà tí àwọn omi rí ọ, ẹ̀rù bà wọ́n, nítòótọ́ ara ibú kò balẹ̀.
17 Obłoki wydały powodzi; niebiosa wydały gromy, a strzały twoje tam i sam biegały.
Àwọn ojú ọ̀run tú omi sílẹ̀, àwọsánmọ̀ fi àrá dáhùn; ọfà rẹ̀ ń tàn sẹ́yìn àti síwájú.
18 Huczało grzmienie twoje po obłokach, błyskawice oświeciły okrąg ziemi, ziemia się wzruszyła i zatrzęsła.
Àrá rẹ̀ ni a gbọ́ nínú ìjì, ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ sí gbogbo ayé; ayé bẹ̀rù, wọ́n sì wárìrì.
19 Przez morze była droga twoja, a ścieżki twoje przez wody wielkie, wszakże śladów twoich nie było.
Ipa rẹ̀ gba Òkun, ọ̀nà rẹ̀ ń bẹ nínú Òkun, ọ̀nà la omi alágbára kọjá ipa rẹ̀ ń bẹ nínú líla omi alágbára kọjá, nítòótọ́ a kò rí ojú ẹsẹ̀ rẹ̀.
20 Prowadziłeś lud twój, jako stado owiec, przez rękę Mojżesza i Aarona.
Ó tọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.

< Psalmów 77 >