< Jesaja 6 >

1 I det år då konung Ussia dog såg jag Herren sitta på en hög och upphöjd tron, och släpet på hans mantel uppfyllde templet.
Ní ọdún tí ọba Ussiah kú, mo rí Olúwa tí ó jókòó lórí ìtẹ́ tí ó ga tí a gbé sókè, ìṣẹ́tí aṣọ ìgúnwà rẹ̀ sì kún inú tẹmpili.
2 Serafer stodo omkring honom. Var och en av dem hade sex vingar: med två betäckte de sina ansikten, med två betäckte de sina fötter, och med två flögo de.
Àwọn Serafu wà ní òkè rẹ̀, ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní ìyẹ́ mẹ́fà, wọ́n fi ìyẹ́ méjì bo ojú wọn, wọ́n fi méjì bo ẹsẹ̀ wọn, wọ́n sí ń fi méjì fò.
3 Och den ene ropade till den andre och sade: "Helig, helig, helig är HERREN Sebaot; hela jorden är full av hans härlighet."
Wọ́n sì ń kọ sí ara wọn wí pé, “Mímọ́, mímọ́, mímọ́ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun gbogbo ayé kún fún ògo rẹ̀.”
4 Och dörrtrösklarnas fästen darrade, när ropet ljöd; och huset blev uppfyllt av rök.
Nípa ìró ohùn un wọn, òpó ìlẹ̀kùn àti gbogbo ògiri ilé náà sì mì tìtì, gbogbo inú tẹmpili sì kún fún èéfín.
5 Då sade jag: "Ve mig, jag förgås! Ty jag har orena läppar, och jag bor ibland ett folk som har orena läppar, och mina ögon hava sett Konungen, HERREN Sebaot."
Mo kígbe pé, “Ègbé ni fún mi! Mo ti gbé!” Nítorí mo jẹ́ ènìyàn aláìmọ́ ètè, mo sì ń gbé láàrín àwọn ènìyàn aláìmọ́ ètè, ojú mi sì ti rí ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ.
6 Men en av seraferna flög fram till mig, och han hade i sin hand ett glödande kol, som han med en tång hade tagit på altaret.
Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn Serafu wọ̀nyí fò wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹ̀yín iná ní ọwọ́ rẹ̀, èyí tí ó ti fi ẹ̀mú mú ní orí pẹpẹ.
7 Och han rörde därmed vid min mun. Därefter sade han: "Se, då nu detta har rört vid dina läppar, har din missgärning blivit tagen ifrån dig, och din synd är försonad."
Èyí ni ó fi kàn mí ní ẹnu tí ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ti kan ètè rẹ; a ti mú ẹ̀bi rẹ kúrò, a sì ti wẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nù.”
8 Och jag hörde Herren tala, och han sade: "Vem skall jag sända, och vem vill vara vår budbärare?" Och jag sade: "Se, här är jag, sänd mig."
Nígbà náà ni mo sì gbọ́ ohùn Olúwa wí pé, “Ta ni èmi yóò rán? Ta ni yóò sì lọ fún wa?” Nígbà náà ni èmi sì wí pé, “Èmi nìyí, rán mi!”
9 Då sade han: "Gå åstad och säg till detta folk: 'Hören alltjämt, men förstån intet; sen alltjämt, men förnimmen intet'.
Òun sì wí pé, “Tọ àwọn ènìyàn yìí lọ kí o sì wí fún wọn pé, “‘Ní gbígbọ́ ẹ̀yin yóò gbọ́, kì yóò sì yé e yín; ní rí rí ẹ̀yin yóò ri, ẹ̀yin kì yóò mọ òye.’
10 Förstocka detta folks hjärta, och tillslut dess öron, och förblinda dess ögon, så att det icke kan se med sina ögon, eller höra med sina öron, eller förstå med sitt hjärta, och omvända sig och bliva helat."
Mú kí àyà àwọn ènìyàn wọ̀nyí yigbì, mú kí etí wọn kí ó wúwo, kí o sì dìwọ́n ní ojú. Kí wọn kí ó má ba fi ojú wọn ríran, kí wọn kí ó má ba fi etí wọn gbọ́rọ̀, kí òye kí ó má ba yé ọkàn wọn, kí wọn kí ó má ba yípadà kí a má ba mú wọn ní ara dá.”
11 Men jag sade: "För huru lång tid, Herre?" Han svarade: "Till dess att städerna bliva öde och utan någon invånare, och husen utan folk, och till dess att fälten ligga öde och förhärjade.
Nígbà náà ni mo wí pé, “Báwo ni yóò ti pẹ́ tó Olúwa?” Òun sì dáhùn pé: “Títí àwọn ìlú ńlá yóò fi dahoro, láìsí olùgbé nínú rẹ̀ mọ́, títí tí àwọn ilé yóò fi wà láìsí ènìyàn, títí tí ilẹ̀ yóò fi dahoro pátápátá.
12 Och när HERREN har fört folket bort i fjärran och ödsligheten bliver stor i landet,
Títí tí Olúwa yóò fi rán gbogbo wọn jìnnà réré tí ilẹ̀ náà sì di ìkọ̀sílẹ̀ pátápátá.
13 och allenast en tiondedel ännu är kvar däri, då skall denna ytterligare förödas såsom en terebint eller en ek av vilken en stubbe har lämnats kvar, när den fälldes. Den stubben skall vara en helig säd."
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìdámẹ́wàá ṣẹ́kù lórí ilẹ̀ náà, yóò sì tún pàpà padà di rírun. Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí igi tẹrẹbinti àti igi óákù, ti í fi kùkùté sílẹ̀ nígbà tí a bá gé wọn lulẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni irúgbìn mímọ́ náà yóò di kùkùté ní ilẹ̀ náà.”

< Jesaja 6 >