< 1 Kings 21 >

1 Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Naboti ará Jesreeli sì ní ọgbà àjàrà kan ní Jesreeli, ní ẹ̀gbẹ́ ààfin Ahabu ọba Samaria.
Po tych wydarzeniach miała miejsce taka sprawa: Nabot Jizreelita miał winnicę, która znajdowała się w Jizreel obok pałacu Achaba, króla Samarii.
2 Ahabu sì wí fún Naboti pé, “Fún mi ní ọgbà àjàrà rẹ, kí èmi kí ó fi ṣe ọgbà-ewébẹ̀, nítorí tí ó súnmọ́ tòsí ilé mi, èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà tí ó sàn jù ú lọ dípò rẹ̀; tàbí bí ó bá sì dára ní ojú rẹ, èmi yóò fi iye owó rẹ̀ fún ọ.”
I Achab powiedział do Nabota: Daj mi swoją winnicę, abym zrobił sobie z niej ogród warzywny, gdyż [leży] ona blisko mojego domu. Dam ci za nią lepszą winnicę albo – jeśli wolisz – dam ci pieniędzy według wartości.
3 Ṣùgbọ́n Naboti wí fún Ahabu pé, “Olúwa má jẹ́ kí èmi fi ogún àwọn baba mi fún ọ.”
Nabot odpowiedział Achabowi: Nie daj, PANIE, abym ci dał dziedzictwo swoich ojców.
4 Ahabu sì wá sí ilé rẹ̀, ó wugbọ́, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí ọ̀rọ̀ tí Naboti ará Jesreeli sọ fún un; nítorí tí ó wí pé, “Èmi kì yóò fún ọ ní ogún àwọn baba mi.” Ó sì dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀, ó sì yí ojú rẹ̀ padà, kò sì fẹ́ jẹun.
Achab przyszedł więc do swego domu smutny i zagniewany z powodu słów, które Nabot Jizreelita wypowiedział do niego: Nie dam ci dziedzictwa swoich ojców. I położył się na swoim łożu, odwrócił swoją twarz i nie jadł chleba.
5 Jesebeli aya rẹ̀ sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí inú rẹ fi bàjẹ́, èéṣe tí ìwọ kò sì jẹun?”
Wtedy przyszła do niego Jezabel, jego żona, i zapytała go: Czemu twój duch jest tak smutny, że nie [chcesz] jeść chleba?
6 Ó sì dá a lóhùn pé, “Nítorí tí mo wí fún Naboti ará Jesreeli pé, ‘Ta ọgbà àjàrà rẹ fún mi, tàbí bí ó bá wù ọ́, èmi yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mìíràn ní ipò rẹ̀.’ Ṣùgbọ́n ó wí pé, ‘Èmi kì yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mi.’”
Odpowiedział jej: Bo rozmawiałem z Nabotem Jizreelitą i powiedziałem mu: Daj mi swoją winnicę za pieniądze albo – jeśli chcesz – dam ci za nią [inną] winnicę. Lecz [on] odpowiedział: Nie dam ci swojej winnicy.
7 Jesebeli aya rẹ̀ sì wí pé, “Ṣé báyìí ni ìwọ yóò ṣe ṣe bí ọba lórí Israẹli? Dìde, jẹun! Kí o sì jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn. Èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà Naboti ará Jesreeli.”
Jego żona Jezabel powiedziała do niego: Czyż nie ty teraz sprawujesz [władzę] nad królestwem Izraela? Wstań, jedz chleb i bądź dobrej myśli. Ja dam ci winnicę Nabota Jizreelity.
8 Bẹ́ẹ̀ ni ó kọ̀wé ní orúkọ Ahabu, ó sì fi èdìdì rẹ̀ dì í, ó sì fi ìwé náà ránṣẹ́ sí àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí ó ń gbé ní ìlú Naboti pẹ̀lú rẹ̀.
Napisała więc listy w imieniu Achaba, opieczętowała [je] jego pieczęcią i wysłała te listy do starszych i do dostojników, którzy [byli] w jego mieście i mieszkali z Nabotem.
9 Nínú àwọn ìwé náà, ó kọ pé, “Ẹ kéde àwẹ̀, kí ẹ sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
W listach tak napisała: Ogłoście post i posadźcie Nabota przed ludem.
10 Ṣùgbọ́n kí ẹ fi ènìyàn méjì, ẹni búburú síwájú rẹ̀ láti jẹ́rìí sí i wí pé, ó bú Ọlọ́run àti ọba. Nígbà náà ni kí ẹ mú u jáde, kí ẹ sì sọ ọ́ ní òkúta pa.”
I postawcie przed nim dwóch synów Beliala, aby zaświadczyli przeciwko niemu, mówiąc: Złorzeczyłeś Bogu i królowi. Potem wyprowadźcie go i ukamienujcie, aby umarł.
11 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí wọ́n ń ṣe ará ìlú Naboti sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwé tí Jesebeli kọ ránṣẹ́ sí wọn.
I mężczyźni tego miasta, mianowicie starsi i dostojnicy mieszkający w jego mieście, uczynili tak, jak im poleciła Jezabel, zgodnie z tym, co [było] napisane w listach, które do nich wysłała.
12 Wọ́n sì kéde àwẹ̀, wọ́n sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
Ogłosili post i posadzili Nabota przed ludem.
13 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin méjì sì dé, àwọn ẹni búburú, wọ́n sì jókòó síwájú rẹ̀, wọ́n sì jẹ́rìí lòdì sí Naboti níwájú àwọn ènìyàn wí pé, “Naboti ti bú Ọlọ́run àti ọba.” Nígbà náà ni wọ́n mú jáde kúrò ní ìlú, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa.
Potem przyszło dwóch synów Beliala i usiadło przed nim. Ci niegodziwi ludzie zaświadczyli przeciwko niemu, [czyli] przeciw Nabotowi, przed ludem, mówiąc: Nabot złorzeczył Bogu i królowi. I wyprowadzili go za miasto, i ukamienowali go, i umarł.
14 Nígbà náà ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jesebeli wí pé, “A ti sọ Naboti ní òkúta, ó sì kú.”
I posłali do Jezabel wiadomość: Nabot został ukamienowany i umarł.
15 Bí Jesebeli sì ti gbọ́ pé, a ti sọ Naboti ní Òkúta pa, ó sì wí fún Ahabu pé, “Dìde! Kí o sì jogún ọgbà àjàrà Naboti, ará Jesreeli, tí ó kọ̀ láti tà fún ọ kò sí láààyè mọ́, ó ti kú.”
A gdy Jezabel usłyszała, że Nabot został ukamienowany i umarł, powiedziała do Achaba: Wstań, weź w posiadanie winnicę Nabota Jizreelity, której nie chciał dać ci za pieniądze. Nabot bowiem nie żyje, ale umarł.
16 Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ pé Naboti ti kú, ó sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún ọgbà àjàrà Naboti.
Kiedy Achab usłyszał, że Nabot umarł, wstał i poszedł do winnicy Nabota Jizreelity, aby ją wziąć w posiadanie.
17 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
Wtedy słowo PANA doszło do Eliasza Tiszbity:
18 “Sọ̀kalẹ̀ lọ láti lọ pàdé Ahabu ọba Israẹli, tí ó wà ní Samaria. Ó wà ní ọgbà àjàrà Naboti báyìí, níbi tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún rẹ̀.
Wstań, zejdź naprzeciw Achaba, króla Izraela, który przebywa w Samarii. Oto [jest] w winnicy Nabota, do której zszedł, aby ją wziąć w posiadanie.
19 Sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Ǹjẹ́ ìwọ kò ti pa ènìyàn, o sì ti fi agbára gba ogún rẹ̀?’ Nígbà náà ni kí o wí fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Níbi tí ajá gbé lá ẹ̀jẹ̀ Naboti, ni àwọn ajá yóò lá ẹ̀jẹ̀ rẹ, àní tìrẹ!’”
I powiesz takie słowa: Tak mówi PAN: Czy zabiłeś i wziąłeś w posiadanie? Powiesz mu jeszcze: Tak mówi PAN: Na miejscu, gdzie psy lizały krew Nabota, psy będą lizać twoją krew, właśnie twoją.
20 Ahabu sì wí fún Elijah pé, “Ìwọ ti rí mi, ìwọ ọ̀tá mi!” Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti rí ọ, nítorí tí ìwọ ti tan ara rẹ láti ṣe búburú níwájú Olúwa.
Achab powiedział do Eliasza: Już mnie znalazłeś, mój wrogu? Odpowiedział: Znalazłem, gdyż zaprzedałeś się, aby czynić zło na oczach PANA.
21 ‘Èmi yóò mú ibi wá sórí rẹ. Èmi yóò sì mú ìran rẹ kúrò, èmi yóò sì ké kúrò lọ́dọ̀ Ahabu gbogbo ọmọdé ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀, àti òmìnira ní Israẹli.
Oto sprowadzę na ciebie zło i usunę twoich potomków, i wytępię z domu Achaba każdego, aż do najmniejszego szczenięcia, każdego więźnia i opuszczonego w Izraelu.
22 Èmi yóò ṣe ilé rẹ bí ilé Jeroboamu, ọmọ Nebati, àti bí ilé Baaṣa, ọmọ Ahijah, nítorí ìwọ ti mú mi bínú, ìwọ sì ti mú Israẹli ṣẹ̀.’
I postąpię z twoim domem jak z domem Jeroboama, syna Nebata, i z domem Baszy, syna Achiasza, z powodu obrazy, którą pobudziłeś mnie do gniewu i przywiodłeś Izraela do grzechu.
23 “Àti ní ti Jesebeli pẹ̀lú Olúwa wí pé, ‘Àwọn ajá yóò jẹ Jesebeli nínú yàrá Jesreeli.’
Także o Jezabel PAN powiedział: Psy zjedzą Jezabel przy murze Jizreel.
24 “Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Ahabu tí ó kú ní ìlú, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ àwọn ẹni tí ó kú ní igbó.”
Tego, kto z domu Achaba umrze w mieście, zjedzą psy, a tego, kto umrze na polu, zjedzą ptaki powietrzne.
25 (Kò sí ẹnìkan bí Ahabu tí ó ta ara rẹ̀ láti ṣe búburú níwájú Olúwa, ẹni tí Jesebeli aya rẹ̀ ń tì.
Nie było bowiem nikogo takiego jak Achab, kto by się zaprzedał, aby czynić niegodziwość na oczach PANA, do czego skłoniła go Jezabel, jego żona.
26 Ó sì ṣe ohun ìríra gidigidi ní tí tọ òrìṣà lẹ́yìn, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí àwọn ará Amori ti ṣe, tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.)
Postępował bardzo obrzydliwie, chodząc za bożkami całkowicie tak samo, jak czynili Amoryci, których PAN wygnał przed synami Izraela.
27 Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ sí ara rẹ̀, ó sì gbààwẹ̀. Ó sì dùbúlẹ̀ nínú aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ń lọ jẹ́ẹ́.
Kiedy Achab usłyszał te słowa, rozdarł swoje szaty, włożył wór na swoje ciało, pościł, spał w worze i chodził pokornie.
28 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
Wtedy słowo PANA doszło do Eliasza Tiszbity:
29 “Ǹjẹ́ ìwọ ti rí bí Ahabu ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú mi? Nítorí tí ó ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀, èmi kì yóò mú ibi náà wá ní ọjọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò mú u wá sí ilé rẹ̀ ní ọjọ́ ọmọ rẹ̀.”
Czy widziałeś, jak Achab upokorzył się przede mną? Ponieważ upokorzył się przede mną, nie sprowadzę tego nieszczęścia za jego dni; [ale] sprowadzę nieszczęście na jego dom za dni jego syna.

< 1 Kings 21 >