< 1 Samuel 12 >

1 Samuẹli sì wí fún gbogbo Israẹli pé, “Èmi tí gbọ́ gbogbo ohun tí ẹ sọ fún mi, èmi sì ti yan ọba fún un yín.
Samuel je rekel vsemu Izraelu: »Glejte, prisluhnil sem vašemu glasu v vsem, kar ste mi rekli in postavil sem kralja nad vami.
2 Nísinsin yìí ẹ ti ní ọba bí olórí yín. Bí ó ṣe tèmi, èmi ti di arúgbó, mo sì ti hewú, àwọn ọmọ mi sì ń bẹ níhìn-ín yìí pẹ̀lú yín. Èmi ti ń ṣe olórí yín láti ìgbà èwe mi wá títí di òní yìí.
In sedaj glejte, kralj hodi pred vami. Jaz pa sem starec in sivolas in glejte, moja sinova sta z vami. Hodil sem pred vami od svojega otroštva, do tega dne.
3 Èmi dúró níhìn-ín yìí, ẹ jẹ́rìí sí mi níwájú Olúwa àti níwájú ẹni àmì òróró rẹ̀. Màlúù ta ni mo gbà rí? Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ta ni mo gbà rí? Ta ni mo rẹ́ jẹ rí? Ọwọ́ ta ni mo ti gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ kan rí láti fi bo ara mi lójú? Bí mo bá ti ṣe nǹkan kan nínú ohun wọ̀nyí, èmi yóò sì san án padà fún yín.”
Glejte, tukaj sem. Pričujte zoper mene pred Gospodom in pred njegovim maziljencem. Čigavega vola sem vzel? Ali čigavega osla sem vzel? Ali sem koga ogoljufal? Koga sem zatiral? Ali iz čigave roke sem sprejel kakršnokoli podkupnino, da bi mi s tem zaslepil oči? In povrnil vam bom.«
4 Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Ìwọ kò rẹ́ wa jẹ tàbí pọ́n wa lójú rí, ìwọ kò sì gba ohunkóhun lọ́wọ́ ẹnìkankan.”
Rekli so: »Nisi nas ogoljufal niti nas nisi zatiral niti nisi vzel karkoli iz roke kateregakoli moža.«
5 Samuẹli sì wí fún wọn pé, “Olúwa ni ẹlẹ́rìí sí i yín, àti ẹni àmì òróró rẹ̀ ni ẹlẹ́rìí lónìí pé, ẹ̀yin kò rí ohunkóhun lọ́wọ́ mi.” Wọ́n sì sọ wí pé, “Òun ni ẹlẹ́rìí.”
Rekel jim je: » Gospod je priča zoper vas in njegov maziljenec je priča ta dan, da v moji roki niste našli ničesar.« Odgovorili so: » On je priča.«
6 Nígbà náà ni Samuẹli wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Olúwa ni ó yan Mose àti Aaroni àti ti ó mú àwọn baba ńlá yín gòkè wá láti Ejibiti.
Samuel je ljudstvu rekel: » Gospod je ta, ki je določil Mojzesa in Arona in ki je vaše očete privedel gor iz egiptovske dežele.
7 Nísinsin yìí, ẹ dúró níbi, nítorí èmi ń lọ láti bá a yín sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa ní ti gbogbo ìṣe òdodo rẹ̀ tí ó ti ṣe fún un yín àti fún àwọn baba yín.
Zdaj torej mirno stojte, da se bom lahko pravdal z vami pred Gospodom o vseh pravičnih dejanjih Gospoda, ki jih je storil vam in vašim očetom.
8 “Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu wọ Ejibiti, wọ́n ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa sì rán Mose àti Aaroni, tí wọ́n mú àwọn baba ńlá yín jáde láti Ejibiti láti mú wọn jókòó níbí yìí.
Ko je Jakob prišel v Egipt in so vaši očetje klicali h Gospodu, potem jim je Gospod poslal Mojzesa in Arona, ki sta vaše očete privedla ven iz Egipta in jim dala prebivati na tem kraju.
9 “Ṣùgbọ́n wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì tà wọ́n sí ọwọ́ àwọn Sisera, olórí ogun Hasori, àti sí ọwọ́ àwọn Filistini àti sí ọwọ́ ọba Moabu, tí ó bá wọn jà.
Ko pa so pozabili Gospoda, svojega Boga, jih je prodal v roko Siserája, poveljnika Hacórjeve vojske in v roko Filistejcev in v roko moábskega kralja in so se borili zoper njih.
10 Wọ́n kégbe pe Olúwa, wọ́n sì wí pé, ‘Àwa ti ṣẹ̀; a ti kọ Olúwa sílẹ̀, a sì ti sin Baali, àti Aṣtoreti. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, àwa yóò sì sìn ọ́.’
Klicali so h Gospodu in rekli: ›Grešili smo, ker smo zapustili Gospoda in smo služili Báalom in Astarti. Toda sedaj nas osvobodi iz roke naših sovražnikov in mi ti bomo služili.‹
11 Nígbà náà ni Olúwa rán Jerubbaali, Bedani, Jefta àti Samuẹli, ó sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá a yín gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ń gbé ní àlàáfíà.
Gospod je poslal Jerubáala, Bedána, Jefteja in Samuela in vas osvobodil iz roke vaših sovražnikov na vsaki strani in vi ste varno prebivali.
12 “Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin sì rí i pé Nahaṣi ọba àwọn Ammoni dìde sí i yín, ẹ sọ fún mi pé, ‘Rárá, àwa ń fẹ́ ọba tí yóò jẹ́ lórí wa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run yín jẹ́ ọba yín.
Ko pa ste videli, da je proti vam prišel Naháš, kralj Amónovih otrok, ste mi rekli: ›Ne, temveč bo kralj kraljeval nad nami.‹ Ko je bil Gospod, vaš Bog, vaš kralj.
13 Nísinsin yìí èyí ni ọba tí ẹ̀yin ti yàn, tí ẹ̀yin béèrè fún; wò ó, Olúwa ti fi ọba jẹ lórí yín.
Zdaj torej glejte kralja, ki ste ga izbrali in ki ste si ga želeli! In glejte, Gospod je postavil kralja nad vami.
14 Bí ẹ̀yin bá bẹ̀rù Olúwa àti bí ẹ̀yin bá ń sìn ín, tí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, tí ẹ̀yin kò sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, àti tí ẹ̀yin àti ọba tí ó jẹ lórí yín bá ń tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín: ó dára
Če se boste bali Gospoda in mu služili in ubogali njegov glas in se ne boste uprli zoper Gospodovo zapoved, potem boste tako vi kot vaš kralj, ki kraljuje nad vami, še naprej sledili Gospodu, svojemu Bogu.
15 ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá gbọ́ tí Olúwa, tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀, ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára yín sí ibi, bí ó ti wà lára baba yín.
Toda če ne boste ubogali glasu Gospoda, temveč se boste uprli zoper Gospodovo zapoved, potem bo Gospodova roka zoper vas, kakor je bila zoper vaše očete.
16 “Nítorí náà, ẹ dúró jẹ́ẹ́ kí ẹ sì wo ohun ńlá yìí tí Olúwa fẹ́ ṣe ní ojú u yín!
Zdaj torej stojte in vidite to veliko stvar, ki jo bo Gospod storil pred vašimi očmi.
17 Òní kì í ha á ṣe ọjọ́ ìkórè ọkà alikama bí? Èmi yóò ké pe Olúwa kí ó rán àrá àti òjò. Ẹ̀yin yóò sì mọ irú ohun búburú tí ẹ ti ṣe níwájú Olúwa nígbà tí ẹ̀ ń béèrè fún ọba.”
Mar ni danes pšenična žetev? Klical bom h Gospodu in poslal bo grmenje in dež, da boste lahko zaznali in videli, da je vaša zlobnost velika, ki ste jo storili v Gospodovih očeh, v tem, da ste si zahtevali kralja.«
18 Nígbà náà ni Samuẹli ké pe Olúwa, Olúwa sì rán àrá àti òjò ní ọjọ́ náà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa àti Samuẹli púpọ̀.
Tako je Samuel zaklical h Gospodu in Gospod je ta dan poslal grmenje in dež, in vse ljudstvo se je silno balo Gospoda in Samuela.
19 Gbogbo àwọn ènìyàn sì wí fún Samuẹli pé, “Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ kí a má ba à kú, nítorí tí àwa ti fi búburú yìí kún ẹ̀ṣẹ̀ wa ní bíbéèrè fún ọba.”
Vse ljudstvo je reklo Samuelu: »Moli za svoje služabnike h Gospodu, svojemu Bogu, da ne umremo, kajti vsem svojim grehom smo dodali to zlo, da smo si zahtevali kralja.«
20 Samuẹli sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ ti ṣe gbogbo búburú yìí; síbẹ̀ ẹ má ṣe yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n ẹ fi gbogbo àyà yín sin Olúwa.
Samuel je ljudstvu rekel: »Ne bojte se. Storili ste vso to zlobnost, vendar se ne obrnite stran od sledenja Gospodu, temveč z vsem svojim srcem služite Gospodu
21 Ẹ má ṣe yípadà sọ́dọ̀ àwọn òrìṣà. Wọn kò le ṣe ohun rere kan fún un yín, tàbí kí wọ́n gbà yín là, nítorí asán ni wọ́n.
in ne obrnite se stran, kajti potem bi šli za praznimi stvarmi, ki ne morejo koristiti niti osvoboditi, kajti prazne so.
22 Nítorí orúkọ ńlá rẹ̀ Olúwa kì yóò kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀, nítorí tí inú Olúwa dùn láti fi yín ṣe ènìyàn rẹ̀.
Kajti Gospod ne bo zapustil svojega ljudstva zaradi svojega veličastnega imena, ker je Gospodu ugajalo, da vas naredi za svoje ljudstvo.
23 Bí ó ṣe ti èmi ni, kí á má rí i pé èmi dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa dídẹ́kun àti gbàdúrà fún un yín. Èmi yóò sì kọ́ ọ yín ní ọ̀nà rere àti ọ̀nà òtítọ́.
Poleg tega, kar se mene tiče, Bog ne daj, da bi grešil zoper Gospoda v [tem], da bi prenehal moliti za vas, temveč vas bom učil dobro in pravilno pot.
24 Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé, ẹ bẹ̀rù Olúwa, kí ẹ sì sìn ín nínú òtítọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn an yín, ẹ kíyèsi ohun ńlá tí ó ti ṣe fún un yín.
Samo bojte se Gospoda in mu služite v resnici, z vsem svojim srcem, kajti preudarite kako velike stvari je storil za vas.
25 Síbẹ̀ bí ẹ̀yin bá ń ṣe búburú, ẹ̀yin àti ọba yín ni a ó gbá kúrò.”
Toda če boste še vedno počeli zlobno, boste použiti, tako vi kakor vaš kralj.«

< 1 Samuel 12 >