< 2 Kings 22 >

1 Josiah jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jedida ọmọbìnrin Adaiah; ó wá láti Boskati.
Osam godina bijaše Josiji kad poèe carovati, i carova trideset i jednu godinu u Jerusalimu. Materi mu bješe ime Jedida, kæi Adajeva, iz Voskata.
2 Ó sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Dafidi baba a rẹ̀, kò sì yípadà sí apá ọ̀tún tàbí sí apá òsì.
On èinjaše što je pravo pred Gospodom, i hoðaše svijem putem Davida oca svojega i ne otstupaše ni nadesno ni nalijevo.
3 Ní ọdún kejìdínlógún tí ó fi jẹ ọba. Ọba Josiah rán akọ̀wé, Ṣafani ọmọ Asalia, ọmọ Meṣullamu, sí ilé Olúwa. Ó wí pé,
A osamnaeste godine carovanja Josijina posla car Safana sina Azalije sina Mesulamova, pisara, u dom Gospodnji, govoreæi:
4 “Gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, kí o sì jẹ́ kí ó ṣírò iye owó tí a mú wá sí ilé Olúwa, tí àwọn olùṣọ́nà ti gbà lọ́wọ́ àwọn ènìyàn.
Idi ka Helkiji poglavaru sveštenièkom, neka izbroji novce donesene u dom Gospodnji, što su nakupili od naroda vratari.
5 Ẹ sì jẹ́ kí wọn ó fi lé àwọn ọkùnrin tí a ti yàn láti bojútó iṣẹ́ náà lórí ilé Olúwa. Kí ẹ sì jẹ́ kí àwọn ọkùnrin san án fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń tún ilé Olúwa ṣe.
I neka ih da poslenicima koji nadgledaju dom Gospodnji, pa neka daju poslenicima koji rade oko doma Gospodnjega da se opravi što je trošno u domu,
6 Àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àwọn ọ̀mọ̀lé àti àwọn akọ́lé. Bákan náà ni wọ́n ra igi àti òkúta ọlọ́ṣọ̀ọ́ láti fi tún tẹmpili ṣe.
Drvodjeljama i kamenarima i zidarima, i da se kupuje drvo i kamen tesani da se opravi dom.
7 Ṣùgbọ́n wọn kò ní láti ṣe ìṣirò fún owó náà tí a fi fún wọn, nítorí wọ́n ṣe òtítọ́.”
Ali da im se ne traže raèuni od novaca koji im se dadu, jer æe vjerno raditi.
8 Hilkiah olórí àlùfáà sọ fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi rí ìwé òfin nílé Olúwa.” Ó fi fún Ṣafani, ẹni tí ó kà á.
Tada reèe Helkija poglavar sveštenièki Safanu pisaru: naðoh zakonik u domu Gospodnjem. I Helkija dade knjigu Safanu, i on je proèita.
9 Nígbà náà, Ṣafani akọ̀wé lọ sí ọ̀dọ̀ ọba. Ó sì sọ fún un pé, “Àwọn ìjòyè rẹ ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa. Èmi sì ti fi lé ọwọ́ àwọn tí ó ń ṣe iṣẹ́ náà àti àwọn alábojútó nílé Olúwa.”
A Safan pisar otide k caru, i javi caru govoreæi: pokupiše sluge tvoje novce što se naðoše u domu, predaše ih poslenicima koji nadgledaju dom Gospodnji.
10 Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sọ fún ọba pé, “Hilkiah àlùfáà ti fún un ní ìwé kan.” Ṣafani kà lára rẹ̀ níwájú ọba.
I kaza Safan pisar caru govoreæi: knjigu mi dade Helkija sveštenik. I proèita je Safan caru.
11 Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
A kad car èu rijeèi u zakoniku, razdrije haljine svoje.
12 Ó pa àṣẹ yìí fún Ahikamu àlùfáà, Hilkiah ọmọ Ṣafani, Akbori ọmọ Mikaiah, àti Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
I zapovjedi car Helkiji svešteniku i Ahikamu sinu Safanovu i Ahvoru sinu Mihejinu i Safanu pisaru i Asaji sluzi carevu, govoreæi:
13 “Lọ, ẹ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi àti fún àwọn ènìyàn àti fún gbogbo Juda nípa ohun tí a kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ń jó sí wa nítorí àwọn baba wa kò tẹ̀lé ọ̀rọ̀ inú ìwé yìí; wọn kò ṣe ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ níbẹ̀ nípa wa.”
Idite, upitajte Gospoda za me i za narod i za svega Judu radi rijeèi ove knjige što se naðe; jer je velik gnjev Gospodnji koji se raspalio na nas zato što oci naši ne slušaše rijeèi ove knjige da èine sve onako kako nam je napisano.
14 Hilkiah àlùfáà, Ahikamu àti Akbori Ṣafani pẹ̀lú Asaiah, lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì obìnrin Hulda láti lọ bá a sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tikfa ọmọ Harhasi alábojútó ibi ìpa aṣọ mọ́ sí. Ó ń gbé ní Jerusalẹmu ní ìdàkejì.
I tako otide Helkija sveštenik i Ahikam i Ahvor i Safan i Asaja k proroèici Oldi ženi Saluma sina Tekuja sina Arasa riznièara; a ona stajaše u Jerusalimu u drugom kraju; i govoriše s njom.
15 Ó wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, Sọ fún ọkùnrin tí ó rán an yín sí mi,
A ona im reèe: ovako veli Gospod Bog Izrailjev: kažite èovjeku koji vas je poslao k meni:
16 ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Èmi yóò mú ibi wá sí ibí àti àwọn ènìyàn rẹ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú ìwé tí ọba Juda ti kà.
Ovako veli Gospod: evo pustiæu zlo na to mjesto i na stanovnike njegove, sve što govori knjiga koju je proèitao car Judin,
17 Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, wọ́n sì tún sun tùràrí fún ọlọ́run mìíràn. Wọ́n sì mú mi bínú nípa gbogbo àwọn òrìṣà tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn dá. Ìbínú mi yóò ru sí ibí yìí, kì yóò sì rọlẹ̀.’
Zato što me ostaviše, i kadiše drugim bogovima da bi me gnjevili svijem djelima ruku svojih; zato se gnjev moj raspalio na to mjesto, i neæe se ugasiti.
18 Sọ fún ọba Juda tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí nípa ọ̀rọ̀ wọ̀n-ọn-nì tí ìwọ ti gbọ́.
A caru Judinu, koji vas je poslao da upitate Gospoda, ovako mu kažite: ovako veli Gospod Bog Izrailjev za rijeèi koje si èuo:
19 Nítorí tí ọkàn rẹ rọ̀, tí ìwọ sì ti rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa, nígbà tí ìwọ gbọ́ èyí tí mo sọ sí ibí yìí àti sí àwọn ènìyàn rẹ pé wọn yóò di ahoro àti ẹni ègún tí ìwọ sì fa aṣọ ọ̀ rẹ ya pẹ̀lú níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ, ni Olúwa wí.
Što je umeknulo srce tvoje, i ponizio si se pred Gospodom kad si èuo šta sam govorio za to mjesto i za stanovnike njegove da æe biti pustoš i prokletinja, i što si razdro haljine svoje i plakao preda mnom, zato i ja usliših tebe, veli Gospod.
20 Nítorí náà èmi yóò kó ọ jọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baba à rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kì yóò rí gbogbo àwọn ibi tí èmi yóò mú wá bá ibí yìí.’” Bẹ́ẹ̀ wọ́n mú èsì rẹ̀ padà tọ ọba wá.
Zato, evo, ja æu te pribrati k ocima tvojim i na miru æeš biti pribran u grob svoj, i neæeš oèima svojim vidjeti zla koje æu pustiti na to mjesto. I kazaše to caru.

< 2 Kings 22 >