< Hosea 5 >

1 “Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yìn àlùfáà! Ẹ fetísílẹ̀ ẹ̀yin ọmọ Israẹli! Ẹ gbọ́, ẹ̀yìn ilé ọba! Ìdájọ́ yìí kàn yín. Ẹ ti jẹ́ ẹ̀bìtì ní Mispa àwọ̀n ti a nà sílẹ̀ lórí Tabori.
O ye Priestes, heare this, and hearken ye, O house of Israel, and giue ye eare, O house of the King: for iudgement is towarde you, because you haue bene a snare on Mizpah, and a net spred vpon Tabor.
2 Àwọn ọlọ̀tẹ̀ ti gbilẹ̀ nínú ìpànìyàn gbogbo wọn ni èmi ó bá wí,
Yet they were profounde, to decline to slaughter, though I haue bene a rebuker of them all.
3 mo mọ ohun gbogbo nípa Efraimu Israẹli kò sì pamọ́ fún mi Efraimu, ní báyìí ó ti ṣe àgbèrè Israẹli sì ti díbàjẹ́.
I knowe Ephraim, and Israel is not hid from me: for nowe, O Ephraim thou art become an harlot, and Israel is defiled.
4 “Ìṣe wọn kò gbà wọ́n láààyè láti padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wọn. Ẹ̀mí àgbèrè wà ni ọkàn wọn, wọn kò sì mọ Olúwa.
They will not giue their mindes to turne vnto their God: for the spirit of fornication is in the middes of them, and they haue not knowen the Lord.
5 Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí lé wọn; àwọn ọmọ Israẹli, àti Efraimu pàápàá kọsẹ̀ nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Juda náà sì kọsẹ̀ pẹ̀lú wọn.
And the pride of Israel doth testifie to his face: therefore shall Israel and Ephraim fall in their iniquitie: Iudah also shall fall with them.
6 Nígbà tí wọ́n bá lọ pẹ̀lú agbo ẹran àti ọ̀wọ́ ẹran wọn láti wá Olúwa, wọn kò ní rí i, ó ti yọ ara rẹ̀ kúrò láàrín wọn.
They shall goe with their sheepe, and with their bullockes to seeke the Lord: but they shall not finde him: for he hath withdrawne himselfe from them.
7 Wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Olúwa wọ́n sì bí àwọn àjèjì ọmọ. Nísinsin yìí, ọdún oṣù tuntun wọn, ni yóò pa wọn run pẹ̀lú ìpín wọn.
They haue transgressed against the Lord: for they haue begotte strange children: now shall a moneth deuoure them with their portions.
8 “Fọn fèrè ní Gibeah, kí ẹ sì fun ìpè ní Rama. Ẹ pariwo ogun ní Beti-Afeni; máa wárìrì, ìwọ Benjamini.
Blowe ye the trumpet in Gibeah, and the shaume in Ramah: crie out at Beth-auen, after thee, O Beniamin.
9 Efraimu yóò di ahoro ní ọjọ́ ìbáwí láàrín àwọn ẹ̀yà Israẹli, Mo sọ ohun tí ó dájú.
Ephraim shall be desolate in the day of rebuke: among the tribes of Israel haue I caused to knowe the trueth.
10 Àwọn olórí Juda dàbí àwọn tí í máa yí òkúta ààlà kúrò. Èmi ó tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí bí ìkún omi.
The princes of Iudah were like them that remoue the bounde: therefore will I powre out my wrath vpon them like water.
11 A ni Efraimu lára, a sì tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ìdájọ́, nítorí pé, ó pinnu láti tẹ̀lé òrìṣà.
Ephraim is oppressed, and broken in iudgement, because he willingly walked after the commandement.
12 Mo dàbí kòkòrò aṣọ sí Efraimu, Mo sì dàbí ìdin ara Juda.
Therefore wil I be vnto Ephraim as a moth, and to the house of Iudah as a rottennesse.
13 “Nígbà ti Efraimu ri àìsàn rẹ̀, tí Juda sì rí ojú egbò rẹ̀ ni Efraimu bá tọ ará Asiria lọ, ó sì ránṣẹ́ sí ọba ńlá náà fún ìrànlọ́wọ́. Ṣùgbọ́n kò le è wò ó sàn bẹ́ẹ̀ ni kò le wo ojú egbò rẹ̀ jinná.
When Ephraim sawe his sickenes, and Iudah his wound, then went Ephraim vnto Asshur, and sent vnto King Iareb: yet coulde hee not heale you, nor cure you of your wound.
14 Nítorí pé, èmi ó dàbí kìnnìún sí Efraimu, bí i kìnnìún ńlá sí ilé Juda. Èmi ó fà wọ́n ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ èmi ó sì lọ; Èmi ó gbé wọn lọ, láìsí ẹni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀.
For I will be vnto Ephraim as a lyon, and as a lyons whelpe to the house of Iudah: I, euen I will spoyle, and goe away: I will take away, and none shall rescue it.
15 Nígbà náà ni èmi ó padà lọ sí ààyè mi títí di ìgbà tí wọn ó fi gbà pé àwọn jẹ̀bi wọn yóò sì wá ojú mi nínú ìpọ́njú wọn, wọn ó fi ìtara wá mi.”
I will go, and returne to my place, til they acknowledge their fault, and seeke me: in their affliction they will seeke me diligently.

< Hosea 5 >