< Jeremiah 10 >

1 Gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ fún yín ẹ̀yin ilé Israẹli.
Słuchajcie słowa, które PAN mówi do was, domu Izraela!
2 Báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe kọ́ ìwà àwọn kèfèrí, kí àmì ọ̀run kí ó má sì dààmú yín, nítorí pé wọ́n ń dààmú orílẹ̀-èdè.
Tak mówi PAN: Nie uczcie się drogi pogan i nie bójcie się znaków na niebie, bo to poganie ich się boją.
3 Nítorí pé asán ni àṣà àwọn ènìyàn, wọ́n gé igi láti inú igbó, oníṣọ̀nà sì gbẹ́ ẹ pẹ̀lú àáké rẹ̀.
Zwyczaje tych narodów są bowiem marnością, gdyż drzewo ścinają w lesie siekierą, dzieło rąk rzemieślnika;
4 Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe é lọ́ṣọ̀ọ́. Wọ́n fi òòlù kàn án àti ìṣó kí ó má ba à ṣubú.
Przyozdabiają je srebrem i złotem, przytwierdzają je gwoździami i młotkiem, aby się nie chwiało.
5 Wọ́n wé mọ́ igi bí ẹ̀gúnsí inú oko, òrìṣà wọn kò le è fọhùn. Wọ́n gbọdọ̀ máa gbé wọn nítorí pé wọn kò lè rìn. Má ṣe bẹ̀rù wọn; wọn kò le è ṣe ibi kankan bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si lè ṣe rere kan.”
Stoją prosto jak palma, ale nie mówią. Trzeba je nosić, bo nie mogą chodzić. Nie bójcie się ich, bo nie mogą czynić nic złego ani nic dobrego.
6 Kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ Olúwa; o tóbi orúkọ rẹ sì tóbi lágbára.
Nie ma nikogo jak ty, PANIE! Ty jesteś wielki i wielkie jest w mocy twoje imię.
7 Ta ni kò yẹ kí ó bẹ̀rù rẹ? Ọba àwọn orílẹ̀-èdè? Nítorí tìrẹ ni. Láàrín àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní orílẹ̀-èdè àti gbogbo ìjọba wọn, kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ.
Któż by się ciebie nie bał, Królu narodów? Tobie bowiem to się należy, ponieważ pośród wszystkich mędrców narodów i we wszystkich ich królestwach nie ma nikogo jak ty.
8 Gbogbo wọn jẹ́ aláìlóye àti aṣiwèrè, wọ́n ń kọ́ ẹ̀kọ́ àwọn ère igi tí kò níláárí.
Wszyscy razem są głupi i nierozumni; czerpanie nauki z drewna to całkowita marność.
9 Fàdákà tí a ti kàn ni a mú wá láti Tarṣiṣi, àti wúrà láti Upasi. Èyí tí àwọn oníṣọ̀nà àti alágbẹ̀dẹ ṣe tí wọ́n kùn ní àwọ̀ aró àti elése àlùkò, èyí jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n oníṣọ̀nà.
Srebro sklepane, przywiezione z Tarszisz, a złoto z Ufas – dzieło rzemieślnika i rąk złotnika. Ich szaty z błękitu i purpury, wszystko to jest dziełem uzdolnionych rzemieślników.
10 Ṣùgbọ́n Olúwa ni Ọlọ́run tòótọ́, òun ni Ọlọ́run alààyè, ọba ayérayé. Nígbà tí ó bá bínú, ayé yóò wárìrì; orílẹ̀-èdè kò lè fi ara da ìbínú rẹ̀.
Ale PAN jest prawdziwym Bogiem, jest Bogiem żywym i królem wiecznym. Od jego gniewu drży ziemia, a narody nie mogą znieść jego oburzenia.
11 “Sọ èyí fún wọn: ‘Àwọn ọlọ́run kéékèèké tí kò dá ọ̀run àti ayé ni yóò ṣègbé láti ayé àti ní abẹ́ ọ̀run.’”
Tak więc im powiecie: Ci bogowie, którzy nie stworzyli nieba i ziemi, znikną z ziemi i spod nieba.
12 Ọlọ́run dá ayé pẹ̀lú agbára rẹ̀, ó dá àgbáyé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, ó mú kí ọ̀run kí ó fẹ̀ síta nípa òye rẹ̀.
On uczynił ziemię swoją mocą, utwierdził okrąg świata swoją mądrością i swoją roztropnością rozpostarł niebiosa.
13 Nígbà tí ó bá sán àrá, àwọn omi lọ́run a sì pariwo; ó mú kí ìkùùkuu ru sókè láti òpin ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì ń mú afẹ́fẹ́ wá láti ilé ìṣúra rẹ̀.
Gdy on wydaje głos, huczą wody w niebiosach, on sprawia, że chmury wznoszą się z krańców ziemi; czyni błyskawice z deszczem i wyprowadza wiatr ze swoich skarbców.
14 Gbogbo ènìyàn jẹ́ aṣiwèrè àti aláìnímọ̀, ojú ti gbogbo alágbẹ̀dẹ níwájú ère rẹ̀, nítorí ère dídá rẹ̀ èké ni, kò sì ṣí ẹ̀mí nínú rẹ̀.
Każdy człowiek jest głupcem i nie wie, że każdy złotnik jest okryty hańbą z powodu posągu, bo jego odlany posąg jest fałszem i nie ma w nich ducha.
15 Asán ni wọ́n, iṣẹ́ ìṣìnà; nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn yóò ṣègbé.
Są marnością i dziełem błędów; w czasie swego nawiedzenia zginą.
16 Ẹni tí ó bá jẹ́ ìpín Jakọbu kò sì dàbí èyí, nítorí òun ni ó ṣẹ̀dá ohun gbogbo àti Israẹli tí ó jẹ́ ẹ̀yà ìjogún rẹ̀. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Nie takim jak one jest dział Jakuba, bo on jest Stwórcą wszystkiego, a Izrael jest szczepem jego dziedzictwa. PAN zastępów – to jego imię.
17 Kó ẹrù rẹ kúrò láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀ ìwọ tí o ń gbé ní ìlú tí a dó tì.
Pozbieraj z ziemi swoje towary, ty, która mieszkasz w miejscu warownym.
18 Nítorí èyí ni Olúwa wí: “Ní àkókò yìí, èmi yóò gbọn àwọn tí ó ń gbé ilẹ̀ náà jáde. Èmi yóò mú ìpọ́njú bá wọn, kí wọn kí ó lè rí wọn mú.”
Tak bowiem mówi PAN: Oto ja tym razem [jak] z procy cisnę w mieszkańców tej ziemi i udręczę ich, aby tego doznali.
19 Ègbé ni fún mi nítorí ìpalára mi! Ọgbẹ́ mi jẹ́ èyí tí kò lè sàn, bẹ́ẹ̀ ni mọ sọ fún ara mi, “Èyí ni àìsàn mi, mo sì gbọdọ̀ fi orí tì í.”
Biada mi z powodu mego zniszczenia, moja rana jest bolesna, ale mówiłem: Właśnie to jest moje cierpienie, muszę je znieść.
20 Àgọ́ mi bàjẹ́, gbogbo okùn rẹ̀ sì já. Àwọn ọmọ mi ti lọ lọ́dọ̀ mi, wọn kò sì sí mọ́, kò sí ẹnìkankan tí yóò na àgọ́ mi ró mọ́, tàbí yóò ṣe ibùgbé fún mi.
Mój namiot został zburzony i wszystkie moje powrozy są zerwane. Moi synowie odeszli ode mnie i nie ma ich. Nie ma już nikogo, kto by rozbił mój namiot i rozciągnął moje zasłony.
21 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn jẹ́ aṣiwèrè, wọn kò sì wá Olúwa: nítorí náà wọn kì yóò ṣe rere àti pé gbogbo agbo wọn ni yóò túká.
Pasterze bowiem stali się głupi i nie szukali PANA. Dlatego im się nie powiedzie, a cała ich trzoda zostanie rozproszona.
22 Fetísílẹ̀! ariwo igbe ń bọ̀, àti ìdàrúdàpọ̀ ńlá láti ilẹ̀ àríwá wá! Yóò sì sọ ìlú Juda di ahoro, àti ihò ọ̀wàwà.
Oto nadchodzi wieść i wielka wrzawa z ziemi północnej, aby miasta Judy zamienić w pustkowie i w siedlisko smoków.
23 Èmi mọ̀ Olúwa wí pé ọ̀nà ènìyàn kì í ṣe ti ara rẹ̀, kì í ṣe fún ènìyàn láti tọ́ ìgbésẹ̀ ara rẹ̀.
Wiem, PANIE, że droga człowieka nie zależy od niego ani nie [leży w mocy] człowieka kierować swoimi krokami, gdy chodzi.
24 Tún mi ṣe Olúwa, pẹ̀lú ìdájọ́ nìkan kí o má sì ṣe é nínú ìbínú rẹ, kí ìwọ má ṣe sọ mí di òfo.
Karć mnie, PANIE, ale według słusznej miary, nie w swym gniewie, abyś mnie nie zniszczył.
25 Tú ìbínú rẹ jáde sórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò mọ̀ ọ́n, sórí àwọn ènìyàn tí wọn kò pe orúkọ rẹ. Nítorí pé wọ́n ti jẹ Jakọbu run, wọ́n ti jẹ ẹ́ run pátápátá, wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ̀ di ahoro.
Wylej swoją zapalczywość na te narody, które cię nie znają, i na rody, które nie wzywają twego imienia. Pochłonęły bowiem Jakuba i pożarły go, strawiły go, a jego mieszkanie zamieniły w pustkowie.

< Jeremiah 10 >