< Luke 22 >

1 Àjọ ọdún àìwúkàrà tí à ń pè ní Ìrékọjá sì kù fẹ́ẹ́rẹ́.
Estava se aproximando a Festa dos Pães sem Fermento, também conhecida como Páscoa.
2 Àti àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn akọ̀wé ń wá ọ̀nà tí wọn ìbá gbà pa á; nítorí tí wọn ń bẹ̀rù àwọn ènìyàn.
Os chefes dos sacerdotes e os educadores religiosos estavam tentando encontrar um modo de matar Jesus, mas tinham medo da reação das pessoas.
3 Satani sì wọ inú Judasi, tí à ń pè ní Iskariotu, ọ̀kan nínú àwọn méjìlá.
Satanás entrou em Judas Iscariotes, um dos doze discípulos.
4 Ó sì mú ọ̀nà rẹ̀ pọ̀n, ó lọ láti bá àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olórí ẹ̀ṣọ́ gbèrò pọ̀, bí òun yóò tí fi í lé wọn lọ́wọ́.
Ele se encontrou com os chefes dos sacerdotes e com os oficiais da guarda, para falar sobre como poderia trair Jesus.
5 Wọ́n sì yọ̀, wọ́n sì bá a dá májẹ̀mú láti fún un ní owó.
Eles ficaram felizes e lhe ofereceram dinheiro.
6 Ó sì gbà; ó sì ń wá àkókò tí ó wọ̀, láti fi í lé wọn lọ́wọ́ láìsí ariwo.
Ele concordou e começou a procurar uma oportunidade para entregar Jesus quando não houvesse muita gente em torno dele.
7 Ọjọ́ àìwúkàrà pé, nígbà tí wọ́n ní láti pa ọ̀dọ́-àgùntàn ìrékọjá fún ìrúbọ.
Chegou o dia da Festa dos Pães sem Fermento, quando se sacrificavam cordeiros para comemorar a Páscoa.
8 Ó sì rán Peteru àti Johanu, wí pé, “Ẹ lọ pèsè ìrékọjá fún wa, kí àwa ó jẹ.”
Jesus enviou Pedro e João, dizendo-lhes: “Vão e preparem a refeição da Páscoa. Assim, poderemos comer juntos.”
9 Wọ́n sì wí fún un pé, “Níbo ni ìwọ ń fẹ́ kí á pèsè sílẹ̀?”
Eles lhe perguntaram: “Onde o senhor quer que preparemos o jantar?”
10 Ó sì wí fún wọn pé, “Kíyèsi i, nígbà tí ẹ̀yin bá ń wọ ìlú lọ, ọkùnrin kan tí ó ru ìkòkò omi yóò pàdé yín, ẹ bá a lọ sí ilé tí ó bá wọ̀,
Jesus respondeu: “Quando vocês entrarem na cidade, encontrarão um homem, carregando um pote com água. Sigam esse homem e entrem em sua casa com ele.
11 kí ẹ sì wí fún baálé ilé náà pé, ‘Olùkọ́ wí fún ọ pé, níbo ni gbàngàn àpèjẹ náà gbé wà, níbi tí èmi ó gbé jẹ ìrékọjá pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mi?’
Digam ao dono da casa que o Mestre perguntou: ‘Onde fica a sala onde eu poderei comemorar a Páscoa com os meus discípulos?’
12 Òun ó sì fi gbàngàn ńlá kan lókè ilé hàn yín, tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́, níbẹ̀ ni kí ẹ̀yin pèsè sílẹ̀.”
Ele lhes mostrará uma grande sala no andar de cima da casa, onde tem tudo o que é necessário. Preparem a refeição lá.”
13 Wọ́n sì lọ wọ́n sì bá a gẹ́gẹ́ bí ó tí sọ fún wọn, wọ́n sì pèsè ìrékọjá sílẹ̀.
Os discípulos foram e encontraram tudo exatamente como Jesus tinha dito. Eles, então, prepararam a refeição de Páscoa lá.
14 Nígbà tí àkókò sì tó, ó jókòó àti àwọn aposteli pẹ̀lú rẹ̀.
Quando chegou a hora, ele se sentou à mesa com os seus apóstolos. Ele lhes disse:
15 Ó sì wí fún wọn pé, “Tinútinú ni èmi fẹ́ fi bá yín jẹ ìrékọjá yìí, kí èmi tó jìyà.
“Eu estava aguardando ansiosamente fazer esta refeição de Páscoa com vocês antes que o meu sofrimento comece.
16 Nítorí mo wí fún yín, Èmi kì yóò jẹ nínú rẹ̀ mọ́, títí a ó fi mú un ṣẹ ní ìjọba Ọlọ́run.”
Eu lhes digo que não comerei este jantar novamente, até que eu o coma no Reino de Deus.”
17 Ó sì gba ago, nígbà tí ó sì ti dúpẹ́, ó wí pé, “Gba èyí, kí ẹ sì pín in láàrín ara yín.
Jesus pegou o cálice e, após ter dado graças a Deus, ele disse: “Peguem isto e repartam entre vocês.
18 Nítorí mo wí fún yín, Èmi kì yóò mu nínú èso àjàrà mọ́, títí ìjọba Ọlọ́run yóò fi dé.”
Eu lhes digo que não beberei novamente deste vinho, até que eu o beba no Reino de Deus.”
19 Ó sì mú àkàrà, nígbà tí ó sì ti dúpẹ́ ó bù ú, ó sì fi fún wọn, ó wí pé, “Èyí ni ara mí tí a fi fún yín, ẹ máa ṣe èyí ní ìrántí mi.”
Ele pegou o pão e, após ter dado graças a Deus, dividiu-o em pedaços e repartiu com os discípulos. Jesus lhes disse: “Isto é o meu corpo que é dado a vocês. Façam isso para se lembrarem de mim.”
20 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ lẹ́yìn oúnjẹ alẹ́, ó sì mú ago wáìnì, ó wí pé, “Ago yìí ni májẹ̀mú tuntun nínú ẹ̀jẹ̀ mi, tí a ta sílẹ̀ fún yín.
Da mesma forma, quando acabaram de jantar, ele pegou o cálice e disse: “Este é o cálice do novo acordo, garantido pelo meu sangue, derramado em favor de vocês.”
21 Ṣùgbọ́n ẹ kíyèsi i, ọwọ́ ẹni tí yóò fi mí hàn wà pẹ̀lú mi lórí tábìlì.
“Apesar disso, meu traidor está sentado bem aqui à mesa.
22 Ọmọ Ènìyàn ń lọ nítòótọ́ bí a tí pinnu rẹ̀, ṣùgbọ́n ègbé ni fún ọkùnrin náà nípasẹ̀ ẹni tí a gbé ti fi í hàn.”
Pois foi determinado que o Filho do Homem irá morrer, mas ai do traidor!”
23 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí béèrè láàrín ara wọn, ta ni nínú wọn tí yóò ṣe nǹkan yìí.
Eles começaram a discutir sobre quem seria e quem poderia fazer isso.
24 Ìjà kan sì ń bẹ láàrín wọn, ní ti ẹni tí a kà sí olórí nínú wọn.
Ao mesmo tempo, também houve uma discussão sobre quem era o mais importante entre eles.
25 Ó sì wí fún wọn pé, “Àwọn ọba aláìkọlà a máa fẹlá lórí wọn, a sì máa pe àwọn aláṣẹ wọn ní olóore.
Jesus lhes disse: “Os reis pagãos dominam os seus povos e, aqueles que têm poder querem até mesmo que as pessoas os chamem de ‘benfeitores.’
26 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kì yóò rí bẹ́ẹ̀; ṣùgbọ́n ẹni tí ó ba pọ̀jù nínú yín kí ó jẹ́ bí ẹni tí o kéré ju àbúrò; ẹni tí ó sì ṣe olórí, bí ẹni tí ń ṣe ìránṣẹ́.
Mas, com vocês, não deve ser assim. Pelo contrário, o mais importante entre vocês deve ser como o menos importante, e o líder deve ser como um empregado.
27 Nítorí ta ni ó pọ̀jù, ẹni tí ó jókòó tí oúnjẹ, tàbí ẹni tí ó ń ṣe ìránṣẹ́. Ẹni tí ó jókòó ti oúnjẹ kọ́ bí? Ṣùgbọ́n èmi ń bẹ láàrín yín bí ẹni tí ń ṣe ìránṣẹ́.
Quem é mais importante: aquele que está sentado à mesa para comer ou aquele que serve? Não é aquele que está sentado à mesa? Mas, eu sou como aquele que serve vocês.
28 Ẹ̀yin ni àwọn tí ó ti dúró tì mí nínú ìdánwò mi.
Vocês têm permanecido ao meu lado durante as minhas dificuldades.
29 Mo sì yan ìjọba fún yín, gẹ́gẹ́ bí Baba mi ti yàn fún mi.
E eu darei a vocês autoridade para governar, exatamente como o meu Pai me deu também,
30 Kí ẹ̀yin lè máa jẹ, kí ẹ̀yin sì lè máa mu lórí tábìlì mi ní ìjọba mi, kí ẹ̀yin lè jókòó lórí ìtẹ́, àti kí ẹ̀yin lè máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá.”
para que vocês possam comer e beber a minha mesa, em meu Reino. E vocês se sentarão em tronos para julgar as doze tribos de Israel.”
31 Olúwa sì wí pé, “Simoni, Simoni, wò ó, Satani fẹ́ láti gbà ọ́, kí ó lè kù ọ́ bí alikama.
“Simão, Simão, Satanás pediu todos vocês para peneirar como trigo,
32 Ṣùgbọ́n mo ti gbàdúrà fún ọ, kí ìgbàgbọ́ rẹ má ṣe yẹ̀; àti ìwọ nígbà tí ìwọ bá sì padà bọ̀ sípò, mú àwọn arákùnrin rẹ lọ́kàn le.”
mas eu tenho orado por você, para que a sua fé em mim não acabe. E quando você se converter, dê força aos seus irmãos.”
33 Ó sì wí fún un pé, “Olúwa, mo múra tán láti bá ọ lọ sínú túbú, àti sí ikú.”
Pedro disse: “Senhor, estou pronto para ir com você para a prisão e para morrer com você!”
34 Ó sì wí pé, “Mo wí fún ọ, Peteru, àkùkọ kì yóò kọ lónìí tí ìwọ ó fi sẹ́ mi lẹ́ẹ̀mẹ́ta pé, ìwọ kò mọ̀ mí.”
Jesus respondeu: “Eu lhe digo Pedro, que antes que o galo cante hoje, você negará três vezes que me conhece.”
35 Ó sì wí fún wọn pé, “Nígbà tí mo rán yín lọ láìní àpò-owó, àti àpò, àti bàtà, ọ̀dá ohun kan dá yín bí?” Wọ́n sì wí pé, “Rárá!”
Jesus perguntou aos discípulos: “Quando eu os enviei sem dinheiro, sem bolsa e sem um par extra de sandálias, faltou algo para vocês?” Eles responderam: “Não, não faltou nada!”
36 Nígbà náà ni ó wí fún wọn pé, “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹni tí ó bá ní àpò-owó kí ó mú un, àti àpò pẹ̀lú; ẹni tí kò bá sì ní idà, kí ó ta aṣọ rẹ̀, kí ó sì fi ra ọ̀kan.
“Mas agora, se vocês tiverem dinheiro devem pegá-lo, o mesmo façam com uma bolsa. E se vocês não têm uma espada devem vender a sua capa e comprar uma.
37 Nítorí mo wí fún yín pé, ‘Èyí tí a ti kọ̀wé rẹ̀ kò lè ṣe kí ó má ṣẹ lára mi, a sì kà á mọ́ àwọn arúfin.’ Nítorí àwọn ohun wọ̀nyí nípa ti èmi yóò ní ìmúṣẹ.” tí a sì kà á mọ́ àwọn alárékọjá.
Eu lhes digo que a afirmação que está nas Sagradas Escrituras sobre mim deve se cumprir: ‘Ele foi considerado como um criminoso.’ O que foi dito a meu respeito está se cumprindo agora.”
38 Wọ́n sì wí pé, “Olúwa, sá wò ó, idà méjì ń bẹ níhìn-ín yìí!” Ó sì wí fún wọn pé, “Ó tó.”
Eles disseram: “Veja, Senhor! Temos duas espadas.” Ele respondeu: “Isso basta!”
39 Ó sì jáde, ó sì lọ bí ìṣe rẹ̀ sí òkè olifi, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
Jesus saiu e, como de costume, foi para o monte das Oliveiras, juntamente com os seus discípulos.
40 Nígbà tí ó wà níbẹ̀, ó wí fún wọn pé, “Ẹ máa gbàdúrà, kí ẹ̀yin má ṣe bọ́ sínú ìdẹwò.”
Quando chegou, disse aos discípulos: “Orem para que não caiam em tentação.”
41 Ó sì fi wọ́n sílẹ̀ níwọ̀n ìsọ-òkò kan, ó sì kúnlẹ̀ ó sì ń gbàdúrà.
Então, ele se afastou dos discípulos e foi caminhar a uns trinta metros de distância. Jesus se ajoelhou e começou a orar.
42 Wí pé, “Baba, bí ìwọ bá fẹ́, mu ago yìí kúrò lọ́dọ́ mi: ṣùgbọ́n ìfẹ́ ti èmi kọ́, bí kò ṣe tìrẹ ni kí à ṣe.”
Ele disse: “Pai, se você quiser, por favor, afaste de mim este cálice de sofrimento! Mas, que não seja feito o que eu quero, mas o que o senhor quer.”
43 Angẹli kan sì yọ sí i láti ọ̀run wá, ó ń gbà á ní ìyànjú.
Na mesma hora, um anjo apareceu do céu para lhe dar forças.
44 Bí ó sì ti wà nínú gbígbóná ara ó ń gbàdúrà sí i kíkankíkan; òógùn rẹ̀ sì dàbí ìró ẹ̀jẹ̀ ńlá, ó ń kán sílẹ̀.
Sentindo uma grande angústia, Jesus orou com mais força e o seu suor caía como gotas de sangue no chão.
45 Nígbà tí ó sì dìde kúrò ní ibi àdúrà, tí ó sì tọ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wá, ó bá wọn, wọ́n ń sùn nítorí ìbànújẹ́ ti mu kí ó rẹ̀ wọ́n.
Ele acabou sua oração, levantou-se e voltou para onde estavam os discípulos. Eles estavam adormecidos, esgotados pela tristeza.
46 Ó sì wí fún wọn pé, “Kí ni ẹ̀ yin ń sùn sí? Ẹ dìde, ẹ máa gbàdúrà, kí ẹ̀yin má ṣe bọ́ sínú ìdẹwò.”
Jesus lhes perguntou: “Por que vocês estão dormindo? Levantem-se e orem para que não caiam em tentação!”
47 Bí ó sì ti ń sọ lọ́wọ́, kíyèsi i, ọ̀pọ̀ ènìyàn, àti ẹni tí a ń pè ní Judasi, ọ̀kan nínú àwọn méjìlá, ó ṣáájú wọn, ó súnmọ́ Jesu láti fi ẹnu kò ó ní ẹnu.
Enquanto ele ainda estava falando, uma multidão apareceu, liderada por Judas, um dos doze discípulos. Judas se aproximou de Jesus e o beijou.
48 Jesu sì wí fún un pé, “Judasi, ìwọ yóò ha fi ìfẹnukonu fi Ọmọ Ènìyàn hàn?”
Mas, Jesus lhe perguntou: “Judas, você está traindo o Filho do Homem com um beijo?”
49 Nígbà tí àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ ń wo bí nǹkan yóò ti jásí, wọ́n bi í pé, “Olúwa kí àwa fi idà sá wọn?”
Os seguidores de Jesus lhe perguntaram: “Senhor, devemos atacá-los com as nossas espadas?”
50 Ọ̀kan nínú wọn sì fi idà ṣá ọmọ ọ̀dọ̀ olórí àlùfáà, ó sì gé etí ọ̀tún rẹ̀ sọnù.
E um deles atingiu o empregado do grande sacerdote, cortando sua orelha direita.
51 Ṣùgbọ́n Jesu dáhùn ó wí pé, “Ko gbọdọ̀ ṣe èyí mọ.” Ó sì fi ọwọ́ tọ́ ọ ní etí, ó sì wò ó sàn.
Jesus disse: “Parem! Chega disto!” Ele tocou a orelha do homem e o curou.
52 Jesu wí fún àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn olórí ẹ̀ṣọ́ tẹmpili, àti àwọn alàgbà, tí wọ́n jáde tọ̀ ọ́ wá pé, “Ẹ̀yin ha jáde wá pẹ̀lú idà àti ọ̀kọ̀ bí ẹni tọ ọlọ́ṣà wá?
Depois, Jesus falou com os chefes dos sacerdotes, com os oficiais da guarda do Templo e com os anciãos do povo: “Eu sou algum tipo de criminoso, para que vocês tenham que vir com espadas e porretes?
53 Nígbà tí èmi wà pẹ̀lú yín lójoojúmọ́ ní tẹmpili, ẹ̀yin kò na ọwọ́ mú mi, ṣùgbọ́n àkókò tiyín ni èyí, àti agbára òkùnkùn n jẹ ọba.”
Vocês não me prenderam antes, mesmo eu estando todos os dias com vocês no Templo. Mas agora, este é o seu momento. Este é o tempo em que as trevas estão no poder.”
54 Wọ́n sì gbá a mú, wọ́n sì fà á lọ, wọ́n sì mú un wá sí ilé olórí àlùfáà. Ṣùgbọ́n Peteru tọ̀ ọ́ lẹ́yìn ní òkèrè.
Eles prenderam Jesus e o levaram para a casa do grande sacerdote. Pedro os seguiu a certa distância.
55 Nígbà tí wọ́n sì ti dáná láàrín àgbàlá, tí wọ́n sì jókòó pọ̀, Peteru jókòó láàrín wọn.
Eles acenderam uma fogueira no meio do pátio e se sentaram próximos a ela. Pedro estava entre eles.
56 Ọmọbìnrin kan sì rí i bí ó ti jókòó níbi ìmọ́lẹ̀ iná náà, ó sì tẹjúmọ́ ọn, ó ní, “Eléyìí náà wà pẹ̀lú rẹ̀.”
Quando ele se sentou lá, uma empregada o viu, olhou diretamente para ele e disse:
57 Ṣùgbọ́n, ó wí pé, “Obìnrin yìí, èmi kò mọ̀ ọ́n.”
“Este homem estava com ele!” Mas, Pedro negou. Ele disse: “Não, eu não o conheço!”
58 Kò pẹ́ lẹ́yìn náà ẹlòmíràn sì rí i, ó ní, “Ìwọ pẹ̀lú wà nínú wọn.” Ṣùgbọ́n Peteru wí pé, “Ọkùnrin yìí, èmi kọ́.”
Pouco tempo depois, mais alguém olhou para ele e disse: “Você também é um deles!” E Pedro respondeu: “Não, eu não sou!”
59 Ó sì tó bí i wákàtí kan síbẹ̀ ẹlòmíràn tẹnumọ́ ọn, wí pé, “Nítòótọ́ eléyìí náà wà pẹ̀lú rẹ̀: nítorí ará Galili ní í ṣe.”
Cerca de uma hora depois, outra pessoa insistiu: “Tenho certeza de que você estava com ele também, pois você é galileu.”
60 Ṣùgbọ́n Peteru wí pé, “Ọkùnrin yìí, èmi kò mọ ohun tí ìwọ ń wí!” Lójúkan náà, bí ó tí ń wí lẹ́nu, àkùkọ kọ!
“Eu não tenho ideia do que você está falando!”, Pedro respondeu. Naquele momento, enquanto ele ainda estava falando, o galo cantou. O Senhor virou-se e olhou para Pedro.
61 Olúwa sì yípadà, ó wo Peteru. Peteru sì rántí ọ̀rọ̀ Olúwa, bí ó ti wí fún un pé, “Kí àkùkọ tó kọ, ìwọ ó sẹ́ mi lẹ́ẹ̀mẹ́ta.”
E Pedro se lembrou do que o Senhor lhe tinha dito: “Hoje, antes que o galo cante, você me negará três vezes.”
62 Peteru sì bọ́ sí òde, ó sọkún kíkorò.
Pedro saiu dali e chorou amargamente.
63 Ó sì ṣe, àwọn ọkùnrin tí wọ́n mú Jesu, sì fi í ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n lù ú.
Os homens que vigiavam Jesus começaram a zombar e a bater nele.
64 Nígbà tí wọ́n sì dì í ní ojú, wọ́n lù ú níwájú, wọ́n ń bi í pé, “Sọtẹ́lẹ̀! Ta ni ó lù ọ́?”
Eles colocaram uma venda em seus olhos e depois lhe perguntaram: “Se você pode fazer profecias, então, adivinhe quem bateu em você dessa vez!”
65 Wọ́n sì sọ ọ̀pọ̀ ohun búburú mìíràn sí i, láti fi ṣe ẹlẹ́yà.
Eles também disseram muitos outros insultos para ele.
66 Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, ìjọ àwọn alàgbà àwọn ènìyàn péjọpọ̀, àti àwọn olórí àlùfáà, àti àwọn akọ̀wé, wọ́n sì fà á lọ sí àjọ wọn, wọ́n ń wí pé,
Na manhã do dia seguinte, o conselho de anciãos do povo se reuniu com os chefes dos sacerdotes e com os educadores religiosos. Jesus foi levado diante do conselho.
67 “Bí ìwọ bá jẹ́ Kristi náà? Sọ fún wa!” Ó sì wí fún wọn pé, “Bí mo bá wí fún yín, ẹ̀yin kì yóò gbàgbọ́,
Eles disseram: “Diga para nós se você é realmente o Messias.” Jesus respondeu: “Mesmo se eu dissesse, vocês não acreditariam em mim.
68 bí mo bá sì bi yín léèrè pẹ̀lú, ẹ̀yin kì yóò dá mi lóhùn.
E se eu lhes fizesse uma pergunta, vocês também não me responderiam.
69 Ṣùgbọ́n láti ìsinsin yìí lọ ni Ọmọ Ènìyàn yóò jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún agbára Ọlọ́run.”
Mas, a partir de agora, o Filho do Homem se sentará à direita do Deus Todo-Poderoso.”
70 Gbogbo wọn sì wí pé, “Ìwọ ha ṣe Ọmọ Ọlọ́run bí?” Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin wí pé, èmi ni.”
Todos eles perguntaram: “Então, você é o Filho de Deus?” Jesus respondeu: “São vocês quem estão dizendo isso!”
71 Wọ́n sì wí pé, “Ẹ̀rí wo ni àwa tún ń fẹ́ àwa tìkára wa sá à ti gbọ́ lẹ́nu rẹ̀!”
Eles falaram: “Por que nós precisamos de qualquer outra testemunha? Nós mesmos ouvimos isso de sua própria boca!”

< Luke 22 >