< Psalms 73 >

1 Saamu ti Asafu. Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli, fún àwọn ọlọ́kàn funfun.
Psaume d'Asaph. Oui, Dieu est bon pour Israël, pour ceux qui ont le cœur pur.
2 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán; ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.
Pour moi, le pied m'a presque manqué, et peu s'en est fallu que mes pas n'aient glissé;
3 Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé nígbà tí mo bá rí àlàáfíà àwọn ènìyàn búburú.
Car j'ai porté envie aux insensés, voyant la prospérité des méchants.
4 Wọn kò ṣe wàhálà; ara wọn mókun wọn sì lágbára.
Car ils ne sont point liés jusqu'à leur mort, et leur force est en son entier.
5 Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn; a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlòmíràn.
Quand les mortels sont en peine, ils n'y sont point; ils ne sont point frappés avec les humains.
6 Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn; ìwà ipá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.
C'est pourquoi l'orgueil les entoure comme un collier, la violence les couvre comme un vêtement.
7 Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá; ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdínwọ̀n.
Leurs yeux sont enflés à force d'embonpoint; les désirs de leur cœur se font jour.
8 Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti ìnilára, wọ́n ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.
Ils sont moqueurs et parlent méchamment d'opprimer; ils parlent avec hauteur.
9 Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run ahọ́n wọn gba ipò ayé.
Ils portent leur bouche jusqu'au ciel, et leur langue parcourt la terre.
10 Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn wọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Aussi son peuple en revient à ceci, quand on leur fait boire les eaux amères en abondance,
11 Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀? Ọ̀gá-ògo ha ní ìmọ̀ bí?”
Et ils disent: Comment Dieu connaîtrait-il? Et comment y aurait-il de la connaissance chez le Très-Haut?
12 Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí, ènìyàn asán, wọ́n ń pọ̀ ní ọrọ̀.
Voici, ceux-là sont des méchants, et, toujours heureux, ils amassent des richesses.
13 Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́; nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀.
Certainement c'est en vain que j'ai purifié mon cœur, et que j'ai lavé mes mains dans l'innocence.
14 Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu; a sì ń jẹ mí ní yà ní gbogbo òwúrọ̀.
Car je suis frappé tous les jours, et mon châtiment revient chaque matin.
15 Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,” èmi ó ṣẹ̀ sí ìran àwọn ọmọ rẹ̀.
Si j'ai dit: Je parlerai ainsi; voici, j'étais infidèle à la race de tes enfants.
16 Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí, Ó jẹ́ ìnilára fún mi,
J'ai donc réfléchi pour comprendre ces choses, et cela m'a semblé fort difficile;
17 títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run; nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi.
Jusqu'à ce qu'entré dans les sanctuaires de Dieu, j'aie pris garde à la fin de ces gens-là.
18 Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́ ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.
Car tu les mets en des lieux glissants; tu les fais tomber dans des précipices.
19 Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí bí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan! Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọ́n pátápátá!
Comme ils sont détruits en un moment! enlevés et consumés par une destruction soudaine!
20 Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí, bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, Olúwa, ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.
Tel un songe quand on s'éveille, ainsi, Seigneur, à ton réveil tu mets en mépris leur vaine apparence.
21 Nígbà tí inú mi bàjẹ́ àti ọkàn mi ṣì korò,
Quand mon cœur s'aigrissait ainsi, et que je me tourmentais en moi-même,
22 mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye; mo jẹ́ ẹranko ní iwájú rẹ.
Alors j'étais abruti et sans connaissance; j'étais devant toi comme les bêtes.
23 Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo; ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.
Mais moi, je serai toujours avec toi; tu m'as pris par la main droite.
24 Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi ní ìkẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo.
Tu me conduiras par ton conseil, puis tu me recevras dans la gloire.
25 Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ? Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn rẹ.
Quel autre que toi ai-je au ciel? Je ne prends plaisir sur la terre qu'en toi.
26 Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí mi àti ìpín mi títí láé.
Ma chair et mon cœur défaillaient; mais Dieu est le rocher de mon cœur et mon partage à toujours.
27 Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé ìwọ ti pa gbogbo wọn run; tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
Car voici: ceux qui s'éloignent de toi périront. Tu retranches tous ceux qui se détournent de toi.
28 Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run. Èmi ti fi Olúwa Olódùmarè ṣe ààbò mi; kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ.
Mais pour moi, m'approcher de Dieu, c'est mon bien; j'ai placé mon refuge dans le Seigneur, l'Éternel, afin de raconter toutes tes œuvres.

< Psalms 73 >